< Genesis 33 >

1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
Şi Iacob şi-a ridicat ochii şi a privit şi, iată, Esau venea şi cu el veneau patru sute de bărbaţi. Şi a împărţit copiii Leei şi Rahelei şi celor două roabe.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
Şi a pus roabele şi copiii lor în frunte şi pe Leea şi copiii ei după şi pe Rahela şi Iosif ultimii.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
Şi a trecut înaintea lor şi s-a aplecat până la pământ de şapte ori, până când a ajuns aproape de fratele său.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
Şi Esau a alergat să îl întâlnească şi l-a îmbrăţişat şi a căzut la gâtul lui şi l-a sărutat şi au plâns.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
Şi el şi-a ridicat ochii şi a văzut femeile şi copiii şi a spus: Cine sunt aceştia împreună cu tine? Iar el a spus: Copiii pe care Dumnezeu i-a dat cu har servitorului tău.
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Atunci roabele s-au apropiat, ele şi copiii lor, şi s-au prosternat;
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Şi Leea de asemenea cu copiii ei s-a apropiat şi s-au prosternat; şi după aceea s-a apropiat Iosif şi Rahela şi s-au prosternat.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
Iar el a spus: Ce doreşti să spui tu cu toată această mulţime pe care am întâlnit-o? Iar el a spus: Acestea sunt pentru a găsi har înaintea ochilor domnului meu.
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
Şi Esau a spus: Eu am destul, fratele meu; ţine ceea ce ai pentru tine.
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
Şi Iacob a spus: Nu, te rog, dacă am găsit acum har înaintea ochilor tăi, atunci primeşte darul meu din mâna mea, căci de aceea am văzut faţa ta, ca şi cum aş fi văzut faţa lui Dumnezeu şi ai fost mulţumit de mine.
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
Ia, te rog, binecuvântarea mea care îţi este adusă, pentru că Dumnezeu m-a tratat cu har şi pentru că am destul. Şi l-a constrâns, iar el l-a luat.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
Şi a spus: Să continuăm călătoria noastră şi să mergem; şi voi merge înaintea ta.
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
Iar el i-a spus: Domnul meu ştie că pruncii sunt plăpânzi şi turmele şi cirezile cu pui sunt cu mine; şi dacă oamenii le vor forţa să meargă repede, toată turma va muri într-o zi.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
Domnul meu să treacă, te rog, înaintea servitorului său şi voi conduce cu blândeţe, după cum vitele care merg înaintea mea şi copiii sunt în stare să îndure, până ce ajung la domnul meu în Seir.
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
Şi Esau a spus: Să las acum cu tine pe unii dintre oamenii care sunt cu mine. Iar el a spus: Ce nevoie este de aceasta? Lasă-mă să găsesc har înaintea ochilor domnului meu.
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
Astfel Esau s-a întors în acea zi pe calea sa în Seir.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
Şi Iacob a călătorit până la Sucot şi şi-a zidit o casă şi a făcut colibe pentru vitele sale, de aceea numele locului este chemat Sucot.
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
Şi Iacob a venit la Salem, o cetate din Sihem, care este în ţara lui Canaan, când a venit de la Padanaram; şi a întins cortul său în faţa cetăţii.
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
Şi a cumpărat o parcelă dintr-un câmp, unde şi-a întins cortul, la îndemâna copiilor lui Hamor, tatăl lui Sihem, pentru o sută de monede.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
Şi a înălţat acolo un altar şi l-a numit Elelohe-Israel.

< Genesis 33 >