< Genesis 32 >

1 Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
Et Jacob continua son chemin, et des anges de Dieu le rencontrèrent.
2 Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
Et Jacob dit, quand il les eut vus: C'est le camp de Dieu! Et il appela ce lieu-là, Mahanaïm (les deux camps).
3 Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
Et Jacob envoya des messagers devant lui vers Ésaü, son frère, au pays de Séir, aux champs d'Édom.
4 Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
Et il leur commanda en disant: Vous parlerez ainsi à Ésaü mon seigneur: Ainsi a dit ton serviteur Jacob: J'ai séjourné chez Laban, et j'y ai demeuré jusqu'à présent.
5 Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
Et j'ai des bœufs et des ânes, des brebis, des serviteurs et des servantes; et j'envoie l'annoncer à mon seigneur, afin de trouver grâce devant tes yeux.
6 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
Et les messagers revinrent auprès de Jacob, en disant: Nous sommes allés vers ton frère Ésaü; et il marche aussi à ta rencontre, avec quatre cents hommes.
7 Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Alors Jacob fut très effrayé et rempli d'angoisse; et il partagea le peuple qui était avec lui, et les brebis, et les bœufs, et les chameaux, en deux camps, et il dit:
8 Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
Si Ésaü attaque l'un des camps et le frappe, le camp qui restera, pourra échapper.
9 Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
Puis Jacob dit: Dieu de mon père Abraham, et Dieu de mon père Isaac! Éternel, qui m'as dit: Retourne en ton pays, et vers ta parenté, et je te ferai du bien;
10 èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
Je suis trop petit pour toutes les faveurs et pour toute la fidélité dont tu as usé envers ton serviteur; car j'ai passé le Jourdain avec mon bâton, et maintenant je forme deux camps.
11 Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
Délivre-moi, je te prie, de la main de mon frère, de la main d'Ésaü; car je crains qu'il ne vienne, et qu'il ne me frappe, et la mère avec les enfants.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
Cependant, tu as dit: Certaine-ment, je te ferai du bien, et je ferai devenir ta postérité comme le sable de la mer, qu'on ne saurait compter à cause de son grand nombre.
13 Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
Et il passa la nuit en ce lieu-là, et il prit de ce qui lui vint en la main, pour en faire un présent à Ésaü, son frère
14 Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
Deux cents chèvres et vingt boucs, deux cents brebis et vingt béliers,
15 ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
Trente chamelles qui allaitaient, avec leurs petits, quarante vaches et dix taureaux, vingt ânesses et dix jeunes ânes.
16 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
Et il mit entre les mains de ses serviteurs chaque troupeau à part, et dit à ses serviteurs: Passez devant moi, et mettez de la distance entre un troupeau et l'autre.
17 Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
Et il donna ordre au premier, en disant: Quand Ésaü mon frère, te rencontrera, et te demandera: A qui es-tu, où vas-tu, et à qui sont ces bêtes devant toi?
18 nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
Tu diras: A ton serviteur Jacob; c'est un présent qu'il envoie à Ésaü mon seigneur; et le voici qui vient lui-même après nous.
19 Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
Il donna le même ordre au second, et au troisième, et à tous ceux qui allaient après les troupeaux, en disant: Vous tiendrez ce langage à Ésaü, quand vous le rencontrerez;
20 Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
Et vous direz: Voici même ton serviteur Jacob qui vient derrière nous. Car il se disait: Je l'apaiserai par ce présent qui va devant moi, et après cela, je verrai sa face; peut-être qu'il m'accueillera favorablement.
21 Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
Le présent marcha donc devant lui; mais lui, il passa cette nuit-là dans le camp.
22 Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
Et il se leva cette nuit, prit ses deux femmes, et ses deux servantes, et ses onze enfants, et passa le gué de Jabbok.
23 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
Il les prit donc, et leur fit passer le torrent. Il fit aussi passer ce qu'il avait.
24 Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
Or Jacob demeura seul; et un homme lutta avec lui, jusqu'au lever de l'aurore.
25 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
Et quand cet homme vit qu'il ne pouvait le vaincre, il toucha l'emboîture de sa hanche; et l'emboîture de la hanche de Jacob fut démise, pendant qu'il luttait avec lui.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
Et cet homme lui dit: Laisse-moi aller, car l'aurore est levée. Mais il dit: Je ne te laisserai point aller, que tu ne m'aies béni.
27 Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
Et il lui dit: Quel est ton nom? et il répondit: Jacob.
28 Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
Alors il dit: Ton nom ne sera plus Jacob, mais Israël (qui lutte avec Dieu); car tu as lutté avec Dieu et avec les hommes, et tu as vaincu.
29 Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
Et Jacob l'interrogea, et dit: Apprends-moi ton nom, je te prie. Et il répondit: Pourquoi demandes-tu mon nom? Et il le bénit là.
30 Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
Et Jacob nomma le lieu, Péniel (face de Dieu); car, dit-il, j'ai vu Dieu face à face et mon âme a été délivrée.
31 Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
Et le soleil se leva pour lui, dés qu'il eut passé Péniel; et il boitait de la hanche.
32 Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.
C'est pourquoi, jusqu'à ce jour, les enfants d'Israël ne mangent point le muscle de la cuisse, qui est à l'emboîture de la hanche, parce que cet homme toucha l'emboîture de la hanche de Jacob, au muscle de la cuisse.

< Genesis 32 >