< Genesis 30 >
1 Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
És látá Rákhel, hogy ő nem szűle Jákóbnak, irigykedni kezde Rákhel az ő nénjére, és monda Jákóbnak: Adj nékem gyermekeket, mert ha nem, meghalok.
2 Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
Felgerjede azért Jákób haragja Rákhel ellen, és monda: Avagy Isten vagyok-é én, ki megtagadta tőled a méhnek gyümölcsét.
3 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
És monda ez: Ímhol az én szolgálóm Bilha, menj be hozzá, hogy szűljön az én térdeimen, és én is megépüljek ő általa.
4 Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
Adá tehát néki az ő szolgálóját Bilhát feleségűl, és beméne ahhoz Jákób.
5 Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
És teherbe esék Bilha és szűle Jákóbnak fiat.
6 Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
És monda Rákhel: Ítélt felőlem az Isten, és meg is hallgatta szavamat, és adott énnékem fiat: azért nevezé nevét Dánnak.
7 Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
Ismét fogada az ő méhében, és szűle Bilha, a Rákhel szolgálója más fiat is Jákóbnak.
8 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
És monda Rákhel: Nagy tusakodással tusakodtam az én nénémmel, és győztem; azért nevezé nevét Nafthalinak.
9 Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
Látván pedig Lea hogy ő megszűnt a szűléstől, vevé az ő szolgálóját Zilpát, és adá azt Jákóbnak feleségűl.
10 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
És szűle Zilpa, Lea szolgálója, fiat Jákóbnak.
11 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
És monda Lea: Szerencsére! és nevezé nevét Gádnak!
12 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
És szűle Zilpa, Lea szolgálója, más fiat is Jákóbnak.
13 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
És monda Lea: Oh én boldogságom! bizony boldognak mondanak engem az asszonyok: és nevezé nevét Ásernek.
14 Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
És kiméne Rúben búzaaratáskor, és talála a mezőn mandragóra-bogyókat s vivé azokat az ő anyjának, Leának. És monda Rákhel Leának: Adj nékem kérlek a fiad mandragóra-bogyóiból.
15 Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
Az pedig monda néki: Talán keveselled, hogy elvetted tőlem az én férjemet, s a fiam mandragóra-bogyóit is elvennéd tőlem? És monda Rákhel: Háljon veled hát az éjjel a te fiad mandragóra-bogyóiért.
16 Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
Mikor Jákób este a mezőről jöve, eleibe méne Lea, és monda: Én hozzám jőjj be, mert megvettelek a fiam mandragóra-bogyóiért; és nála hála azon éjszaka.
17 Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
És meghallgatá Isten Leát, mert fogada az ő méhében és szűle Jákóbnak ötödik fiat.
18 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
És monda Lea: Megadta az Isten jutalmamat, a miért szolgálómat férjemnek adtam; azért nevezé nevét Izsakhárnak.
19 Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
És ismét fogada az ő méhében Lea, és szűle hatodik fiat Jákóbnak.
20 Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
És monda Lea: Megajándékozott az Isten engem jó ajándékkal; most már velem lakik az én férjem, mert hat fiat szűltem néki, és nevezé nevét Zebulonnak.
21 Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
Annakutána szűle leányt, és nevezé nevét Dínának.
22 Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
Megemlékezék pedig az Isten Rákhelről; és meghallgatá őt az Isten és megnyitá az ő méhét.
23 Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
És fogada méhében, és szűle fiat, s monda: Elvevé Isten az én gyalázatomat.
24 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
És nevezé nevét Józsefnek, mondván: Adjon ehhez az Úr nékem más fiat is.
25 Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
És lőn, a mint szűlte vala Rákhel Józsefet, monda Jákób Lábánnak: Bocsáss el engemet, hadd menjek el az én helyembe, az én hazámba.
26 Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
Add meg nékem az én feleségeimet és magzatimat, a kikért szolgáltalak téged, hadd menjek el, mert te tudod az én szolgálatomat, a melylyel szolgáltalak téged.
27 Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
És monda néki Lábán: Vajha kedvet találtam volna szemeid előtt! Úgy sejtem, hogy te éretted áldott meg engem az Úr.
28 Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
És monda: Szabj bért magadnak és én megadom.
29 Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
Ez pedig monda: Te tudod mimódon szolgáltalak téged, és hogy mivé lett nálam a te jószágod.
30 Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
Mert a mi kevesed vala én előttem, sokra szaporodott, és megáldott az Úr téged az én lábam nyomán. Immár mikor tehetek valamit a magam házáért is?
31 Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
És monda Lábán: Mit adjak néked? Felele Jákób: Ne adj nékem semmit; juhaidat ismét legeltetem és őrizem, ha nekem ezt a dolgot megteszed:
32 Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
Nyájaidat ma mind végig járom, minden pettyegetett és tarka bárányt kiszaggatok közűlök, és minden fekete bárányt a juhok közűl, s a tarkát és pettyegetettet a kecskék közűl, s legyen ez az én bérem.
33 Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
S a mikor majd bérem iránt eljövéndesz, mi előtted lesz, becsületességemről ez felel: a mi nem pettyegetett vagy tarka a kecskék, s nem fekete a juhok közt, az mind lopott jószág nálam.
34 Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
És monda Lábán: Ám legyen: Vajha a te beszéded szerint lenne.
35 Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
Külön választá azért azon a napon a pettyegetett és tarka kosokat, és minden csíkos lábú és tarka kecskét, mind a melyikben valami fehérség vala, és minden feketét a juhok közűl, és adá az ő fiainak keze alá.
36 Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
És három napi járó földet vete maga közé és Jákób közé; Jákób pedig legelteti vala Lábán egyéb juhait.
37 Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
És vőn Jákób zöld nyár-, mogyoró- és gesztenye-vesszőket, és meghántá azokat fehéresen csíkosra, hogy látható legyen a vesszők fehére.
38 Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
És a vesszőket, melyeket meghántott vala, felállítá a csatornákba, az itató válúkba, melyekre a juhok inni járnak vala, szembe a juhokkal, hogy foganjanak, mikor inni jönnek.
39 Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
És a juhok a vesszők előtt foganának és ellenek vala csíkos lábúakat, pettyegetetteket és tarkákat.
40 Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
Azután külön szakasztá Jákób ezeket a bárányokat, és a Lábán nyáját arczczal fordítja vala a csíkos lábú és fekete bárányokra; így szerze magának külön falkákat, melyeket nem ereszte a Lábán juhai közé.
41 Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
És lőn, hogy mikor a nyáj java részének vala párzási ideje, akkor Jákób a vesszőket oda raká a válúkba a juhok eleibe, hogy a vesszőket látva foganjanak.
42 Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
De mikor satnya vala a nyáj, nem rakja vala oda s ily módon Lábánéi lőnek a satnyák, a java pedig Jákóbé.
43 Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
És felette igen meggazdagodék a férfiú; és vala néki sok juha, szolgálója, szolgája, tevéje és szamara.