< Genesis 34 >

1 Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
Leah canu Dinah, Jakob ham a cun pah te tolrhum kah tanu rhoek te sawt hamla cet.
2 Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
Tedae khohmuen kah khoboei Khivee Hamor capa Shekhem loh anih te a hmuh dongah a loh tih a yalh puei phoeiah a tholh puei.
3 Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
Te phoeiah Jakob canu Dinah taengah a hinglu tlun tih hula te a lungnah dongah hula kah lungbuei te doelh a voek.
4 Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
Te dongah Shekhem loh a napa Hamor la, “Hekah hutaca he kai ham ka yuu la han lo,” a ti nah tih a thui pah.
5 Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
A canu Dinah a poeih pah te Jakob loh a yaak dae kohong ah a ca rhoek neh boiva te a om pueng dongah amih halo uh due Jakob loh hil a phah.
6 Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
Jakob te voekhlak ham Shekhem napa Hamor te cet.
7 Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
Jakob ca rhoek khaw pong lamkah a pai uh vaengah a yaak uh. Tongpa tongpa rhoek te a kothae uh tih amih te muep sai uh. Jakob canu taengah a yalh te Israel taengah boethaehalang ni a. saii. Tedae he he a saii tueng moenih.
8 Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
Tedae Hamor loh amih taengah, “Ka capa Shekhem loh nang canu soah a hinglu loh a ven oeh tih a yuu la m'pae mai.
9 Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
Te phoeiah nangmih nu te kaimih taengah vasak sak ham kaimih m'pae lamtah namamih ham kaimih nu na loh uh mako.
10 Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
Kaimih taengah khosa uh mai. Na mikhmuh ah khohmuen om coeng. Khosa uh lamtah thimpom neh a khuikah te bawn uh,” a ti nah.
11 Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
Te vaengah Shekhem loh Dinah kah a napa neh a nganpa rhoek taengah, “Nangmih mikhmuh ah mikdaithen ka dang atah kai taengah na kuek uh vanbangla kan paek uh bitni.
12 Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
Kai soah maan neh kutdoe muep na kuek uh akhaw kai taengah na kuek uh te tah kan paek bitni. Tedae hula te ka yuu la kai taengah paek uh,” a ti nah.
13 Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
Tedae a ngannu Dinah te a poeih pah dongah Jakob ca rhoek loh Shekhem neh a napa Hamor te a doo uh vaengah thailatnah neh a voek uh.
14 Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
Amih rhoi te, “Hlang yanghli taengah ka ngannu paek ham hno saii he kaimih ham kokhahnah la om tih coeng pawh.
15 Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
Nangmih taengkah tongpa boeih te yahhmui a rhet tih kaimih bangla na om uh atah he nen bueng ni nangmih te kan rhoi uh eh.
16 Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
Te daengah ni kaimih nu rhoek te nangmih kan paek uh phoeiah kamamih ham nangmih nu rhoek te ka loh uh vetih nangmih taengah kho ka sak uh vaengah pilnam pakhat la n'coeng uh eh.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
Tedae yahhmui rhet ham kaimih neh nan rhoi uh pawt atah ka canu he ka loh uh vetih ka bal uh ni,” a ti uh.
18 Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
Te dongah amih kah olka te Hamor mikhmuh ah khaw, Harmor capa Shekhem mikhmuh ah khaw then.
19 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
Tedae cadong loh Jakob canu te a ngaih coeng dongah hno saii ham te uelh pawh. Te dongah anih te a napa imkhui boeih soah a thangpom.
20 Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
Te dongah Hamor neh a capa Shekhem loh amah khopuei vongka la cet tih amah khopuei kah hlang rhoek taengah,
21 Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
Hekah hlang rhoek he mamih neh baerhoep la tolrhum ah khaw khosa uh saeh. Te phoeiah amih kah nongcen rhoeh la khotuk khaw amih ham a dang ka mungkung mai. Mamih kah yuu la amih nu rhoek te lo sih lamtah mah nu te amih pae uh sih.
22 Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
Tedae tongpa boeih loh yahvin a rhet uh vanbangla mamih ah pilnam pakhat la om ham atah ning taengkah aka om tongpa rhoek kah yahhmui a rhet nen bueng he ni mamih te n'rhoi uh eh.
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
Amih kah boiva neh hnopai, rhamsa boeih khaw mamih ham moenih a? Te dongah amih te rhoi uh mai sih lamtah mamih taengah khosa uh saeh,” a ti uh.
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
Te dongah a khopuei kah vongka ah aka cet boeih loh Hamor neh a capa Shekhem te a ngai uh tih tongpa boeih khukah a khopuei vongka aka pha boeih loh yahhmui a rhet uh.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
Tedae hnin thum a lo vaengah amih te a tloh pah. Te dongah Dinah nganpa Simeon neh Levi, Jakob ca rhoi loh cunghang rhirha a muk rhoi tih ngaikhuek la khopuei te a paan rhoi. Te vaengah tongpa boeih te a ngawn rhoi.
26 Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
Hamor neh a capa Shekhem te cunghang ha neh a ngawn rhoi. Dinah te khaw Shekhem im lamloh a lat rhoi tih bal rhoi.
27 Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
A ngannu a poeih pa uh dongah Jakob ca rhoek loh rhok te a paan uh tih khopuei te a poelyoe uh.
28 Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
Amih kah boiva neh saelhung khaw, laak khaw, khopuei khui neh lohma kah te a mawt pa uh.
29 Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
Amih kah tatthai boeih neh a yuu, a ca boeih te a sol pa uh tih im kah aka om boeih te khaw a poelyoe uh.
30 Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
Te dongah Jakob loh Simeon neh Levi taengah, “Khohmuen kah kho aka sa Kanaan neh Perizzi rhoek taengah ka bo nan rhim sak rhoi tih kai nan lawn rhoi coeng. Tahae ah kai hlang sii taengah tingtun uh tih kai he n'ngawn uh koinih kamah neh ka imko loh ka mit uh ni ta he,” a ti nah.
31 Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”
Tedae, “Ka ngannu te pumyoi bangla a saii ham om a?” a ti uh.

< Genesis 34 >