< Genesis 31 >
1 Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
És meghallá a Lábán fiainak beszédét, kik ezt mondják vala: Valamije volt atyánknak, mind elvette Jákób; és atyánkéból szerezte mind e gazdagságot.
2 Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
És látá Jákób a Lábán orczáját, hogy ímé nem olyan ő hozzá mint annakelőtte.
3 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Monda pedig az Úr Jákóbnak: Térj meg atyáid földére, a te rokonságod közé, és veled lészek.
4 Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
Elkülde tehát Jákób, és kihívatá magához Rákhelt és Leát a mezőre az ő nyájához.
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
És monda nékik: Látom atyátok orczáját, hogy nem olyan hozzám, mint ennekelőtte; de az én atyám Istene velem volt.
6 Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
Ti pedig tudjátok, hogy teljes erőm szerint szolgáltam atyátokat.
7 síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
De atyátok engem megcsalt s tízszer is megváltoztatta béremet; mindazáltal az Isten nem engedte, hogy nékem kárt tehessen.
8 Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
Mikor azt mondotta: A pettyegetettek legyenek a te béred, a juhok mind pettyegetetteket ellenek vala. Ha azt mondotta: A csíkos lábúak legyenek a te béred, a juhok mind csíkos lábúakat ellenek vala.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
Így vette el Isten atyátok jószágát és nékem adta.
10 “Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
Mert lőn a juhok foganásának idejekor, szemeimet felemelém, és látom vala álomban, hogy ímé a juhokat hágó kosok csíkos lábúak, pettyegetettek és tarkák.
11 Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
Akkor monda nékem az Isten Angyala álomban: Jákób. És felelék: Ímhol vagyok.
12 Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
És ő monda: Emeld fel szemeidet és lásd, hogy a mely kosok a juhokat hágják, azok mind csíkos lábúak, pettyegetettek és tarkák. Mert mindazt láttam, a mit veled Lábán cselekeszik vala.
13 Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
Én vagyok ama Béthelnek Istene, a hol emlékoszlopot kentél fel, és a hol fogadást tettél nékem. Most kelj fel, menj ki e földről, és térj vissza szülőföldedre.
14 Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
És felele Rákhel és Lea, és mondának néki: Vajjon vagyon-é még nékünk valami részünk és örökségünk a mi atyánk házában?
15 Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
Avagy nem úgy tartott-é minket mint idegeneket? midőn minket eladott, és értékünket is teljesen megemésztette.
16 Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
Mert mind ez a gazdagság, melyet Isten vett el a mi atyánktól, miénk és a mi fiainké. Most azért valamit néked az Isten mondott, azt cselekedjed.
17 Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
Felkele tehát Jákób, és feltevé gyermekeit és feleségeit a tevékre;
18 Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
És elvivé minden nyáját, és minden keresményét, melyet keresett vala; minden jószágát, melyet szerzett vala Mésopotámiában, hogy elmenjen az ő atyjához Izsákhoz Kanaán földére.
19 Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
Lábán pedig elment vala juhait nyírni; azonközben ellopá Rákhel a házi bálványokat, melyek atyjánál valának.
20 Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
Jákób pedig meglopá a Siriabeli Lábánnak szívét, mivelhogy nem adá tudtára, hogy szökni akar.
21 Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
Megszökék tehát mindenestől, és felkelvén, általméne a folyóvízen, és Gileád hegye felé tarta.
22 Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
És mikor harmad napra megmondák Lábánnak, hogy Jákób elszökött;
23 Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
Maga mellé vévén az ő rokonait, hét napi járó földig űzé őket; és eléré a Gileád hegyén.
24 Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
Isten pedig megjelenék a Siriabeli Lábánnak éjjel álomban, és monda néki: Vigyázz magadra, Jákóbnak se jót, se rosszat ne szólj.
25 Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
Mikor eléré Lábán Jákóbot, s Jákób a hegyen voná fel sátorát; Lábán is a Gileád hegyén voná fel az ő rokonaival egybe.
26 Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
És monda Lábán Jákóbnak: Mit cselekedtél, hogy megloptad szívemet, és leányaimat fegyverrel nyert foglyokként vitted el?
27 Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
Miért futottál el titkon, s loptál meg engem? miért nem jelentetted nékem, hogy elbocsátottalak volna örömmel, énekszóval, dob- és hegedűszóval?
28 Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
És nem engedted meg, hogy megcsókoljam fiaimat és leányaimat. Ez egyszer bolondul cselekedtél.
29 Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
Volna erőm hozzá, hogy rosszat tegyek veletek, de a ti atyátok Istene tegnap éjszaka megszólíta engem, ezt mondván: Vigyázz magadra, Jákóbnak se jót, se rosszat ne szólj.
30 Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
Hogyha pedig immár el akartál menni, mivelhogy nagy kívánsággal kívánkoztál atyád házához: miért loptad el az én isteneimet?
31 Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
Felelvén pedig Jákób, monda Lábánnak: Mert féltem, mert gondolom vala, hogy talán elveszed a te leányaidat én tőlem erővel.
32 Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
A kinél pedig megtalálod a te isteneidet, ne éljen az. Atyánkfiai előtt vizsgáld meg, mid van nálam, és vidd el. Mert nem tudja vala Jákób, hogy Rákhel lopta el azokat.
33 Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
Beméne tehát Lábán Jákób sátorába, és Lea sátorába, és a két szolgáló sátorába, és nem találá meg; akkor kiméne Lea sátorából, és méne a Rákhel sátorába.
34 Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
Rákhel pedig vette vala a házi bálványokat, és tette vala azokat egy tevének a nyergébe, és rájok űle; Lábán pedig felhányá az egész sátort, és nem találta vala meg azokat.
35 Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
Akkor monda az ő atyjának: Ne haragudjék az én uram, hogy fel nem kelhetek előtted, mert asszonyok baja van rajtam. Keresé tehát, de nem találá a házi bálványokat.
36 Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
Jákób pedig haragra gerjede s feddődék Lábánnal. Megszólala Jákób és monda Lábánnak: Mi a vétkem, és mi a bűnöm, hogy üldözőbe vettél?
37 Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
Bezzeg minden holmimat felhánytad, mit találtál a magad házi holmija közűl valót? add elő itt az én rokonaim és a te rokonaid előtt, hogy tegyenek ítéletet kettőnk között.
38 “Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
Immár húsz esztendeje vagyok nálad, juhaid és kecskéid nem vetéltek el, és nyájad kosait nem ettem meg.
39 Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
A mit a vad megszaggatott, nem vittem hozzád, én fizettem meg azt; tőlem követelted a nappal lopottat, mint az éjjel lopottat is.
40 Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
Úgy voltam hogy nappal a hőség emésztett, éjjel pedig a hideg; és az álom távol maradt szemeimtől.
41 Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
Immár húsz esztendeje hogy házadnál vagyok; tizennégy esztendeig szolgáltalak két leányodért, és hat esztendeig juhaidért; te pedig béremet tízszer is megváltoztattad.
42 Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
Ha az én atyám Istene, Ábrahám Istene, és az Izsák félelme velem nem volt volna, bizony most üresen bocsátanál el engem, de megtekintette Isten az én nyomorúságomat és kezeim munkáját, és megfeddett téged tegnap éjjel.
43 Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
Felele pedig Lábán és monda Jákóbnak: A leányok én leányaim és a fiak én fiaim, és a nyáj az én nyájam, s valamit látsz mind az enyim, de mit tehetek ma ezeknek az én leányaimnak, vagy az ő magzatjaiknak, a kiket szűltek?
44 Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
Most tehát jer, kössünk szövetséget, én meg te, hogy az légyen bizonyságul közöttem és közötted.
45 Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
És vőn Jákób egy követ, és felemelé azt emlékoszlopul.
46 Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
És monda Jákób az ő atyjafiainak: Szedjetek köveket! És gyűjtének köveket, és csinálának rakást; és evének ott a rakáson.
47 Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
És nevezé azt Lábán Jegár-Sahaduthának, Jákób pedig nevezé Gálhédnek.
48 Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
És mondja vala Lábán: E rakás bizonyság ma, közöttem és közötted, azért nevezék Gálhédnek.
49 Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
És Miczpának, mivelhogy mondá: Az Úr legyen vigyázó közöttem és te közötted, a mikor egymástól elválunk.
50 Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
Ha az én leányaimat nyomorgatándod, és ha az én leányaimon kivűl több feleséget veéndesz, senki sincs ugyan velünk; de meglásd: Isten a bizonyság én közöttem és te közötted.
51 Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
És monda Lábán Jákóbnak: Ímé e rakás kő és ímé ez emlékoszlop, a melyet raktam én közöttem és te közötted,
52 yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
Bizonyság legyen e rakás kő, és bizonyság ez az emlékoszlop, hogy sem én nem megyek el e rakás kő mellett te hozzád, sem te nem jössz át én hozzám e rakás kő, és ez emlékoszlop mellett gonosz végre.
53 Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
Az Ábrahám Istene, és a Nákhor Istene, és az ő atyjok Istene tegyenek ítéletet közöttünk: És megesküvék Jákób az ő atyjának Izsáknak félelmére.
54 Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
Akkor Jákób áldozatot öle ott a hegyen, és vendégségbe hívá az ő rokonait. És vendégeskedtek vala, s meghálának a hegyen.
55 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.
Reggel pedig felkele Lábán és megcsókolá fiait és leányait és megáldá őket. Azután elméne Lábán, és visszatére az ő helyére.