< Genesis 34 >

1 Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
Og Dina, Leas Datter, som hun havde født Jakob, gik ud for at se paa Landets Døtre.
2 Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
Og Sikem, Landsherren Hemor den Heviters Søn, saa hende, og han tog hende og laa hos hende og krænkede hende.
3 Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
Og hans Hjerte hængte ved Dina, Jakobs Datter, og han havde Pigen kær og talede kærligen med Pigen.
4 Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
Og Sikem talede til sin Fader, Hemor, og sagde: Tag mig denne Pige til Hustru!
5 Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
Og Jakob havde hørt, at han havde skændet Dina, hans Datter, og hans Sønner vare med hans Kvæg paa Marken, og Jakob tav, indtil de kom.
6 Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
Og Hemor, Sikems Fader, gik ud til Jakob at tale med ham.
7 Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
Og Jakobs Sønner kom fra Marken, der de hørte det, og Mændene forbitredes og bleve saare vrede; thi han havde gjort en Daarlighed mod Israel ved at ligge hos Jakobs Datter, og saaledes burde det ikke ske.
8 Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
Da talede Hemor med dem og sagde: Min Søn Sikems Hjerte har Lyst til eders Datter; kære, giver ham hende til Hustru,
9 Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
og gører Svogerskab med os; giver os eders Døtre, og tager eder vore Døtre!
10 Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
Og I skulle bo hos os, og Landet skal være for eders Aasyn, bor og handler deri, tager eder Ejendom i det!
11 Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
Og Sikem sagde til hendes Fader og til hendes Brødre: Lad mig finde Naade for eders Øjne, og jeg vil give, hvad I ville sige til mig.
12 Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
Begærer saare meget af mig til Morgengave og Skænk, og jeg vil give, efter som I sige mig, men giver mig Pigen til Hustru!
13 Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
Da svarede Jakobs Sønner Sikem og hans Fader Hemor svigagtigen og talede med dem, fordi han havde skændet Dina, deres Søster,
14 Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
og de sagde til dem: Vi kunne ikke gøre denne Gerning, at give vor Søster til en Mand, som har Forhud; thi det er en Forsmædelse for os.
15 Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
Dog ville vi være eder til Villie i dette, dersom I ville blive som vi, saa I lade alt Mandkøn hos eder omskære.
16 Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
Og vi ville give eder vore Døtre og tage os eders Døtre og bo hos eder, og vi ville være eet Folk.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
Men dersom I ikke ville høre os i at lade eder omskære, da ville vi tage vor Datter og drage bort.
18 Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
Og deres Tale behagede Hemor og Sikem, Hemors Søn.
19 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
Og den unge Karl tøvede ikke med at gøre denne Gerning; thi han havde Lyst til Jakobs Datter, og han var æret fremfor hele sin Faders Hus.
20 Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
Saa kom Hemor og Sikem, hans Søn, til deres Stads Port og talede til deres Bymænd og sagde:
21 Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
disse Mænd ere fredsommelige hos os og ville bo i Landet og handle deri, og se, Landet er vidt nok for dem; vi ville tage os deres Døtre til Hustruer og give dem vore Døtre.
22 Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
Dog i saa Maade ville Mændene være os til Villie med at bo hos os og blive eet Folk med os, om vi ville omskære alt Mandkøn iblandt os, lige som de ere omskaarne.
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
Deres Fæ og deres Gods og alt deres Kvæg, blive de ikke vore? ikkun at vi ere dem til Villie, da ville de bo hos os.
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
Og de løde Hemor og hans Søn Sikem, alle de, som gik ud af hans Stads Port, og alt Mandkøn lod sig omskære, alle som gik ud af hans Stads Port.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
Og det skete paa den tredje Dag, der de havde Smerter, da toge de to Jakobs Sønner, Simeon og Levi, Dinas Brødre, hver sit Sværd og kom ind i den trygge Stad, og de sloge alt Mandkøn ihjel.
26 Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
Og de sloge Hemor og hans Søn, Sikem, ihjel med skarpe Sværd og toge Dina af Sikems Hus og gik bort.
27 Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
Saa kom Jakobs Sønner over de ihjelslagne og plyndrede Staden, fordi de havde skændet deres Søster.
28 Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
Deres Kvæg og deres Øksen og deres Asener, baade hvad der var i Staden, og hvad der var paa Marken, toge de.
29 Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
Og al deres Formue og alle deres Børn og deres Kvinder fangede og røvede de, og alt, hvad der var i Huset.
30 Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
Da sagde Jakob til Simeon og Levi: I have forstyrret mig, idet I gjorde mig stinkende for dette Lands Indbyggere, for Kananiten og Feresiten, og jeg er en liden Hob, og de kunne samle sig imod mig og slaa mig, og jeg maatte ødelægges, jeg og mit Hus.
31 Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”
Og de sagde: Mon han skulde handle med vor Søster som med en Skøge?

< Genesis 34 >