< Genesis 30 >
1 Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
І побачила Рахіль, що вона не вродила Якову. І заздрила Рахіль сестрі своїй, і сказала до Якова: „Дай мені синів! А коли ні, то я вмираю!“
2 Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
І запалився гнів Яковів на Рахіль, і він сказав: „Чи я замість Бога, що затримав від тебе плід утроби?“
3 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
І сказала вона: „Ось неві́льниця моя Білга. Прийди до неї, і нехай вона вродить на коліна мої, і я також буду мати від неї дітей“.
4 Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
І вона дала йому Білгу, невільницю свою, за жінку. І ввійшов до неї Яків.
5 Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
І завагітніла Білга, і вродила Якову сина.
6 Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
І сказала Рахіль: „Розсудив Бог мене, а також вислухав голос мій, і дав мені сина.“Тому́ назвала ймення йому: Дан.
7 Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
І завагітніла вона ще, і вродила Білга, невільниця Рахілина, другого сина Якову.
8 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
І сказала Рахіль: „Великою боротьбою боролась я з сестрою своєю, — і перемогла. І назвала ймення йому: Нефтали́м.
9 Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
І побачила Лія, що вона перестала родити, і взяла Зілпу, свою невільницю, і дала́ її Якову за жінку.
10 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
І вродила Зілпа, неві́льниця Леїна, Якову сина.
11 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
І сказала Лія: „Прийшло щастя“, і назвала ймення йому Ґад.
12 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
І вродила Зілпа, невільниця Ліїна, другого сина Якову.
13 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
І промовила Лія: „ То на блаже́нство моє, бо будуть уважати мене за жінку блаженну“. І назвала ймення йому: Аси́р.
14 Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
І пішов Рувим за тих днів, коли жато пшеницю, і знайшов на полі мандрагорові яблучка, і приніс їх до Лії, матері своєї. І сказала Рахіль до Лії: „Дай мені з мандрагорових яблучок сина твого!“
15 Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
А та відказала їй: „Чи мало тобі, що забрала мого чоловіка? І забереш також мандрагорові яблучка сина мого?“І сказала Рахіль: „Тому то він ляже з тобою цієї ночі за мандрагорові яблучка сина твого!“
16 Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
І прийшов Яків з поля ввечері, а Лія вийшла назустріч і сказала: „Уві́йдеш до мене, бо справді найняла я тебе за мандрагорові яблучка сина мого“. І лежав він із нею ночі тієї.
17 Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
І вислухав Бог Лію, і завагітніла вона, і вродила Якову п'ятого сина.
18 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
І промовила Лія: „Дав Бог заплату мені, що дала я невільницю свою своєму чоловікові“. І назвала ймення йому: Іссаха́р.
19 Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
І завагітніла Лія ще, і вродила Якову шостого сина.
20 Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
І промовила Лія: „Обдарував мене Бог добрим подарунком, — цим разом замешкає в мене мій чоловік, бо я породила йому шестеро синів“. І назвала ймення йому: Завуло́н.
21 Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
А потому вродила дочку, і назвала ймення їй: Діна.
22 Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
І згадав Бог про Рахіль, і вислухав її Бог, і відчинив їй утробу.
23 Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
І завагітніла вона, і сина вродила, і сказала: „Бог забрав мою ганьбу!“
24 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
І назвала ймення йому: Йо́сип, кажучи: „Додасть Господь мені іншого сина!“
25 Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
І сталося, коли Рахіль породила Йо́сипа, то сказав Яків до Лавана: „Відпусти мене, і нехай я піду́ до свого місця й до Кра́ю свого.
26 Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
Дай же жінок моїх і дітей моїх, що служив тобі за них, і нехай я піду́, бо ти знаєш службу мою, яку я служив був тобі“.
27 Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
І промовив до нього Лаван: „Коли я знайшов милість в очах твоїх, побудь з нами, бо я зрозумів, що поблагословив мене Господь через тебе“.
28 Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
І далі казав: „Признач собі заплату від мене, — і я дам“.
29 Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
А той відказав: „Ти знаєш, як я служив тобі, і якою стала худоба твоя зо мною.
30 Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
Бо те мале, що було в тебе до мене, розмножилося на велике, і Господь поблагословив тебе, відко́ли нога моя в тебе. А тепер, коли ж я буду працювати для власного дому?“
31 Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
І сказав Лаван: „Що́ ж я тобі дам?“А Яків промовив: „Не давай мені нічого. Коли зробиш мені оцю річ, то вернуся, буду пасти отару твою, буду пильнувати.
32 Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
Я сьогодні перейду́ через усю отару твою, щоб вилучити звідти кожну овечку крапчасту й перепола́су, і кожну овечку чорну — з-поміж овець, і переполасе й крапчасте з-поміж кіз, — і це буде заплата мені.
33 Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
І справедливість моя посвідчить за мене в завтрішнім дні, коли при́йдеш гля́нути на заплату мою від тебе. Усе, що воно не крапчасте й не переполасе з-поміж кіз і не чорне з-поміж овець, — крадене воно в мене“.
34 Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
А Лаван відказав: „Так, — нехай буде за словом твоїм!“
35 Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
І того дня вилучив він козлів пасастих і покрапованих, і всі кози крапчасті й переполасі, усе, що біле було́ в ньому, і все чорне серед овець, і дав до рук своїх синів.
36 Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
І визначив дорогу триденну поміж собою й поміж Яковом. А Яків пас позосталу Лаванову отару.
37 Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
І взяв собі Яків сирого кия тополевого, і мігдалового, і каштанового, і налупив з них білих лушпин, відкриваючи білість, що на киях була.
38 Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
І поставив кийки, що їх облупив, перед отарою при жолобах при коритах води, куди отара приходить пити. І вони злучувалися, як прихо́дили пити.
39 Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
І злучувалася отара при киях, і котилася овечками та козами пасастими, крапчастими й переполасими.
40 Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
І відділя́в Яків тих овечок, і ставив отару обличчям до пасастого й до всього чорного серед отари Лавана. І клав свої стада окремо, і не клав їх до отари Лаванової.
41 Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
І бувало, що кожного разу, коли злучувалася отара міцна, то Яків клав при жолобах киї перед очі отари, щоб вона злучувалася при тих киях.
42 Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
А як отара слаба була, то не клав. І ставалось, що слабе припадало Лаванові, а міцніше — Якову.
43 Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
І дуже-дуже зможнів той чоловік. І було в нього багато отар, і невільниці, і раби, і верблюди, і осли.