< Genesis 35 >

1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
And God said unto Jacob, Arise, go up to Beth-el, and dwell there; and make there an altar unto the God that appeared unto thee when thou fleddest from the face of Esau thy brother.
2 Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
Then said Jacob unto his household, and to all that were with him, Put away the strange gods that are among you, and cleanse yourselves, and change your garments.
3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
And let us arise, and go up to Beth-el: and I will make there an altar unto the God who answered me on the day of my distress, and was with me on the way which I went.
4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
And they gave unto Jacob all the strange gods which were in their hand, and the earrings which were in their ears; and Jacob hid them under the oak which was near Shechem.
5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
And they journeyed; and the terror of God was upon the cities that were round about them, and they did not pursue after the sons of Jacob.
6 Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
So Jacob came to Luz, which is in the land of Canaan, that is, Beth-el, he and all the people that were with him.
7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
And he built there an altar, and called the place El-beth-el: because there God appeared unto him, when he fled from the face of his brother.
8 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
And Deborah Rebekah's nurse died, and she was buried beneath Beth-el under an oak: and he called its named Allon-bachuth.
9 Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
And God appeared unto Jacob again, when he came from Padan-aram, and blessed him.
10 Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
And God said unto him, Thy name is Jacob; thy name shall not be called any more Jacob, but Israel shall be thy name: and he called his name Israel.
11 Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
And God said unto him, I am God the Almighty; be fruitful and multiply; a nation and an assemblage of nations shall spring from thee, and kings shall come out of thy loins.
12 Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
And the land which I gave to Abraham and to Isaac, to thee will I give it; and to thy seed after thee will I give the land.
13 Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
And God went up from him on the place where he had spoken with him.
14 Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
And Jacob set up a pillar at the place where he had spoken with him, a pillar of stone; and he poured a drink offering thereon, and he poured oil thereon.
15 Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
And Jacob called the name of the place where God had spoken with him, Beth-el.
16 Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
And they journeyed from Beth-el: and there was yet some distance to come to Ephrath, when Rachel travailed, and she had hard labor.
17 Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
And it came to pass, when she was in hard labor, that the midwife said unto her, Fear not; for this child also is a son for thee.
18 Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
And it came to pass, as her soul was departing, [for she died] that she called his name Ben-oni; but his father called him Benjamin.
19 Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
And so Rachel died, and was buried on the way to Ephrath, which is Beth-lechem.
20 Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
And Jacob set a pillar upon her grave: this is the pillar of Rachel's grave unto this day.
21 Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
And Israel journeyed, and spread his tent beyond the tower of flocks [Eder].
22 Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
And it came to pass, when Israel dwelt in that land, that Reuben went and lay with Bilhah his father's concubine; and Israel heard it. Now the sons of Jacob were twelve.
23 Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
The sons of Leah, Jacob's first-born, Reuben, and Simeon, and Levi, and Judah, and Issachar, and Zebulun.
24 Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
The sons of Rachel, Joseph, and Benjamin.
25 Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
And the sons of Bilhah, Rachel's handmaid, Dan, and Naphtali.
26 Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
And the sons of Zilpah, Leah's handmaid, Gad, and Asher: these are the sons of Jacob, that were born to him in Padan-aram.
27 Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
And Jacob came unto Isaac his father unto Mamre, the city of Arba', which is Hebron, where Abraham and Isaac had sojourned.
28 Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
And the days of Isaac were one hundred and eighty years.
29 Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.
And Isaac departed this life, and died, and was gathered unto his people, old and full of days; and Esau and Jacob his sons buried him.

< Genesis 35 >