< Genesis 34 >

1 Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
I wyszła Dyna, córka Lii, którą była urodziła Jakóbowi, aby oglądała córki onej ziemi.
2 Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
A ujrzawszy ją Sychem, syn Hemora Hewejczyka, książęcia ziemi onej, porwał ją, i spał z nią, i zelżył ją.
3 Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
I spoiła się dusza jego z Dyną, córką Jakóbową, a rozmiłowawszy się dzieweczki, mówił do serca jej.
4 Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
Tedy Sychem rzekł do Hemora, ojca swego, mówiąc: Weźmij mi te dzieweczkę za żonę.
5 Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
A gdy Jakób usłyszał, że zgwałcona była Dyna, córka jego, a synowi jego byli z bydłem jego na polu, zamilczał tego Jakób, aż się oni zwrócili.
6 Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
Tedy wyszedł Hemor, ojciec Sychemów, do Jakóba, aby z nim mówił.
7 Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
A synowie Jakóbowi gdy przyszli z pola, a usłyszeli to, boleścią zjęci byli mężowie oni, i rozgniewali się bardzo, że tę sprośność uczynił w Izraelu, śpiąc z córką Jakóbową, co być nie miało.
8 Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
I rzekł Hemor do nich mówiąc: Sychem, syn mój, przyłożył serce swe ku córce waszej; dajcież mu ją proszę za żonę.
9 Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
A spowinowaćcie się z nami, córki wasze dawając nam, a córki nasze pojmując sobie.
10 Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
I będziecie z nami mieszkać, a ziemia będzie przed wami; mieszkajcie, i handlujcie w niej, i osadzajcie się w niej.
11 Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
I mówił też Sychem do ojca jej, i braci jej: Niech znajdę łaskę w oczach waszych, a co mi rzeczecie, to dam.
12 Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
Podwyższcie mi znacznie wiana, i upominków żądajcie, a dam jako mi rzeczecie; tylko mi dajcie tę dzieweczkę za żonę.
13 Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
Tedy odpowiedzieli synowie Jakóbowi Sychemowi i Hemorowi, ojcu jego, na zdradzie mówiąc z nimi, dla tego iż zgwałcił Dynę, siostrę ich.
14 Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
I rzekli im: Nie możemy tej rzeczy uczynić, abyśmy mieli dać siostrę naszę mężowi nieobrzezanemu; bo to obrzydła rzecz u nas.
15 Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
A wszakże tym sposobem wam pozwolimy, jeźliże chcecie być nam podobni, aby był obrzezany między wami każdy mężczyzna;
16 Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
Tedy wam damy córki nasze, a córki wasze pojmiemy sobie, i będziemy mieszkać z wami, a będziemy ludem jednym.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
Ale jeźlibyście nas nie usłuchali, abyście się obrzezali, weźmiemy córkę naszę, i odejdziemy.
18 Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
I podobała się ta rzecz ich Hemorowi i Sychemowi, synowi Hemorowemu.
19 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
Tedy nie odkładał on młodzieniec długo tej rzeczy, bo się był rozmiłował córki Jakóbowej; a on był ze wszech najzacniejszy w domu ojca swego.
20 Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
I przyszedł Hemor i Sychem, syn jego, do bramy miasta swego, i rzekli do mężów miasta swego mówiąc:
21 Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
Mężowie ci spokojnie żyją z nami; niechże mieszkają w tej ziemi, i niech handlują w niej, gdyż oto ziemia nasza dosyć jest przestronna dla nich; córki ich będziemy brać sobie za żony, a córki nasze będziemy im dawać.
22 Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
Ale tym sposobem pozwalają mężowie ci, mieszkać z nami, abyśmy byli jednym ludem: żeby był obrzezan między nami każdy mężczyzna, tak jako oni są obrzezani.
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
Trzody ich, i majętności ich, i wszystkie bydła ich, azaż nie nasze będą? na to tylko im pozwólmy, a będą mieszkać z nami.
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
I usłuchali Hemora i Sychema, syna jego, wszyscy wychodzący z bramy miasta jego, i obrzezał się każdy mężczyzna, cokolwiek ich wychodziło z bramy miasta jego.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
I stało się dnia trzeciego gdy byli w najcięższym bólu, tedy wzięli dwaj synowie Jakóbowi, Symeon i Lewi, bracia Dyny, każdy miecz swój, a weszli do miasta śmiele, i pomordowali wszystkie mężczyzny.
26 Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
Hemora też i Sychema, syna jego, zabili mieczem, a wziąwszy Dynę z domu Sychemowego, odeszli.
27 Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
Drudzy też synowie Jakóbowi przyszli do pobitych, i złupili miasto, przeto iż zgwałcili siostrę ich.
28 Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
Owce ich, i woły ich, i osły ich, i co w mieście było, i co na polu, pobrali.
29 Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
I wszystkę majętność ich, i wszystkie dzieci ich, i żony ich, w niewolą zabrali, i wybrali wszystko, co w domach było.
30 Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
Tedy rzekł Jakób do Symeona i Lewiego: Zafrasowaliście mię, a przywiedliście mię w ohydę u obywateli ziemi tej, u Chananejczyków i Ferezejczyków; ja niewielką liczbę ludu mam, a zebrawszy się przeciwko mnie, porażą mię, a tak zginę ja, i dom mój
31 Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”
A oni odpowiedzieli: Izali jako wszetecznicy miał używać siostry naszej?

< Genesis 34 >