< Genesis 31 >

1 Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
Jacob entendit les paroles des fils de Laban, qui disaient: « Jacob a emporté tout ce qui appartenait à notre père. Il a obtenu toutes ces richesses avec ce qui appartenait à notre père. »
2 Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
Jacob vit l'expression du visage de Laban, et voici, elle n'était pas tournée vers lui comme auparavant.
3 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Yahvé dit à Jacob: « Retourne dans le pays de tes pères et dans ta famille, et je serai avec toi. »
4 Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
Jacob envoya appeler Rachel et Léa aux champs, vers son troupeau,
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
et leur dit: Je vois l'expression du visage de votre père, qui n'est pas envers moi comme auparavant; mais le Dieu de mon père a été avec moi.
6 Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
Vous savez que j'ai servi votre père de toute ma force.
7 síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
Ton père m'a trompé et a changé dix fois mon salaire, mais Dieu n'a pas permis qu'il me fasse du mal.
8 Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
S'il a dit: « Les tachetés seront ton salaire », tout le troupeau a porté des tachetés. S'il a dit: « Les rayés seront ton salaire », tout le troupeau a porté des rayés.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
C'est ainsi que Dieu a pris le bétail de ton père et me l'a donné.
10 “Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
Pendant la saison des amours, j'ai levé les yeux et j'ai regardé en songe: voici que les boucs qui sautaient sur le troupeau étaient rayés, tachetés et hérissés.
11 Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
L'ange de Dieu me dit en songe: « Jacob », et je répondis: « Me voici ».
12 Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
Il dit: Lève les yeux, et voici, tous les boucs qui sautent sur le troupeau sont rayés, tachetés et marquetés; car j'ai vu tout ce que Laban te fait.
13 Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
Je suis le Dieu de Béthel, où tu as oint une colonne, où tu m'as fait un vœu. Maintenant, lève-toi, sors de ce pays, et retourne dans le pays de ta naissance. »
14 Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
Rachel et Léa lui répondirent: « Y a-t-il encore pour nous une part ou un héritage dans la maison de notre père?
15 Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
Ne sommes-nous pas considérées par lui comme des étrangères? Car il nous a vendues, et il a aussi épuisé notre argent.
16 Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
Car toutes les richesses que Dieu a enlevées à notre père sont à nous et à nos enfants. Maintenant donc, tout ce que Dieu vous a dit, faites-le. »
17 Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
Alors Jacob se leva, fit monter ses fils et ses femmes sur les chameaux,
18 Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
et il emmena tout son bétail et tous les biens qu'il avait rassemblés, y compris le bétail qu'il avait acquis à Paddan Aram, pour aller vers Isaac, son père, au pays de Canaan.
19 Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
Or Laban était allé tondre ses brebis; et Rachel vola les théraphim qui appartenaient à son père.
20 Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
Jacob trompa Laban, l'Araméen, en ne lui disant pas qu'il s'enfuyait.
21 Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
Il s'enfuit donc avec tout ce qu'il avait. Il se leva, passa le fleuve et se dirigea vers la montagne de Galaad.
22 Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
Le troisième jour, Laban fut informé que Jacob s'était enfui.
23 Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
Il prit avec lui ses proches, et le poursuivit pendant sept jours de marche. Il l'atteignit dans la montagne de Galaad.
24 Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
Dieu apparut à Laban, l'Araméen, dans un songe nocturne, et lui dit: « Prends garde de ne pas parler à Jacob, ni en bien ni en mal. »
25 Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
Laban rattrapa Jacob. Jacob avait dressé sa tente dans la montagne, et Laban et sa famille campaient dans la montagne de Galaad.
26 Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
Laban dit à Jacob: « Qu'as-tu fait pour me tromper, et pour emmener mes filles comme des captives de l'épée?
27 Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
Pourquoi t'es-tu enfui en cachette, et m'as-tu trompé, et ne m'as-tu rien dit, afin que je te renvoie avec de la joie et des chants, avec du tambourin et de la harpe;
28 Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
et ne m'as-tu pas permis d'embrasser mes fils et mes filles? Maintenant, vous avez fait une folie.
29 Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
Il est au pouvoir de ma main de te faire du mal, mais le Dieu de ton père m'a parlé cette nuit, en disant: « Prends garde de ne pas parler à Jacob en bien ou en mal ».
30 Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
Maintenant, tu veux partir, parce que tu as eu un grand désir de la maison de ton père, mais pourquoi as-tu volé mes dieux? »
31 Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
Jacob répondit à Laban: « Parce que j'ai eu peur, car j'ai dit: « De peur que tu ne m'enlèves tes filles par la force ».
32 Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
Toute personne avec laquelle tu trouveras tes dieux ne vivra pas. Devant nos parents, discerne ce qui t'appartient chez moi, et prends-le. » Car Jacob ne savait pas que Rachel les avait volées.
33 Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
Laban entra dans la tente de Jacob, dans la tente de Léa, et dans la tente des deux servantes; mais il ne les trouva pas. Il sortit de la tente de Léa, et entra dans la tente de Rachel.
34 Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
Rachel avait pris les théraphim, les avait mis sur la selle du chameau et s'était assise dessus. Laban tâta toute la tente, mais ne les trouva pas.
35 Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
Elle dit à son père: « Que mon seigneur ne soit pas fâché que je ne puisse pas me lever devant toi, car j'ai mes règles. » Il chercha, mais ne trouva pas les théraphim.
36 Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
Jacob se mit en colère et discuta avec Laban. Jacob répondit à Laban: « Quelle est ma faute? Quel est mon péché, pour que tu me poursuives avec ardeur?
37 Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
Maintenant que tu as fouillé dans toutes mes affaires, qu'as-tu trouvé de toutes tes affaires de famille? Mets-le ici devant ma famille et devant ta famille, afin qu'elles jugent entre nous deux.
38 “Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
« Voilà vingt ans que je suis avec vous. Tes brebis et tes chèvres n'ont pas mis bas, et je n'ai pas mangé les béliers de tes troupeaux.
39 Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
Ce qui a été déchiré des animaux, je ne te l'ai pas apporté. J'en ai supporté la perte. C'est de ma main que vous l'avez exigé, qu'il ait été volé de jour ou de nuit.
40 Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
Telle était ma situation: la sécheresse me consumait le jour, et la gelée la nuit; le sommeil fuyait de mes yeux.
41 Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
Voilà vingt ans que je suis dans ta maison. Je t'ai servi quatorze ans pour tes deux filles, et six ans pour ton troupeau, et tu as changé dix fois mon salaire.
42 Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
Si le Dieu de mon père, le Dieu d'Abraham et d'Isaac, n'avait pas été avec moi, tu m'aurais renvoyé à vide. Dieu a vu mon malheur et le travail de mes mains, et il t'a repris cette nuit. »
43 Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
Laban répondit à Jacob: « Les filles sont mes filles, les enfants sont mes enfants, les troupeaux sont mes troupeaux, et tout ce que tu vois est à moi! Que puis-je faire aujourd'hui à ces filles, ou aux enfants qu'elles ont enfantés?
44 Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
Maintenant, viens, faisons une alliance, toi et moi. Que cela serve de témoignage entre moi et toi. »
45 Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
Jacob prit une pierre, et la dressa pour faire un pilier.
46 Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
Jacob dit à ses proches: « Ramassez des pierres. » Ils prirent des pierres, et firent un tas. Ils mangèrent là, près du tas.
47 Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
Laban l'appela Jegar Sahadutha, mais Jacob l'appela Galeed.
48 Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
Laban dit: « Ce tas est un témoignage entre moi et toi aujourd'hui. » C'est pourquoi on l'appela Galéed
49 Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
et Mitspa, car il dit: « L'Éternel veille entre moi et toi, quand nous sommes absents l'un de l'autre.
50 Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
Si tu affliges mes filles, ou si tu prends des femmes en plus de mes filles, aucun homme n'est avec nous; voici, Dieu est témoin entre moi et toi. »
51 Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
Laban dit à Jacob: « Vois ce monceau et vois le pilier que j'ai mis entre moi et toi.
52 yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
Que ce monceau soit témoin, et que la colonne soit témoin, que je ne passerai pas ce monceau devant toi, et que tu ne passeras pas ce monceau et cette colonne devant moi, pour faire du mal.
53 Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
Le Dieu d'Abraham et le Dieu de Nachor, le Dieu de leur père, juge entre nous. » Alors Jacob jura par la crainte de son père, Isaac.
54 Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
Jacob offrit un sacrifice sur la montagne, et il appela ses proches à manger du pain. Ils mangèrent du pain et passèrent la nuit dans la montagne.
55 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.
De bon matin, Laban se leva, embrassa ses fils et ses filles, et les bénit. Laban s'en alla et retourna à sa place.

< Genesis 31 >