< Genesis 35 >
1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
OLELO mai la ke Akua ia Iakoba, E ku ae oe, e pii aku i Betela, ilaila e noho ai: ilaila oe e hana'i i kuahu no ke Akua i ikea e oe i kou wa i mahuka ai mai ka maka o kou kaikuaana o Esau.
2 Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
Alaila, i aku la o Iakoba i ko ka hale ona, a i ka poe a pau me ia, E haalele oukou i na akua e iwaena o oukou, e huikala ia oukou iho, a e aahu iho i na kapa hou:
3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
A e ku ae kakou, e pii aku i Betela; malaila au e hana'i i kuahu no ke Akua nana au i maliu mai i ka la o ko'u popilikia, a i hele pu me au i kuu ala i hele ai.
4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
Haawi mai la lakou ia Iakoba i na akua e ma ko lakou lima, a me na apo ma na pepeiao o lakou: a huna iho la o Iakoba ia mau mea malalo o ka laau oka aia ma Sekema.
5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
Hele aku la lakou: a kau mai la ka weliweli mai ke Akua mai maluna o na kulanakauhale ma kela aoao a keia aoao o lakou, a alualu ole mai la lakou i na keiki o Iakoba.
6 Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
A hiki aku la o Iakoba ia Luza, oia hoi o Betela, ma ka aina o Kanaana, oia a me na kanaka a pau me ia.
7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
Hana iho la ia i kuahu malaila, a kapa iho la ia wahi o i Ele-betela: no ka mea, ilaila ke Akua i ikea ai e ia i kona wa i mahuka ai mai ka maka aku o kona kaikuaana.
8 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
Make iho la o Debora o ke kahu no Rebeka, a ua kanuia oia malalo o Betela malalo o kekahi laau oka: a ua kapaia ka inoa o ia wahi, o i Alona-bakuta.
9 Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
Ikea hou ke Akua e Iakoba, i kona hoi ana mai, noloko mai o Padanarama, a hoomaikai mai la ia ia.
10 Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
I mai la ke Akua ia ia, O Iakoba kou inoa: aole e hea hou ia kou inoa o Iakoba, aka, o Iseraela kou inoa: a kapa iho la oia i kona inoa o Iseraela.
11 Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
I mai la ke Akua ia ia, Owau no ke Akua Mana: a e hoohua ae oe, a e mahuahua; nau mai no kekahi lahuikanaka, a me na lahuikanaka; a e puka mai auanei na alii mailoko mai o kou puhaka;
12 Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
A o ka aina a'u i haawi aku ai no Aberahama, a no Isaaka, e haawi aku hoi au nou, a no kau poe mamo mahope ou ka'u e haawi aku ai i ka aina.
13 Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
A pii aku la ke Akua iluna mai ona aku la, ma kahi ana i kamailio pu ai me ia.
14 Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
Hooku ae la o Iakoba i eho ma kahi ana i kamailio mai ai me ia, he eho pohaku: a ninini iho la ia i ka mohaiinu maluna; a ninini iho la hoi oia i ka aila maluna.
15 Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
Kapa iho la o Iakoba i ka aina o kahi a ke Akua i olelo mai ai me ia, o Betela.
16 Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
Hele aku la lakou mai Betela aku, a ua kokoke e hiki i Eperata, haakohi iho la o Rahela, a puua iho i ka hanau keiki ana.
17 Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
A i kona puua ana, i aku la ka pale keiki ia ia, Mai makau oe, e loaa auanei ia oe keia keiki no hoi.
18 Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
A i ka wa e kaili ana kona ea, (no ka mea, make no oia, ) kapa iho la ia i kona inoa, i Benoni: aka, kapa aka la kona makuakane ia ia, o Beniamina.
19 Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
Make iho la o Rahela, a kanuia oia ma ke alanui e hele ai i Eperata, oia o Betelehema.
20 Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
Hooku ae la o Iseraela, i pohaku eho maluna o kona he, oia ka eho no ka he o Rahela, a hiki i keia manawa.
21 Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
Hele aku la o Iseraela, a kukulu iho la i kona halelewa ma o aku o ka halekiai o Edara.
22 Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
A i ka noho ana o Iseraela ma ia aina, hele aka la o Reubena, a moe pu iho la me Bileha me ka haiawahine a kona makuakane; a lohe ae la o Iseraela. O na keikikane a Iakoba he umikumamalua:
23 Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
O na keikikane a Lea; o Reubena ka makahiapo a Iakoba, o Simeona, o Levi, o Iuda, o Isakara, a o Zebuluna.
24 Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
O na keikikane a Rahela; o Iosepa, a o Beniamina.
25 Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
O na keikikane a Bileha, a ke kauwawahine a Rahela; o Dana, a o Napetali.
26 Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
O na keikikane a Zilepa, a ke kauwawahine a Lea; o Gada a o Asera. O lakou na keikikane a Iakoba, i hanau nana ma Padanarama.
27 Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
Hele aku la o Iakoba i kona makuakane ia Isaaka ma Mamere, ma ke kulanakauhale o Areba, (oia o Heberona, ) kahi i noho ai o Aberahama a me Isaaka.
28 Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
A o na la o Isaaka, hookahi haneri makahiki a me kanawalu.
29 Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.
Kuu aku la o Isaaka i ka uhane, a make iho la, a ua huiia'ku ia me kona poe kanaka: ua elemakule ia, a nui loa kona mau la: na kana mau keikikane na Esau ma laua o Iakoba oia i kanu.