< Genesis 32 >

1 Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
Jakub też poszedł swoją drogą i spotkali go aniołowie Boga.
2 Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
Gdy Jakub ich ujrzał, powiedział: To obóz Boga. I nadał temu miejscu nazwę Machanaim.
3 Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
Potem Jakub wysłał przed sobą posłańców do swego brata Ezawa, do ziemi Seir, do krainy Edomu.
4 Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
I rozkazał im: Tak powiecie do mego pana Ezawa: To mówi twój sługa Jakub: Byłem gościem u Labana i przebywałem z nim aż do tego czasu.
5 Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
Mam woły, osły i owce, służących i służące, a posyłam oznajmić to memu panu, żebym znalazł łaskę w twoich oczach.
6 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
Posłańcy wrócili do Jakuba i mówili: Przyszliśmy do twego brata Ezawa, a on też idzie naprzeciwko ciebie, a z nim czterystu mężów.
7 Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Jakub bardzo się przestraszył i ogarnęła go trwoga. Podzielił więc lud, który z nim [był], oraz owce, woły i wielbłądy na dwa obozy.
8 Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
I powiedział: Jeśli Ezaw przyjdzie do jednego obozu i uderzy na niego, to drugi obóz ocaleje.
9 Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
Potem Jakub powiedział: Boże mego ojca Abrahama i Boże mego ojca Izaaka, PANIE, który do mnie powiedziałeś: Wróć do twojej ziemi i do twojej rodziny, a będę ci wyświadczał dobro.
10 èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
Nie jestem godzien wszelkiego miłosierdzia i całej wierności, które okazałeś swemu słudze. Bo tylko o lasce przeszedłem ten Jordan, a teraz mam dwa obozy.
11 Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
Wyrwij mnie, proszę, z ręki mego brata, z ręki Ezawa, bo się go boję, że przyjdzie i zabije mnie [i] matki z dziećmi.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
Ty bowiem powiedziałeś: Na pewno będę ci wyświadczał dobro i rozmnożę twoje potomstwo jak piasek morski, który nie może być zliczony z powodu jego mnóstwa.
13 Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
I przenocował tam tej nocy, i wziął z tego, co miał pod ręką, dar dla swego brata Ezawa;
14 Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
Dwieście kóz i dwadzieścia kozłów, dwieście owiec i dwadzieścia baranów;
15 ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
Trzydzieści karmiących wielbłądzic z młodymi, czterdzieści krów i dziesięć wołów, dwadzieścia oślic i dziesięcioro ośląt.
16 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
I oddał [je] w ręce swoich sług, każde stado oddzielnie, i powiedział do swoich sług: Idźcie przede mną i zachowajcie odstęp między stadami.
17 Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
I rozkazał pierwszemu: Gdy spotka cię mój brat Ezaw, a spyta cię: Czyj jesteś? I dokąd idziesz? A czyje to [stado] przed tobą?
18 nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
Wtedy odpowiesz: To jest dar od twego sługi Jakuba, posłany memu panu Ezawowi. A oto on sam [idzie] za nami.
19 Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
Tak też rozkazał drugiemu i trzeciemu, i wszystkim idącym za tymi stadami: Tymi słowy mówcie do Ezawa, gdy go spotkacie.
20 Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
Powiecie [mu] też: Oto twój sługa Jakub [idzie] za nami. Myślał bowiem: Przebłagam go darem, który idzie przede mną, a potem zobaczę jego oblicze. Może mnie przyjmie łaskawie.
21 Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
I poszedł przed nim ten dar, a sam przenocował tej nocy ze [swoim] obozem.
22 Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
Wstał tej nocy, wziął obie swe żony i dwie swoje służebnice oraz jedenastu swoich synów i przeszedł przez bród Jabboku.
23 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
I wziął ich, przeprawił przez tę rzekę i przeprowadził [wszystko], co miał.
24 Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
Jakub zaś został sam. I walczył z nim [pewien] mężczyzna aż do wzejścia zorzy.
25 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
A widząc, że nie może go pokonać, dotknął go w staw biodrowy i wytrącił biodro Jakubowi ze stawu, gdy się z nim mocował.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
I powiedział: Puść mnie, bo już wzeszła zorza. Odpowiedział: Nie puszczę cię, aż mi pobłogosławisz.
27 Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
Wtedy mu powiedział: Jakie jest twoje imię? I odpowiedział: Jakub.
28 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
I powiedział: Twoim imieniem nie będzie już Jakub, ale Izrael, bo mężnie zmagałeś się z Bogiem i z ludźmi i zwyciężyłeś.
29 Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
I Jakub spytał: Powiedz mi, proszę, twoje imię. A on odpowiedział: Czemu pytasz o moje imię? I tam mu błogosławił.
30 Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
Jakub nadał więc temu miejscu nazwę Penuel, [mówiąc]: Widziałem bowiem Boga twarzą w twarz, a moja dusza została zachowana.
31 Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
I kiedy minął [miejsce] Penuel, wzeszło słońce, a on utykał z powodu swojego biodra.
32 Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.
Dlatego do dziś synowie Izraela nie jadają ścięgna, które jest w stawie biodrowym, gdyż dotknął Jakuba w staw biodrowy, w ścięgno, które się skurczyło.

< Genesis 32 >