< Genesis 34 >

1 Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
HELE aku la o Dina o ke kaikamahine a Lea i hanau ai na Iakoba, e ike i na kaikamahine o ia aina.
2 Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
A ike mai la o Sekema o ke keiki a Hamora no ka Hivi ke alii o ua aina la ia ia, lalau aku la kela ia ia, moe iho la me ia, a hoohaumia ia ia.
3 Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
Hoopili mai la kona naau ia Dina i ke kaikamahine a Iakoba; aloha mai la ia i ua kaikamahine la, a olelo oluolu mai la i ua kaikamahine la.
4 Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
Olelo aku la o Sekema i kona makuakane ia Hamora, E kii aku oe i ua kaikamahine la, i wahine na'u.
5 Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
Lohe ae la o Iakoba ua hoohaumia oia i kana kaikamahine ia Dina: aia no kana mau keikikane ma ke kula me kona poe holoholona; a noho olelo ole la o Iakoba, a hoi mai la lakou.
6 Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
Hele aku la o Hamora, ka makuakane o Sekema iwaho io Iakoba la e kamailio me ia.
7 Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
A lohe ae la na keiki a Iakoba, hoi mai la lakou mai ke kela mai: ehaeha loa ka naau o ua poe kanaka la, a huhu loa iho la lakou, no ka mea, ua hana mai ia i ka mea kolohe i ka Iseraela, i ka moe ana me ke kaikamahine a Iakoba; ka mea pono ole ke hanaia pela.
8 Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
Kamailio mai la o Hamora me lakou, i mai la, Ua pili ka naau o kuu keikikane i ka oukou kaikamahine: ke noi aku nei au ia oukou, e haawi mai ia ia i wahine nana.
9 Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
E mare mai oukou me makou; e haawi mai i na kaikamahine a oukou na makou, a e lawe hoi i na kaikamahine a makou na oukou.
10 Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
E noho pu oukou me makou: imua hoi o ko oukou alo ka aina: e noho oukou, a e kuai hoi iloko, a e hoolilo i ka aina no oukou.
11 Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
Olelo mai la hoi o Sekema i ko Dina makuakane a me kona mau kaikunane, E lokomaikai mai oukou ia'u, a e haawi aku hoi au i ka oukou mea e olelo mai ai ia'u.
12 Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
E hoonui loa oukou i ka'u mea e uku aku ai, a me ka makana, a e haawi aku no au e like me ka oukou e olelo mai ai: aka, e haawi mai i ke kaikamahine i wahine na'u.
13 Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
Olelo hoopunipuni aku la na keikikane a Iakoba ia Sekema, a ia Hamora i kona makuakane, olelo lakou pela, no ka mea, ua hoohaumia oia ia Dina i ko lakou kaikuwahine.
14 Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
Olelo aku la lakou ia laua, Aole e pono ia makou ke hana ia mea, ke haawi aku i ko makou kaikuwahine na ka mea i okipoepoe ole ia; no ka mea, he mea hoino ia no makou.
15 Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
Penei wale no ka makou e ae aku ai ia olua, a i like auanei oukou me makou, i okipoepoeia na kane o oukou a pau;
16 Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
Alaila makou e haawi aku ai i ka makou kaikamahine na oukou, a e lawe hoi i na kaikamahine a oukou na makou; a e noho pu me oukou, a lilo kakou i hookahi poe kanaka.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
Aka, ke hoolohe ole oukou i ka makou, e okipoepoeia'i; alaila e lawe aku makou i ka makou kaikamahine, a e hele.
18 Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
A he oluolu ka lakou olelo ia Hamora, a me Sekema ke keiki a Hamora.
19 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
Aole i hoopanee aku na kanaka opiopio la i ka hana ana ia mea; no ka mea, he makemake kona i ke kaikamahine a Iakoba: a ua oi aku kona maikai imua o ko ka hale a pau o kona makuakane.
20 Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
Hele aku la o Hamora, laua o Sekema o kana keiki ma ka ipuka o ko laua kulanakauhale, a kamailio pu iho la me na kanaka o ko laua kulanakauhale, i kai ana aku,
21 Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
Ea, ke noho malie nei keia poe kanaka me kakou; nolaila, e hoonoho kakou ia lakou ma ka aina, e piele lakou iloko; no ka mea, o ka aina, aia hoi, ua akea ia no lakou; e lawe kakou i na kaikamahine a lakou i wahine na kakou, a e haawi aku hoi kakou i na kaikamahine a kakou na lakou.
22 Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
Penei wale no e ae mai ai ua poe kanaka la e noho me kakou, hookahi poe, i okipoepoeia na kane a pau o kakou, e like me lakou i okipoepoeia'i.
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
Aole anei e lilo na kakou ko lakou poe holoholona iki, ka lakou waiwai, a me na holoholona nui a pau a lakou? E ae wale aku no kakou ia lakou, a e noho pu auanei lakou me kakou.
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
Hoolohe aku la lakou ia Hamora a i kana keiki ia Sekema, o ka poe a pau i puka iwaho ma ka ipuka o kona kulanakauhale: a ua okipoepoeia na kane a pau, ka poe a pau i puka iwaho ma ka ipuka o kona kulanakauhale.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
A i ke kolu o ka la, ia lakou i eha ai, o na keikikane elua a Iakoba, o Simeona laua o Levi, na kaikunane o Dina, lalau aku la laua i na pahikaua a laua, hele aku la laua i ua kulanakauhale la me ka makau ole, a pepehi aku la i na kane a pau.
26 Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
Pepehi aku la laua ia Hamora, laua o Sekema o kana keiki me ka maka o ka pahikaua, lawe aku la hoi ia Dina iwaho o ka hale o Sekema, a hele aku la iwaho.
27 Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
Held mai la na keiki a Iakoba i ka poe i pepehiia, a lawe pio ae la i ka waiwai o ke kulanakauhale; no ka mea, ua hoohaumia lakou i ko lakou kaikuwahine.
28 Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
Lawe pio aku la hoi lakou i na hipa a lakou, a me na bipi a lakou, a me na hoki a lakou, me ko loko o ke kulanakauhale, a me ko ke kula,
29 Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
Me ko lakou waiwai a pau, me ka lakou kamalii a pau, a me na wahine a lakou, na pau ia lakou i ka hoopioia; a hao ae la lakou i na mea a pau o ka hale.
30 Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
Olelo aku la o Iakoba ia Simeona laua o Levi, Ua hoopilikia mai olua ia'u, i pilau aku ai au iwaena o na kanaka o ka aina nei, iwaena o ka Kanaana a me ka Perezi: a owau la e, he poe uuku ko'u, e hoakoakoa mai auanei lakou e ku e ia'u, a e pepehi mai ia'u, a e make auanei au me ko ka Hale o'u.
31 Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”
I mai la lakou, E pono anei e hana mai ia i ko makou kaikuwahine, me he wahine hookamakama la?

< Genesis 34 >