< Genesis 31 >

1 Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
Aftir that Jacob herde the wordis of the sones of Laban, that seiden, Jacob hath take awei alle thingis that weren oure fadris, and of his catel Jacob is maad riche, and noble.
2 Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
Also Jacob perseyuede the face of Laban, that it was not ayens hym as yistirdai, and the thridde dai agoon,
3 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
moost for the Lord seide to hym, Turne ayen into the lond of thi fadris, and to thi generacioun, and Y shal be with thee.
4 Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
He sente, and clepide Rachel, and Lya, in to the feeld, where he kepte flockis, and he seide to hem,
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
Y se the face of youre fadir, that it is not ayens me as `yisterdai and the thridde dai agoon; but God of my fadir was with me.
6 Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
And ye witen that with alle my strengthis Y seruede youre fadir;
7 síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
but and youre fadir disseyuyde me, and chaungide my meede ten sithis; and netheles God suffride not hym to anoye me.
8 Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
If he seide ony tyme, Dyuerse colourid sheep schulen be thi medis, alle sheep brouyten forth dyuerse colourid lambren; forsothe whanne he seide ayenward, Thou shalte take alle white for mede, alle the flockis brouyten forth white beestis;
9 Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
and God took a wey the substaunce of youre fadir, and yaf to me.
10 “Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
For aftir that the tyme of conseyuyng of sheep cam, Y reiside myn iyen, and seiy in sleep malis dyuerse, and spotti, and of dyuerse colouris, stiynge on femalis.
11 Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
And the aungel of the Lord seide to me in sleep, Jacob! and Y answeride, Y am redy.
12 Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
Which seide, Reise thin iyen, and se alle malis dyuerse, byspreynt, and spotti, stiynge on femalis; for Y seiy alle thingis whiche Laban dide to thee;
13 Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
Y am God of Bethel, where thou anoyntidist a stoon, and madist auow to me. Now therefor rise thou, and go out of this lond, and turne ayen in to the lond of thi birthe.
14 Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
And Rachel and Lya answeriden, Wher we han ony thing residue in the catels, and eritage of oure fadir?
15 Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
Wher he `arettide not vs as aliens, and selde, and eet oure prijs?
16 Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
But God took awei the richessis of oure fadir, and yaf tho to vs, and to oure sones; wherfor do thou alle thingis whiche God hath comaundide to thee.
17 Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
Forsothe Jacob roos, and puttide hise fre children and wyues on camels, and yede forth;
18 Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
and he took al his catel, flockis, and what euer thing he hadde gete in Mesopotanye, and yede to Isaac, his fadir, into the lond of Canaan.
19 Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
In that tyme Laban yede to schere scheep, and Rachel stal the idols of hir fadir.
20 Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
And Jacob nolde knouleche to the fadir of his wijf, that he wolde fle;
21 Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
and whanne he hadde go, as wel he as alle thingis that weren of his riyt, and whanne he hadde passid the water, and he yede ayens the hil of Galaad,
22 Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
it was teld to Laban, in the thridde dai, that Jacob fledde.
23 Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
And Laban took his britheren, and pursuede hym seuene daies, and took hym in the hil of Galaad.
24 Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
And Laban seiy in sleep the Lord seiynge to him, Be war that thou speke not ony thing sharpli ayens Jacob.
25 Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
And thanne Jacob hadde stretchid forth the tabernacle in the hil; and whanne he hadde sued Jacob with his britheren, `he settide tente in the same hil of Galaad; and he seide to Jacob,
26 Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
Whi hast thou do so, that the while I wiste not thou woldist dryue awey my douytris as caitifs by swerd?
27 Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
Whi woldist thou fle the while Y wiste not, nether woldist shewe to me, that Y shulde sue thee with ioie, and songis, and tympans, and harpis?
28 Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
Thou suffridist not that Y schulde kisse my sones and douytris; thou hast wrouyt folili.
29 Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
And now sotheli myn hond mai yelde yuel to thee, but the God of thi fadir seide to me yisterdai, Be war that thou speke not ony harder thing with Jacob.
30 Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
Suppose, if thou coueitedist to go to thi kynesmen, and the hows of thi fadir was in desir to thee, whi hast thou stole my goddis?
31 Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
Jacob answeride, That Y yede forth while thou wistist not, Y dredde lest thou woldist take awey thi douytris violentli;
32 Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
sotheli that thou repreuest me of thefte, at whom euer thou fyndist thi goddis, be he slayn bifor oure britheren; seke thou, what euer thing of thine thou fyndist at me, and take awei. Jacob seide these thingis, and wiste not that Rachel stal the idols.
33 Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
And so Laban entride into the tabernacle of Jacob, and of Lya, and of euer eithir meyne, and foond not; and whanne Laban hadde entrid in to the tente of Rachel,
34 Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
sche hastide, and hidde the idols vndur the strewyngis of the camel, and sat aboue. And sche seide to Laban, sekynge al the tente and fyndynge no thing,
35 Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
My lord, be not wrooth that Y may not rise bifore thee, for it bifelde now to me bi the custom of wymmen; so the bisynesse of the sekere was scorned.
36 Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
And Jacob bolnyde, and seide with strijf, For what cause of me, and for what synne of me, hast thou come so fersly aftir me,
37 Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
and hast souyt al `the portenaunce of myn hous? What `hast thou founde of al the catel of thin hows? Putte thou here bifore my britheren and thi britheren, and deme thei betwixe me and thee.
38 “Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
Was I with thee herfore twenti yeer? Thi sheep and geet weren not bareyn, Y eet not the rammes of thi flok,
39 Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
nether Y schewide to thee ony thing takun of a beeste; Y yeldide al harm; what euer thing perischide bi thefte, thou axidist of me;
40 Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
Y was angwischid in dai and nyyt with heete and frost, and sleep fledde fro myn iyen;
41 Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
so Y seruede thee bi twenti yeer in thin hows, fourtene yeer for thi douytris, and sixe yeer for thi flockis; and thou chaungidist my mede ten sithis.
42 Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
If God of my fadir Abraham, and the drede of Isaac hadde not helpid me, perauenture now thou haddist left me nakid; the Lord bihelde my turmentyng and the traueyl of myn hondis, and repreuyde thee yistirdai.
43 Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
Laban answeride hym, The douytris, and thi sones, and flockis, and alle thingis whiche thou seest, ben myne, what mai Y do to my sones, and to the sones of sones?
44 Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
Therfor come thou, and make we boond of pees, that it be witnessyng bitwixe me, and thee.
45 Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
And so Jacob took a stoon, and reiside it in to a signe, and seide to hise britheren,
46 Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
Brynge ye stoonus; whiche gadriden, and maden an heep, and eten on it.
47 Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
And Laban clepide it the heep of wittnesse, and Jacob clepide it the heep of witnessyng; euer eithir clepide bi the proprete of his langage.
48 Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
And Laban seide, This heep schal be witnesse bytwixe me and thee to day, and herfor the name therof was clepid Galaad, that is, the heep of witnesse.
49 Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
And Laban addide, The Lord biholde, and deme bitwixe vs, whanne we schulen go awei fro yow;
50 Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
if thou schalt turmente my douytris, and if thou schal brynge yn othere wyues on hem, noon is witnesse of oure word, outakun God, whiche is present, and biholdith.
51 Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
And eft he seide to Jacob, Lo! this heep, and stoon, whiche Y reiside bitwixe me and thee, schal be witnesse;
52 yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
sotheli this heep, and stoon be in to witnessyng, forsothe if Y schal passe it, and go to thee, ether thou shalt passe, and thenke yuel to me.
53 Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
God of Abraham, and God of Nachor, God of the fadir of hem, deme bitwixe vs. Therfor Jacob swoor by the drede of his fadir Ysaac;
54 Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
and whanne slayn sacrifices weren offrid in the hil, he clepyde his britheren to ete breed, and whanne thei hadden ete, thei dwelliden there.
55 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.
Forsothe Laban roos bi nyyt, and kisside his sones, and douytris, and blesside hem, and turnede ayen in to his place.

< Genesis 31 >