< Genesis 34 >

1 Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
És kiment Dina, Léa leánya, a kit szült Jákóbnak, hogy megnézze az ország leányait.
2 Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
És meglátta őt Sekhem, a chivvita, Chamór fia, az ország fejedelme, vette őt, hált vele és meggyalázta.
3 Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
És ragaszkodott a lelke Dinához, Jákób leányához, s megszerette a leányt és a leánynak szívére beszélt.
4 Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
És szólt Sekhem Chamórhoz, az atyjához, mondván: Vedd el nekem e leányt feleségül.
5 Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
Jákób pedig meghallotta, hogy megfertőztették Dinát, a leányát, de fiai az ő jószágával a mezőn voltak, és hallgatott Jákób, míg megjöttek.
6 Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
És kiment Chamór, Sekhem atyja Jákóbhoz, hogy beszéljen vele.
7 Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
Jákób fiai pedig jöttek a mezőről; midőn meghallották, bosszankodtak a férfiak és haragjukra volt nagyon, hogy aljasságot tettek Izraélben, hálván Jákób leányával, és így nem szabad tenni.
8 Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
És beszélt velük Chamór, mondván: Sekhem fiam lelke csüng leánytokon, adjátok, kérlek, őt neki feleségül.
9 Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
Házasodjatok össze velünk: leányaitokat adjátok nekünk és leányainkat vegyétek el magatoknak;
10 Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
és velünk lakjatok: az ország legyen előttetek, lakjátok és járjátok be és foglaljatok birtokot benne.
11 Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
És szólt Sekhem az atyjához és fivéreihez: Csak találjak kegyet szemeitekben, és a mit mondtok nekem, azt megadom.
12 Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
Vessetek ki reám igen sok jegybért meg ajándékot és én megadom, a mint mondjátok nekem; de adjátok nekem a leányt feleségül.
13 Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
És feleltek Jákób fiai Sekhemnek és Chamórnak, az atyjának csellel és szóltak – mivelhogy megfertőztette Dinát, a nővérüket –
14 Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
és mondták nekik: Nem tehetjük ezt a dolgot, hogy odaadjuk nővérünket egy férfiúnak, kinek előbőre van, mert szégyen az nekünk.
15 Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
Csak akképpen egyezünk meg veletek, ha olyanok lesztek, mint mi, körülmetélkedvén köztetek minden férfi;
16 Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
akkor odaadjuk leányainkat nektek, leányaitokat pedig elvesszük magunknak, veletek lakunk és leszünk egy néppé.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
De ha nem hallgattok reánk, hogy körülmetélkedjetek, akkor vesszük leányunkat és megyünk.
18 Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
És jónak tetszettek szavaik Chamór szemeiben és Sekhem, Chamór fiának szemeiben.
19 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
És nem késett az ifjú megtenni a dolgot, mert megkedvelte Jákób leányát; ő pedig tiszteltebb volt atyja egész házánál.
20 Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
És jöttek Chamór és Sekhem a fia, városuk kapujába és szóltak városuk embereihez, mondván:
21 Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
Ezek az emberek békések velünk, lakjanak hát az országban és járják azt be, és az ország íme tág határú előttük; leányaikat vegyük el magunknak feleségül, leányainkat pedig adjuk nekik.
22 Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
Csak akképpen egyeznek meg velünk ez emberek, hogy velünk lakjanak, hogy egy néppé legyünk, ha körülmetélkedik közöttünk minden férfi, a mint ők körülmetéltek.
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
Jószáguk, birtokuk s minden barmuk, nemde a mienk? Csak egyezzünk meg velük, hogy velünk lakjanak.
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
És hallgattak Chamórra és Sekhemre, a fiára mind, a kik kimentek városának kapujába és körülmetélkedett minden férfi, mind, a kik kimentek városának kapujába.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
És történt a harmadik napon, midőn fájdalmat szenvedtek, vették Jákóbnak két fia, Simeón és Lévi, Dina fivérei, mindegyik a kardját és mentek a gyanútlan város ellen és megöltek minden férfit;
26 Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
Chamórt és Sekhemet a fiát is megölték a kard élével és vették Dinát Sekhem házából és elmentek.
27 Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
Jákób fiai rámentek a megöltekre és kifosztották a várost, mivelhogy megfertőztették nővérüket.
28 Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
Juhaikat, marhájukat és szamaraikat és a mi a városban meg a mezőn volt, elvették;
29 Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
és egész vagyonukat és mind a gyermekeiket s asszonyaikat fogva vitték és elprédálták – mindent, a mi a házban volt.
30 Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
És szólt Jákób Simeónhoz és Lévihez: Megzavartatok engem, rossz hírbe kevervén az ország lakójánál, a kanaáninál és a perizzinél, holott én csekély számmal vagyok, s ha ők összegyülekeznek ellenem, megvernek és elpusztulok én és házam.
31 Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”
És mondták: Hát mint paráznával bánjanak-e nővérünkkel?

< Genesis 34 >