< Genesis 33 >

1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
Jakob je povzdignil svoje oči, pogledal in glej, prišel je Ezav in z njim štiristo mož. Otroke je razdelil Lei in Raheli ter dvema pomočnicama.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
Najbolj spredaj je postavil pomočnici ter njune otroke, za njimi Leo ter njene otroke, nazadnje pa Rahelo in Jožefa.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
Šel je pred njimi in se sedemkrat priklonil do tal, dokler se ni približal svojemu bratu.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
Ezav je stekel, da ga sreča, ga objel, se spustil na njegov vrat in ga poljubil, in oba sta jokala.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
Povzdignil je svoje oči in zagledal ženske in otroke ter rekel: »Kdo so ti s teboj?« Rekel je: »Otroci, ki jih je Bog milostljivo dal tvojemu služabniku.«
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Nato sta se približali pomočnici, oni in njuni otroci ter se priklonili.
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Tudi Lea s svojimi otroki se je približala in se priklonila in potem sta prišla bliže Jožef in Rahela ter se oba priklonila.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
Rekel je: »Kaj nameravaš z vso to čredo, ki sem jo srečal?« On pa je rekel: » Ti so, da najdem milost v očeh mojega gospoda.«
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
Ezav je rekel: »Dovolj imam, moj brat. To, kar imaš, obdrži zase.«
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
Jakob je rekel: »Ne, prosim te, če sem torej našel milost v tvojih očeh, potem sprejmi moje darilo v moji roki, kajti zato sem videl tvoj obraz, kot da sem videl Božje obličje in ti si bil zadovoljen z menoj.
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
Vzemi, prosim te, moj blagoslov, ki je priveden k tebi, ker je Bog milostljivo postopal z menoj in ker imam dovolj.« Prigovarjal mu je in on je to vzel.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
Rekel je: »Naj greva najino potovanje in naj greva, jaz pa bom šel pred teboj.«
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
Rekel mu je: »Moj gospod ve, da so otroci nežni in [da] so z menoj tropi in črede z mladiči in če jih bodo ljudje en dan preveč gonili, bo ves trop poginil.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
Naj moj gospod, prosim te, gre preko pred svojim služabnikom, jaz pa bom mirno vodil dalje, kolikor bodo živina, ki gre pred menoj in otroci zmožni prenesti, dokler ne pridem k mojemu gospodu v Seír.«
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
Ezav je rekel: »Naj torej pustim s teboj nekaj ljudstva, ki je z menoj.« Rekel je: »Kaj potrebujem to? Naj najdem milost v očeh svojega gospoda.«
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
Tako se je ta dan Ezav vrnil na svojo pot v Seír.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
Jakob pa je odpotoval v Sukót, si zgradil hišo in naredil šotore za svojo živino. Zato se ime kraja imenuje Sukót.
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
Ko je Jakob prišel iz Padan–arama, je prišel v Salem, mesto v Sihemu, ki je v kánaanski deželi in svoj šotor postavil pred mestom.
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
Kupil je kos poljskega zemljišča, kjer je razširil svoj šotor, iz roke otrok Hamórja, Sihemovega očeta, za sto koščkov denarja.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
Tam je postavil oltar in ga imenoval El–elohe–Izrael.

< Genesis 33 >