< Genesis 32 >

1 Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
Na haere ana a Hakopa i tona huarahi, a ka tutaki ki a ia nga anahera a te Atua.
2 Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
A ka mea a Hakopa i tona kitenga i a ratou, Ko te ope tenei a te Atua: na huaina iho e ia te ingoa o tena wahi ko Mahanaima.
3 Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
Na ka tono tangata atu a Hakopa ki mua i a ia ki a Ehau, ki tona tuakana, ki te whenua o Heira, ki te whenua o Eroma.
4 Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
Ka ako hoki ia ki a ratou, ka mea, Kia penei he korero atu ma koutou ki toku ariki, ki a Ehau; E penei ana te kupu a tau pononga, a Hakopa, I a Rapana ahau e noho ana a tae mai ki tenei wa;
5 Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
He kau ano aku, he kaihe, he hipi, he pononga tane, he pononga wahine: a kua tono tangata nei ahau ki te korero ki toku ariki, kia manakohia ai ahau e koe.
6 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
Na ka hoki mai nga karere ki a Hakopa, ka mea, I tae atu matou ki tou tuakana, ki a Ehau, a tenei ano ia te haere mai nei ki te whakatau i a koe, ratou tahi ko nga tangata e wha rau.
7 Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Na he nui te wehi o Hakopa, ka manukanuka; na ka wehea e ia ona tangata, me nga hipi, me nga kau, me nga kamera, kia rua nga ropu;
8 Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
I mea hoki ia, Ki te tae mai a Ehau ki te ropu tuatahi, a ka patua e ia, na, ka mawhiti te ropu i mahue.
9 Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
Na ka mea a Hakopa, E te Atua o toku papa, o Aperahama, e te Atua o toku papa, o Ihaka, e Ihowa, nau nei te kupu ki ahau, Hoki atu ki tou whenua, ki ou whanaunga hoki, a ka pai taku mahi ki a koe:
10 èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
He iti rawa ahau, he nui au arohatanga katoa, me te pono katoa hoki i whakaputaina mai e koe ki tau pononga; i whiti mai hoki ahau me toku tokotoko i tenei Horano; a ka rua nei oku ropu.
11 Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
Tena ra, whakaorangia ahau i te ringa o toku tuakana, i te ringa o Ehau; e wehi ana hoki ahau i a ia, kei haere mai ia ki te patu i ahau, i te whaea ratou tahi ko nga tamariki.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
I mea mai nei hoki koe, Ina, ka pai taku mahi ki a koe, a ka meinga e ahau ou uri kia rite ki te onepu o te moana, e kore nei e taea te tatau i te tini.
13 Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
A i moe ia ki reira i taua po; a i tangohia e ia i roto i nga mea i pono ki tona ringa he hakari ma Ehau, ma tona tuakana;
14 Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
E rua rau nga koati hua, e rua tekau hoki nga koati toa, e rua rau nga hipi uha, e rua tekau nga hipi toa,
15 ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
E toru tekau nga kamera whai waiu, me a ratou kuao, e wha tekau nga kau, kotahi tekau hoki nga puru, e rua tekau nga kaihe uha, me nga kuao hoki kotahi tekau.
16 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
A ka hoatu e ia ki nga ringa o ana pononga tenei kahui, tenei kahui, motumotu rawa; ka mea ia ki ana pononga, Haere i mua i ahau, kia whai takiwa tetahi kahui, tetahi kahui.
17 Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
I ako ano ia i te tuatahi, i mea, E tutaki a Ehau, toku tuakana, i a koe, e mea, Na wai koe? a e haere ana koe ki hea? a na wai enei mea i tou aroaro?
18 nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
Na ka mea atu koe, Na tau pononga, na Hakopa; i homai e ia hei hakari ma toku ariki, ma Ehau; a tenei ano hoki ia kei muri i a matou.
19 Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
He pera ano tana ako ki te tuarua, ki te tuatoru hoki, ki nga tangata katoa ano hoki i haere i muri i nga kahui, i mea ia, Ko te tikanga tenei mo nga kupu e korero ai koutou ki a Ehau, ina tutaki ki a ia;
20 Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
A me ki atu e koutou, Na, tenei ano hoki tau pononga, a Hakopa, kei muri i a matou. I mea hoki ia, Me whakamarie ia e ahau ki te hakari e haere ana i mua i ahau, a, muri iho ka kite ahau i tona kanohi; tera pea ia e manako ki ahau.
21 Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
Na ka haere atu te hakari i mua i a ia: a ko ia i moe i taua po i te puni.
22 Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
A i whakatika ia i taua po, i tango hoki i ana wahine tokorua, me ana wahine pononga tokorua, me ana tamariki tekau ma tahi, a ka whiti i te whitinga i Iapoko.
23 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
A i tango ia i a ratou, i mea hoki kia whiti i te awa, a i tukuna atu e ia kia whiti nga mea i a ia.
24 Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
A i mahue iho a Hakopa ko ia anake; a nonoke ana raua ko tetahi tangata, a takiri noa te ata.
25 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
A, no te kitenga o tera kihai ia i taea e ia, ka pa ia ki te ateatenga o tona huha; a ka takoki te ateatenga o te huha o Hakopa i a raua e nonoke ana.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
Na ka mea ia, Tukua ahau, kua takiri hoki te ata. A ka mea ia, E kore koe e tukua e ahau, kia manaakitia ra ano ahau e koe.
27 Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
A ka mea ia, Ko wai tou ingoa? A ka mea ia, Ko Hakopa.
28 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
A ka mea ia, Heoi ano kianga ko Hakopa tou ingoa, engari ko Iharaira: no te mea kua tohe koe ki te Atua, ki te tangata hoki, a i a koe ano te mutunga.
29 Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
Na ka ui a Hakopa, ka mea, Tena koa, korerotia mai tou ingoa. Ano ra ko ia, He aha toku ingoa i uia ai e koe? a ka manaaki ia i a ia i reira.
30 Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
Na huaina ana e Hakopa te ingoa o taua wahi ko Peniere: i mea hoki ia, Moku i titiro ki te Atua, he kanohi, he kanohi, a kei te ora nei ahau.
31 Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
A i tara mai te ra ki a ia i a ia ka whiti i Penuere, kei te toitoti ano tona huha.
32 Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.
Koia nga tama a Iharaira te kai ai i te uaua i memenge, ara i tera i te ateatenga o te huha, a tae noa ki tenei ra: no te mea hoki i pa ia ki te ateatenga o te huha o Hakopa, ki te uaua i memenge.

< Genesis 32 >