< Genesis 31 >
1 Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
LOHE aku la o Iakoba i na olelo a na keikikane a Labana, i ka i ana ae, Ua lawe aku la o Iakoba i na mea a pau a ko kakou makuakane, a ua loaa ia ia keia waiwai a pau no na mea a ko kakou makuakane.
2 Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
Nana aku la o Iakoba i ka maka o Labana, aole ia i maliu mai ia ia e like mamua.
3 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Olelo mai la hoi o Iehova ia Iakoba, E hoi hou aku oe i ka aina o kou poe makua, a i na hoahanau ou; a owau kekahi pu me oe.
4 Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
Hoouna aku la o Iakoba e kahea ia Rahela laua o Lea e hele mai ma ke kula i kona poe holoholona.
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
I aku la oia ia laua, Ua ike no wau i ka maka o ko olua makuakane, aole ia i maliu mai ia'u e like mamua: aka, me au no ke Akua o ko'u makuakane.
6 Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
Ua ike hoi olua i ko'u malama i ana i ko olua makuakane me ko'u ikaika a pau.
7 síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
A ua hoopunipuni mai ko olua makuakane ia'u, a he umi kana hoololi ana i ka'u uku: aka, aole ke Akua i ae mai e hoopoino mai ia ia'u.
8 Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
Ina i olelo mai kela penei, O na mea kikokiko kau uku, alaila hanau mai la na holoholona i na mea kikokiko: a i olelo mai ia penei, O na mea onionio kau uku, alaila hanau mai la na holoholona a pau i na mea onionio.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
Pela ke Akua i lawe ai i na holoholona a ko olua makuakane, a ua haawi mai ia'u.
10 “Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
A i ka manawa a ka poe holoholona i ko ai, nana aku la ko'u mau maka ma ka moeuhane, ike aku la, aia hoi, o na kao kane i lele aku maluna o na kao wahine ua onionio, a ua kikokiko, a me ke kikohukohu.
11 Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
Olelo mai la ka anela o ke Akua ia'u ma ka moeuhane, E Iakoba: i aku la au, Eia wau.
12 Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
I mai la kela, E nana aku oe e ike, o na kao kane e lele ana maluna o na kao wahine, ua onionio, ua kikokiko, a me ke kikohukohu: no ka mea, ua ike no wau i ka mea a pau a Labana i hana mai ai ia oe.
13 Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
Owau no ke Akua no Betela, kahi au i poni ai i ka pohaku kukulu, kahi hoi au i hoohiki ai i ka hoohiki ia'u: ano hoi, e ku ae oe, e haalele aku i keia aina, a e hoi hou aku i ka aina o kou poe hoahanau.
14 Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
Olelo mai la o Rahela laua o Lea, i mai la ia ia, Auhea kekahi kuleana, a o kekahi waiwai hooili no maua ma ka hale o ko maua makuakane?
15 Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
Aole anei i manaoia maua e ia, he mau mea e? no ka mea, ua lilo maua i ke kuaiia e ia, a ua pau loa hoi ko maua kala ia ia.
16 Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
Nolaila, o ka waiwai a pau a ke Akua i lawe ae mai ko maua makuakane mai, no kakou ia a no na keiki a kakou: ano hoi, e hana aku oe i ka mea a ke Akua i olelo mai ai ia oe.
17 Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
Alaila, ku ae la o Iakoba, hoee aku la i kana mau keiki a me kana mau wahine maluna o na kamelo;
18 Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
A lawe aku la ia i kana poe holoholona a pau, a me kona waiwai a pau i loaa ia ia, o na holoholona ana, i loaa ia ia ma Padanarama, e hele aku ai io Isaaka la i kona makuakane, ma ka aina o Kanaana.
19 Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
Ua hala aku la o Labana e ako i kana poe hipa: a aihue iho la o Rahela i na kii o kona makuakane.
20 Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
Puni aku la ka naau o Labana ka Suria, ia Iakoba, i ka hai ole aku ia ia i kona mahuka ana.
21 Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
Pela oia i mahuka ai me kana mau mea a pau: ku ae la ia, hele mai la ma keia aoao o ka muliwai, a hele pololei mai la i ka mauna o Gileada.
22 Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
I ke kolu o ka la, olelo aku la kekahi ia Labana, Ua mahuka aku o Iakoba.
23 Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
Kono aku la ia i kona poe hoahanau e hele pa me ia, alualu mai mahope ona i na la hele ehiku, a hiki mai la io Iakoba la ma ka mauna o Gileada.
24 Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
Hele mai la ke Akua io Labana la ka Suria ma ka moeuhane i ka po, i mai la ia ia, E ao ia oe iho, mai olelo aku oe ia Iakoba i ka mea aloha, aole hoi ka mea hoino.
25 Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
Alaila loaa mai la o Iakoba ia Labana. Ua kukulu o Iakoba i kona halelewa ma ua mauna la: kukulu hoi o Labana me kona poe hoahanau ma ka mauna o Gileada.
26 Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
Olelo mai la o Labana ia Iakoba, Heaha kau i hana'i i hoopunipuni mai ai oe ia'u, a i lawe aku ai hoi i ka'u mau kaikamahine, e like me na pio e ke kana?
27 Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
No ke aha la oe i holo malu mai ai, me ka puni mai ia'u, aole hoi i hai mai ia'u, i hoihoi aku ai au ia oe me ka olioli a me na mele, me na pahukani a me na lira!
28 Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
Aole hoi i ae mai oe ia'u e honi i ka'u mau moopuna a me na kaikamahine a'u? He lapuwale ka hana ana au i hana'i.
29 Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
E hiki no i kuu lima ke hana aku ia oe i ke ino: aka, o ke Akua o kou makuakane i olelo mai ia'u, i ka po nei, i ka i ana, E ao oe, mai olelo aku oe ia Iakoba i ka mea aloha, aole hoi ka mea hoino.
30 Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
Ano hoi, i ka hele ana ua hala aku la oe, no kou iini nui ana i ka hale o kou makuakane; no ke aha hoi oe i aihue ai i ko'u mau akua?
31 Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
Olelo aku la o Iakoba ia Labana, i aku la, No ka mea, ua makau wau: i iho la au, E kaili aku paha oe i kau mau kaikamahine mai o'u aku nei.
32 Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
A o ka mea e loaa ia oe, ia ia kou mau akua, aole ia e ola; imua o ko kana mau hoahanau e nana oe i kau maanei me au, a e lawe aku oe i ou la. No ka mea, aole i ike o Iakoba, na Rahela i aihue ia mau mea.
33 Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
Komo aku la o Labana iloko o ka halelewa o Iakoba, a iloko o ka halelewa o Lea, iloko hoi o na halelewa o na kauwawahine elua, aole i loaa. Alaila, hele aku la ia iwaho o ka halelewa o Lea, a komo aku la iloko o ka halelewa o Rahela.
34 Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
Ua lawe aku no o Rahela i ua mau kii la, a waiho pu iho la me na noho kamelo, a noho iho la maluna. Huli iho la o Labana i ka halelewa a pau, aole nae i loaa.
35 Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
I aku la o Rahela i kona makuakane, mai huhu mai ko'u haku i kuu hiki ole ke ku ae iluna; no ka mea, he mai wahine ko'u. Imi iho la oia, aole nae i loaa ia ia na kii.
36 Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
Ukiuki iho la o Iakoba, a ao aku la ia Labana: olelo aku la o Iakoba, i aku la ia Labana, Heaha ko'u hala? heaha hoi ko'u hewa, i alualu wela mai ai oe ia'o?
37 Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
A ua huli iho oe i ka'u ukana a pau, a heaha kau i loaa ai o na mea a pau o kou hale? e kau mai ianei imua o ko'u mau hoahanau a me kou mau hoahanau, i hooponopono mai ai lakou iwaena o kaua.
38 “Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
He iwakalua na makahiki a'u i noho ai me oe; o kau poe hipa wahine a me kau poe kao wahine, aole lakou i hanau i ka wa, aole hoi au i ai i na hipa kane o kou poe holoholona.
39 Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
O na mea i haehaeia, aole au i lawe aku ion la; na'u no i uku aku: nau i lawe aku ia mea mai kuu lima aku, no ka mea i aihueia i ke ao, a i aihueia i ka po.
40 Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
Pela wau; i ke ao, ua wela au i ka la, a i ka po, ua make i ke anu: a holo aku la ka hiamoe mai o'u mau maka aku.
41 Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
Pela wau i na makahiki he iwakalua maloko o kou hale; hooikaika au nau i na makahiki he umikumamaha no kau mau kaikamahine, a me na makahiki eono no kou poe holoholona: a he umi kau hoololi ana i ka'u uku.
42 Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
Ina aole me au ke Akua o ko'u knpunakane, ke Akua o Aberahama, a o ka makau o Isaaka, he oiaio, ina ua hoihoi nele mai oe ia'u i neia manawa. Ua ike mai no ke Akua i ko'u popilikia, a me ka hana ana a ko u mau lima, a ua papa mai ia oe i ka po nei.
43 Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
Olelo mai la o Labana ia Iakoba, i mai la, Na'u no keia mau kaikamahine, a na'u no keia mau kamalii, a na'u no hoi keia poe holoholona, a na'u no na mea a pau au e ike nei; a heaha ka'u mea e hiki ai i keia la ke hana aku i keia mau kaikamahine a'u, a me keia mau kamalii a lakou i hanau ai?
44 Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
Nolaila ea, e hoopaa kaua i berita, owau a o oe, i mea hoikeike mawaena o kaua.
45 Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
Lalau aku la o Iakoba i ka pohaku, a hooku ae la ia mea i kukulu.
46 Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
I aku la hoi o Iakoba i kona poe hoahanau, E houluulu mai oukou i na pohaku; lawe mai la lakou i na pohaku, a hana iho la i ahu; a ai iho la lakou maluna o ua ahu la.
47 Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
Kapa iho la o Labana ia ahu, o I Iegasaduha: kapa iho ia o Iakoba ia mea, o I Galeeda.
48 Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
Olelo mai la o Labana, He mea hoikeike keia ahu pohaku mawaena o kaua i keia la. Nolaila i kapaia'i kona inoa o Galeeda.
49 Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
A o I Mizepa hoi; no ka mea, i mai la ia, O Iehova ke kiai mai mawaena o kaua, i ko kaua manawa e noho kaawale ana.
50 Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
Ina oe e hoopilikia i ka'u mau kaikamahine ina hoi oe e lawe i na wahine hou, he okoa keia mau kaikamahine a'u, aohe kanaka me kaua; e ao oe, o ke Akua no ke ike maka mai mawaena o kaua.
51 Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
I mai la o Labana ia Iakoba, E nana i keia ahu, e nana hoi i keia pohaku kukulu a'u i hoolei aku ai mawaena o kaua;
52 yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
He mea hoikeike keia ahu, he mea hoikeike hoi keia pohaku kukulu, i hele ole aku ai au ma keia aoao o keia ahu i ou la, aole hoi oe e hele mai ma keia aoao o ua ahu nei a me keia pohaku kukulu i o'u nei, e hana ino.
53 Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
O ke Akua o Aberahama, a o ke Akua o Nahora, ke Akua o ko laua makuakane, e hooponopono mawaena o kaua. A hoohiki aku la o Iakoba ma ka Makau o kona makuakane o Isaaka.
54 Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
Alaila, kaumaha aku la o Iakoba i ka mohai maluna o ia mauna, a kahea aku la i kona poe hoahanau e ai i ka berena: ai iho la lakou i ka berena, a moe iho la ia po ma ka mauna.
55 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.
I kakahiaka nui, aia ae ia o Labana, honi ae la i kana mau moopuna a me kana mau kaikamahine, a hoomaikai iho la ia lakou; hele aku la o Labana, a hoi aku la i kona wahi.