< Genesis 30 >
1 Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
Rĩrĩa Rakeli onire atĩ ndaraciarĩra Jakubu ciana-rĩ, akĩiguĩra mwarĩ wa nyina ũiru. Nĩ ũndũ ũcio akĩĩra Jakubu atĩrĩ, “He ciana kana ngue!”
2 Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
Jakubu akĩrakario nĩ Rakeli akĩmũũria atĩrĩ, “Kaarĩ niĩ ndĩ ithenya rĩa Ngai ũrĩa ũkũimĩte ciana?”
3 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
Rakeli akĩmwĩra atĩrĩ, “Biliha ndungata yakwa ya mũirĩtu ĩrĩ haha; koma nayo nĩgeetha ĩnjiarĩre ciana, na niĩ ngĩe na nyũmba na ũndũ wayo.”
4 Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio akĩmũhe Biliha ndungata yake ya mũirĩtu ĩrĩ ta mũtumia wake. Jakubu agĩkoma nayo,
5 Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
nake Biliha akĩgĩa nda, akĩmũciarĩra kahĩĩ.
6 Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
Rakeli akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩandĩhĩria na nĩaiguĩte gũthaithana gwakwa, na nĩaheete kahĩĩ.” Na tondũ ũcio, agĩgatua Dani.
7 Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
Biliha ndungata ĩyo ya Rakeli ĩkĩgĩa nda ĩngĩ, na ĩgĩciarĩra Jakubu kahĩĩ ga keerĩ.
8 Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
Nake Rakeli akiuga atĩrĩ, “Nĩ ngoretwo na kũgiana kũnene na mwarĩ wa maitũ, na nĩ hootanĩte.” Nĩ ũndũ ũcio agĩgatua Nafitali.
9 Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
Na rĩrĩa Lea onire atĩ nĩarũgamĩte kũgĩa ciana-rĩ, akĩoya Zilipa ndungata yake ya mũirĩtu akĩmĩhe Jakubu ĩrĩ ta mũtumia wake.
10 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
Nake Zilipa, ndungata ĩyo ya Lea, ĩgĩciarĩra Jakubu kahĩĩ.
11 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
Nake Lea akiuga atĩrĩ, “Hĩ, kaĩ ũyũ nĩ mũnyaka-ĩ!” Nĩ ũndũ ũcio agĩgatua Gadi.
12 Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
Zilipa ndungata ĩyo ya Lea ĩgĩciarĩra Jakubu kahĩĩ ga keerĩ.
13 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
Ningĩ Lea akiuga atĩrĩ, “Kaĩ ndĩ mũkenu-ĩ! Andũ-a-nja marĩnjĩtaga ‘mũkenu.’” Nĩ ũndũ ũcio agĩgatua Asheri.
14 Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
Na rĩrĩ, hĩndĩ ya kũgetha ngano-rĩ, Rubeni agĩthiĩ mũgũnda-inĩ na akĩona mĩmera ya mandarĩki, na akĩrehera nyina Lea. Nake Rakeli akĩĩra Lea atĩrĩ, “Ndagũthaitha he mandarĩki mamwe ma mũrũguo.”
15 Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
Nake Lea akĩmũcookeria atĩrĩ, “Kaĩ arĩ ũndũ mũnini kũndunya mũthuuri wakwa? Rĩu ningĩ nĩũkuoya mandarĩki ma mũriũ wakwa o namo?” Rakeli akĩmwĩra atĩrĩ, “He mandarĩki ma mũrũguo, nake Jakubu akome nawe ũmũthĩ.”
16 Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
Na rĩrĩa Jakubu ookire hwaĩ-inĩ oimĩte mũgũnda-rĩ, Lea agĩthiĩ kũmũtũnga. Akĩmwĩra atĩrĩ, “No nginya ũkome na niĩ, tondũ nĩngũgũrire na mandarĩki ma mũriũ wakwa.” Nĩ ũndũ ũcio agĩkoma nake ũtukũ ũcio.
17 Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
Nake Ngai akĩigua mahooya ma Lea, nake akĩgĩa nda na agĩciarĩra Jakubu kahĩĩ ga gatano.
18 Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
Ningĩ Lea akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩaheete kĩheo nĩ ũndũ wa kũheana ndungata yakwa ya mũirĩtu kũrĩ mũthuuri wakwa.” Nĩ ũndũ ũcio agĩgatua Isakaru.
19 Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
Lea agĩcooka akĩgĩa nda ĩngĩ, na agĩciarĩra Jakubu, kahĩĩ ga gatandatũ.
20 Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
Ningĩ Lea akiuga atĩrĩ, “Ngai ekũhe kĩheo kĩa goro mũno. Rĩu mũthuuri wakwa nĩarĩheeaga gĩtĩĩo tondũ ndĩmũciarĩire ihĩĩ ithathatũ.” Nĩ ũndũ ũcio agĩgatua Zebuluni.
21 Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
Thuutha ũcio agĩciara mũirĩtu na akĩmũtua Dina.
22 Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
Thuutha ũcio Ngai akĩririkana Rakeli, akĩmũigua, na akĩhingũra nda yake.
23 Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
Nake akĩgĩa nda na agĩciara kahĩĩ, akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩanjehereria thoni.”
24 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
Nake agĩgatua Jusufu, akiuga atĩrĩ, “Ngai arohe kahĩĩ kangĩ!”
25 Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
Thuutha wa Rakeli gũciara Jusufu, Jakubu akĩĩra Labani atĩrĩ, “Ndekereria ndĩthiĩre, nĩguo njooke bũrũri witũ.
26 Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
Nengera atumia akwa na ciana ciakwa, arĩa ngũtungatĩire nĩ ũndũ wao, na niĩ ndĩthiĩre. Wee nĩũũĩ wĩra ũrĩa ngũrutĩire.”
27 Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
No Labani akĩmwĩra atĩrĩ, “Angĩkorwo nĩnjĩtĩkĩrĩkĩte maitho-inĩ maku-rĩ, ndagũthaitha ikaranga. Nĩmenyete na ũndũ wa ũragũri atĩ Jehova nĩandathimĩte nĩ ũndũ waku.”
28 Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
Agĩthiĩ na mbere, akiuga atĩrĩ, “Njĩĩra mũcaara ũrĩa ũkwenda na nĩ ngũkũrĩha.”
29 Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
Jakubu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee nĩũũĩ ũrĩa ngũrutĩire wĩra na ũrĩa menyereire mahiũ maku nginya makaingĩha.
30 Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
Kĩrĩa kĩnini warĩ nakĩo itaanoka nĩkĩingĩhĩte mũno, nake Jehova nĩakũrathimĩte kũrĩa guothe ngoretwo. No rĩrĩ, ngeekĩra nyũmba yakwa ũndũ rĩ?”
31 Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
Labani akĩmũũria atĩrĩ, “Ũkwenda ngũhe kĩ?” Jakubu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndũkahe kĩndũ o na kĩ. Korwo no ũnjĩkĩre ũndũ ũyũ ũmwe tu, no thiĩ na mbere na kũrĩithia ndũũru ciaku na gũcimenyerera:
32 Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
Naguo ũndũ ũcio nĩ ũyũ: Njĩtĩkĩria thiĩ ndũũru-inĩ ciaku ciothe ũmũthĩ, na njeherie thĩinĩ wacio ngʼondu iria ciothe irĩ maara kana irĩ marooro, na ndũrũme ciothe iria njirũ na mbũri ciothe iria irĩ maara na irĩ maroro. Icio nĩcio igũtuĩka mũcaara wakwa.
33 Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
Naguo wĩhokeku wakwa nĩguo ũkaanjarĩrĩria thuutha-inĩ, rĩrĩa rĩothe ũngĩũka kuona mũcaara ũrĩa ũndĩhĩte. Mbũri o yothe ĩtarĩ maara kana maroro, kana ndũrũme o yothe ĩtarĩ njirũ, ingĩgaakorwo nacio, igaatuĩka nĩ cia ũici.”
34 Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
Nake Labani akiuga atĩrĩ, “Nĩndetĩkĩra; reke gũtuĩke o ro ũguo woiga.”
35 Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
Mũthenya o ro ũcio-rĩ, Labani akĩeheria thenge ciothe iria ciarĩ maara na iria ciarĩ na maroro, na mĩgoma yothe ĩrĩa yarĩ maara na ĩrĩa yarĩ na marooro (iria ciothe ciarĩ na handũ herũ), na ndũrũme ciothe iria ciarĩ njirũ agĩcineana kũrĩ ariũ ake macirĩithagie.
36 Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
Ningĩ agĩcieheranĩria na iria ingĩ na ũraihu wa rũgendo rwa mĩthenya ĩtatũ gatagatĩ gake na Jakubu. Nake Jakubu agĩthiĩ na mbere kũrĩithia ndũũru iria ingĩ cia Labani ciatigarire.
37 Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
No rĩrĩ, Jakubu agĩtema thanju njigũ cia mũribina, na mũrothi, na cia mũarimaũ, agĩciĩkĩra mĩcoora mĩerũ na ũndũ wa kũnũra igoko agatũma werũ wa thĩinĩ wa thanju icio wonekane.
38 Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
Agĩcooka akĩiga thanju icio oonũrĩte mĩtaro-inĩ yothe ĩrĩa yanyuuagĩrwo maaĩ, nĩgeetha ikoragwo irĩ mbere ya mbũri rĩrĩa cioka kũnyua maaĩ. Rĩrĩa ndũũru icio ciakorwo irĩ na mũrukĩ na cioka kũnyua maaĩ-rĩ,
39 Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
igakĩhaicanĩra hau mbere ya thanju icio. Thuutha ũcio igaciara tũũri tũrĩ na manyaga, kana maara, kana marooro.
40 Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
Jakubu akĩamũrania tũũri tũu kuuma rũũru-inĩ rwa Labani, na tũgetindia, no agatũma icio ingĩ ingʼethere iria ciarĩ na maroro na iria njirũ cia Labani. Nĩ ũndũ ũcio agĩĩthondekera ndũũru ciake mwene, na ndaacituranĩrire na cia Labani.
41 Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
Hĩndĩ ĩrĩa yothe mbũri iria ciarĩ na hinya ciagĩa na mũrukĩ-rĩ, Jakubu aigaga thanju icio mĩtaro-inĩ ya maaĩ mbere yacio, nĩgeetha cihaicanĩre hakuhĩ na thanju icio;
42 Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
no ingĩakorirwo nĩ iria itaarĩ na hinya, ndaigaga thanju icio ho. Nĩ ũndũ ũcio mbũri iria ciarĩ mocu igĩtuĩka cia Labani, na iria ciarĩ hinya igĩtuĩka cia Jakubu.
43 Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Nĩ ũndũ wa gwĩka ũguo, mũndũ ũcio ti Jakubu agĩkĩrĩrĩria kũgĩa na indo nyingĩ, akĩgĩa na mahiũ maingĩ, na ndungata cia airĩtu na cia arũme, o na ngamĩĩra na ndigiri.