< Genesis 35 >

1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
Dieu dit à Jacob: « Lève-toi, monte à Béthel, et tu y habiteras. Fais-y un autel à Dieu, qui t'est apparu lorsque tu fuyais la face d'Ésaü, ton frère. »
2 Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
Alors Jacob dit à sa famille et à tous ceux qui étaient avec lui: « Otez les dieux étrangers qui sont au milieu de vous, purifiez-vous et changez de vêtements.
3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
Levons-nous, et montons à Béthel. J'y ferai un autel à Dieu, qui m'a exaucé au jour de ma détresse et qui a été avec moi sur le chemin que j'ai parcouru. »
4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
Ils donnèrent à Jacob tous les dieux étrangers qui étaient dans leurs mains et les anneaux qui étaient à leurs oreilles, et Jacob les cacha sous le chêne qui était près de Sichem.
5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
Ils voyagèrent, et la terreur de Dieu était sur les villes qui les entouraient, et elles ne poursuivirent pas les fils de Jacob.
6 Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
Jacob arriva à Luz (c'est-à-dire à Béthel), qui est dans le pays de Canaan, lui et tout le peuple qui était avec lui.
7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
Il y bâtit un autel et appela le lieu El Beth El, car c'est là que Dieu se révéla à lui, lorsqu'il fuyait la face de son frère.
8 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
Débora, la nourrice de Rebecca, mourut, et elle fut enterrée au-dessous de Béthel, sous le chêne; et son nom fut appelé Allon Bacuth.
9 Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
Dieu apparut de nouveau à Jacob, lorsqu'il revint de Paddan Aram, et il le bénit.
10 Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Dieu lui dit: « Ton nom est Jacob. Ton nom ne sera plus Jacob, mais ton nom sera Israël. » Il lui donna le nom d`Israël.
11 Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
Dieu lui dit: « Je suis le Dieu tout-puissant. Sois fécond et multiplie. Une nation et une multitude de nations naîtront de toi, et des rois sortiront de ton corps.
12 Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
Le pays que j'ai donné à Abraham et à Isaac, je te le donnerai, et je le donnerai à ta postérité après toi. »
13 Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
Dieu se retira de lui dans le lieu où il lui avait parlé.
14 Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
Jacob dressa une colonne dans le lieu où il lui avait parlé, une colonne de pierre. Il y versa une libation et y répandit de l'huile.
15 Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
Jacob appela « Béthel » le nom du lieu où Dieu lui avait parlé.
16 Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
Ils partirent de Béthel. Il y avait encore de la distance à parcourir jusqu'à Ephrath, et Rachel était en travail. Elle a eu un travail difficile.
17 Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
Comme elle était en plein travail, la sage-femme lui dit: « N'aie pas peur, car tu vas avoir un autre fils. »
18 Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
Comme son âme s'en allait (car elle est morte), elle l'appela Benoni, mais son père l'appela Benjamin.
19 Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
Rachel mourut, et elle fut enterrée sur le chemin d'Éphrata (appelée aussi Bethléhem).
20 Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
Jacob dressa un pilier sur son tombeau. C'est encore aujourd'hui le pilier du tombeau de Rachel.
21 Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
Israël partit en voyage et étendit sa tente au-delà de la tour d'Eder.
22 Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
Pendant qu'Israël habitait dans ce pays, Ruben alla coucher avec Bilha, la concubine de son père, et Israël en entendit parler. Les fils de Jacob étaient au nombre de douze.
23 Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
Fils de Léa: Ruben (premier-né de Jacob), Siméon, Lévi, Juda, Issacar et Zabulon.
24 Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
Fils de Rachel: Joseph et Benjamin.
25 Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
Fils de Bilha (servante de Rachel): Dan et Nephtali.
26 Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
Fils de Zilpa (servante de Léa): Gad et Aser. Ce sont là les fils de Jacob, qui lui sont nés à Paddan Aram.
27 Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
Jacob vint auprès d'Isaac, son père, à Mamré, à Kiriath Arba (qui est Hébron), où Abraham et Isaac vivaient en étrangers.
28 Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
Les jours d'Isaac furent de cent quatre-vingts ans.
29 Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.
Isaac rendit l'esprit et mourut, et il fut recueilli auprès de son peuple, âgé et rassasié de jours. Ésaü et Jacob, ses fils, l'ensevelirent.

< Genesis 35 >