< Genesis 33 >
1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
NANA aku la na maka o Iakoba, ike aku la, aia hoi, ua hiki mai o Esau me na haneri kanaka eha. A puunaue aku la ia i na kamalii ia Lea, a ia Rahela, a i na kauwawahine elua.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
Hoonoho aku la ia i na kauwawahine me na keiki a laua mamua, ia Lea hoi me kana mau keiki mahope iho, a ia Rahela me Iosepa mahope loa.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
Hele e aku la ia mamua o lakou; kulou pahiku iho la ia ma ka honua, a hiki aku la ia i kona kaikuaana.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
Holo mai la o Esau e halawai me ia, apo mai la ia ia, kau iho la ma kona a-i, a honi iho la ia ia: a uwe iho la laua.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
Alawa ae la kona mau maka, ike ae i na wahine a me na kamalii; ninau mai la ia, Owai lakou nei me oe? I aku la kela, O lakou no na keiki a ke Akua i haawi lokomaikai mai ai i kau kauwa.
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Alaila neenee mai la na kauwawahine, o laua me na keiki a laua, a kulou iho la lakou.
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Neenee mai la hoi o Lea me kana mau keiki, a kulou iho la lakou: a mahope iho, neenee mai la o Iosepa me Rahela, a kulou iho la laua.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
Ninau mai la kela, Heaha ia oe kela poe nui a pau i halawai me au? I aku la oia, He mea ia e loaa mai ai ke aloha o kuu haku.
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
I mai la kela, He nui no ka'u, e kuu kaikaina, ia oe no kau mea.
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
I aku la o Iakoba, Aole, ke noi aku nei au ia oe, ina i loaa ia'u ke alohaia imua on, e lawe oe i ka'u makana ma ko'u lima: no ka mea, ua ike iho nei au i kou maka, e like me kuu ike ana i ka maka o ke Akua, a ua oluolu mai oe ia'u.
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
Ke noi aku nei au ia oe, e lawe oe i ka'u hoomaikai ana i haawiia ku nau; no ka mea, ua lokomaikai mai ke Akua ia'u, a no ka mea, ua lako hoi au. Koi aku la oia ia ia, a lawe hoi kela.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
I mai la kela, e neenee aku kakou i ko kakou hele ana, a e hele hoi au imua ou.
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
I aku la oia ia ia, Ua ike no kuu haku, he palupalu na kamalii, a me au no na hipa hapai a me na bipi hapai: ina e hoolalelaleia lakou i ka la hookahi, e pau ka ohana holoholona i ka make.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
Ke noi aku nei au ia oe, e hele e aku kuu haku mamua o kana kauwa ma kela kapa; a na'u no e hele malie aku, e like me ka hiki ana o na holoholona a me na kamalii ke hele imua o'u, a hiki aku au i kuu haku ma Seira.
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
I mai la o Esau, E pono paha na'u e waiho me oe i kekahi poe kanaka o'u. I aku la ia, No ke aha hoi ia? ina e loaa ia'u ke alohaia imua o kuu haku.
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
A hoi hou aku la o Esau ia la i kona hele ana i Seira.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
Hele aku la o Iakoba i Sukota, a kukulu ia i hale nona, a hana iho la i hale kamala no kona poe holoholona: nolaila, i kapaia'i ka inoa o ia wahi, o i Sukota.
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
Hele pomaikai aku la o Iakoba i kekahi kulanakauhale o Sekema, ma ka aina o Kanaana ia ia i hoi mai ai mai Padanarama mai, a kukulu iho la ia i kona halelewa imua o ua kulanakauhale la.
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
Kuai aku la ia i kauwahi o ka aina, kahi ana i kukulu ai i kona halelewa, ma ka lima o na keiki a Hamora a ka makuakane o Sekema, i na apana kala he haneri.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
Malaila oia i hana'i i kuahu, a kapa iho la i kona inoa, o Elelohe-Iseraela.