< Genesis 30 >

1 Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
Kad nu Rahēle redzēja, ka tā Jēkabam nedzemdēja, tad tā apskauda savu māsu un sacīja uz Jēkabu: dabū man bērnus, bet ja ne, tad man jāmirst.
2 Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
Tad Jēkabs apskaitās uz Rahēli un sacīja: vai es esmu Dieva vietā, kas tev miesas augļus liedzis?
3 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
Un tā sacīja: redzi, še ir mana kalpone Bilha, ej pie tās, ka tā uz manu klēpi dzemdē, un es arīdzan caur viņu augļojos.
4 Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
Un viņa tam deva Bilu, savu kalponi par sievu, un Jēkabs gāja pie tās.
5 Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
Un Bilha tapa grūta un dzemdēja Jēkabam dēlu.
6 Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
Tad Rahēle sacīja: Dievs man tiesu ir iznesis un arī manu balsi paklausījis un man dēlu devis. Tādēļ tā viņa vārdu nosauca Danu.
7 Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
Un Bilha, Rahēles kalpone, tapa atkal grūta un dzemdēja Jēkabam otru dēlu.
8 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
Tad Rahēle sacīja: Dieva cīnīšanos esmu cīnījusies ar savu māsu un arī uzvarējusi, - un nosauca viņa vārdu Naftali.
9 Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
Kad nu Lea redzēja, ka bija mitējusies dzemdēt, tad tā arīdzan ņēma savu kalponi Zilfu un to Jēkabam deva par sievu.
10 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
Un Zilfa, Leas kalpone, dzemdēja Jēkabam dēlu.
11 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
Tad Lea sacīja: laime, - un nosauca viņa vārdu Gadu.
12 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
Un Zilfa, Leas kalpone, dzemdēja Jēkabam otru dēlu.
13 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
Tad Lea sacīja: labi man, jo meitas mani teiks svētīgu, - un tā nosauca viņa vārdu Ašeru.
14 Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
Un Rūbens gāja kviešu pļaujamā laikā un atrada dudaīm (mīlestības ābols) laukā un atnesa tos Leai, savai mātei, un Rahēle sacīja uz Leū: dod man jel no tava dēla dudaīm.
15 Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
Un viņa uz to sacīja: vai tā ir maza lieta, ka tu manu vīru esi atņēmusi, un tu arī mana dēla dudaīm gribi ņemt? Tad Rahēle sacīja: tam būs šo nakti pie tevis gulēt par tava dēla dudaīm.
16 Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
Kad nu Jēkabs vakarā no lauka nāca, tad Lea tam izgāja pretī un sacīja: tev būs nākt pie manis, jo es tevi ar maksu esmu saderējusi par sava dēla dudaīm. Un viņš pie tās gulēja tanī naktī.
17 Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
Un Dievs paklausīja Leū, un tā tapa grūta un dzemdēja Jēkabam piekto dēlu.
18 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
Tad Lea sacīja: Dievs man to atmaksājis, ka es savam vīram esmu devusi savu kalponi, - un tā nosauca viņa vārdu Īsašaru.
19 Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
Un Lea tapa atkal grūta un dzemdēja Jēkabam sesto dēlu.
20 Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
Tad Lea sacīja: Dievs mani apdāvinājis ar labu dāvanu, nu mans vīrs pie manis dzīvos, tāpēc, ka es viņam esmu dzemdējusi sešus dēlus - un tā nosauca viņa vārdu Zebulonu.
21 Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
Un pēc tam viņa dzemdēja meitu un nosauca viņas vārdu Dinu.
22 Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
Un Dievs pieminēja Rahēli un paklausīja viņu un darīja viņu auglīgu.
23 Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
Un viņa tapa grūta un dzemdēja dēlu un sacīja: Dievs manu apsmieklu no manis atņēmis.
24 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
Un tā nosauca viņa vārdu Jāzepu, sacīdama: lai Tas Kungs mani apdāvina vēl ar citu dēlu.
25 Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
Un notikās, kad Rahēle Jāzepu bija dzemdējusi, tad Jēkabs sacīja uz Lābanu: atlaid mani, ka es noeju uz savu vietu savā zemē,
26 Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
Dod man manas sievas un manus bērnus, kuru dēļ tev esmu kalpojis, tad es iešu, jo tu gan zini to kalpošanu, ko tev esmu kalpojis.
27 Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
Un Lābans uz to sacīja: kaut es būtu atradis žēlastību tavās acīs! - es esmu nopratis, ka Tas Kungs mani tevis dēļ ir svētījis.
28 Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
Un viņš sacīja: prasi savu algu no manis, tad es to došu.
29 Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
Un tas uz viņu sacīja: tu zini, kā es tev esmu kalpojis, un kā tavi lopi pie manis ir izdevušies.
30 Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
Jo priekš manas atnākšanas tev bija mazums, un tas ir lielā pulkā vairojies, un Tas Kungs tevi svētījis caur maniem soļiem; un nu, kad tad man būs apgādāt savu namu?
31 Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
Un viņš sacīja: ko lai tev dodu? Tad Jēkabs sacīja: tev man nekā nav jādod; ja tu man šo darīsi, tad es atkal ganīšu un sargāšu tavas avis.
32 Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
Es izstaigāšu šodien pa visu tavu ganāmo pulku un atšķiršu no turienes visus raibos un lāsainos un visus melnos starp jēriem un visus lāsainos un raibos starp kazām, - un tās būs man par algu.
33 Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
Tad mana taisnība liecinās par mani nākamās dienās, kad tu nāksi, manu algu raudzīt: viss, kas nav raibs un lāsains starp kazām un melns starp jēriem, to es būšu zadzis.
34 Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
Tad Lābans sacīja: redzi, lai jel notiek pēc tava vārda.
35 Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
Un viņš atšķīra tanī dienā tos lāsainos un raibos āžus, un visas lāsainās un raibās kazas, visu, pie kā bija baltums, un visu, kas bija melns starp jēriem, un viņš tos iedeva savu bērnu rokā;
36 Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
Un lika starpu treju dienu gājumā starp sevi un Jēkabu. Un Jēkabs ganīja Lābana citas avis.
37 Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
Tad Jēkabs ņēma rīkstes no zaļām apsēm un mandeļu kokiem un kļavām, un nodrāza tām baltas strīpas, atklādams to baltumu pie tām rīkstēm.
38 Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
Un tos kociņus, ko bija nomizojis, viņš ielika ūdens silēs un dzeramos traukos avīm priekšā, ka tās nākdamas dzert apietos.
39 Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
Un tās avis apgājās pār tām rīkstēm, un vedās strīpainas, lāsainas un raibas.
40 Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
Un Jēkabs šķīra tos jērus, un lika tām mātēm skatīties uz tām strīpainām un melnām starp Lābana avīm, un lika savus ganāmos pulkus atsevišķi, un nelika tos pie Lābana avīm.
41 Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
Un notikās allažiņ, kad tās agrās avis apgājās, tad Jēkabs to avju priekšā tos kociņus ielika ūdens silēs, ka tās pār tiem kokiem apietos.
42 Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
Bet kad tās vēlās avis apgājās, tad Jēkabs tos kociņus nelika iekšā, tad tie atpīļi(vājie) kļuva Lābanam un tie agrējie(spēcīgie) Jēkabam.
43 Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Un tas vīrs auga ļoti varens, un tam bija daudz avju, kalpoņu un kalpu, kamieļu un ēzeļu.

< Genesis 30 >