< Genesis 3 >

1 Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”
Pahui loe Angraeng mah sak ih moi kasan boih thungah aling thaih koek ah oh. Anih mah nongpata khaeah, Takha thungah kaom thingkung hoiah kathai athaih to caa hoi boih hmah, tiah Sithaw mah thuih tangtang maw? tiah a naa.
2 Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà,
Nongpata mah pahui khaeah, Takha thungah kaom thingkungnawk hoiah kathai athaih to ka caak hoi thaih;
3 ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’”
toe Sithaw mah, Takha um ah kaom thingkung pong ih athaih loe caa hoi hmah, sui doeh sui hoi hmah, na dueh hoi tih, tiah thuih, tiah a naa.
4 Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.”
Pahui mah nongpata khaeah, Na dueh hoi tangtang mak ai, tiah a naa.
5 “Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”
Na caak hoi niah na mik to amtueng ueloe, sithawnawk baktih toengah, kasae kahoih na panoek hoi toeng tih, tiah Sithaw mah panoek pongah ni, to tiah ang thuih, tiah a naa.
6 Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́.
Nongpata mah thingkung loe caak han kahoih thingkung ah a hnuk, mik hoiah khit moe, palunghahaih paek thaih thingkung ah oh pongah, thingthai to pakhrik moe, a caak, a sava han doeh a paek; anih mah doeh caak toeng.
7 Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.
To naah nihnik ih mik to amtueng, nihnik loe bangkrai ah ni ka oh hoi, tiah panoekhaih to a tawnh hoi boeh; to naah thaiduet qamnawk to a huih hoi moe, kaeng ah angzaeng hoi.
8 Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà.
Ni amding ruehaih atue phak naah loe, takha thungah amkae Angraeng Sithaw ih atuen to a thaih hoi: Adam hoi anih ih zu mah Angraeng to takha thung ih thingkungnawk salakah anghawk hoi taak ving.
9 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”
Angraeng Sithaw mah Adam to kawk, anih khaeah, Naa ah maw na oh? tiah a naa.
10 Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”
Anih mah, Takha thungah na lok to ka thaih, bangkrai ah ka oh pongah, zithaih ka tawnh moe, kang hawk ving boeh, tiah a naa.
11 Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”
Anih mah, bangkrai ah na oh, tiah mi mah maw ang thuih? Caa hmah tiah kang thuih ih thingthai to na caak ving boeh tani? tiah a naa.
12 Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”
To naah Adam mah, Kai han nang paek ih nongpata mah thingkung pong ih athaih to ang paek moe, ka caak, tiah a naa.
13 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”
Angraeng Sithaw mah nongpata khaeah, Tipongah hae tiah na sak loe? tiah a naa. Nongpata mah, Pahui mah ang ling pongah, ka caak, tiah a naa.
14 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí, “Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ! Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́, ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
To pongah Angraeng Sithaw mah pahui khaeah, Hae hmuen hae na sak boeh pongah, Moinawk boih, taw ih moisannawk boih pongah tangoenghaih na zok boeh; nang loe zok hoiah avak ueloe, na hing thung maiphu to na caa tih boeh.
15 Èmi yóò sì fi ọ̀tá sí àárín ìwọ àti obìnrin náà, àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà; òun yóò fọ́ orí rẹ, ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”
Nang hoi nongpata salak, na tii hoi nongpata ih atii salak misa ah ka suek han; anih mah na lu to ati tih, nang mah anih ih khok tahmawh to na patuk pae tih, tiah a naa.
16 Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé, “Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ; ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ. Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí, òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”
Nongpata khaeah, Zok na pomh naah nathaih kating ai kang pungsak han, kana pauephaih hoiah caa na sah tih; na sava koehhaih palung loe boeng mak ai, anih mah na uk tih, tiah a naa.
17 Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’ “Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ; nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
Adam khaeah, Na zu ih lok to na tahngaih moe, Caa hmah, tiah kang thuih ih thingthai to na caak boeh pongah, nang pongah long loe tangoenghaih zok boeh; na hing thung patanghaih hoi toksak naah ni buh na caa tih boeh.
18 Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ, ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.
Nang han soekhring congca kam prawksak han; lawk ih aannawk to na caa tih;
19 Nínú òógùn ojú rẹ ni ìwọ yóò máa jẹun títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀, nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá; erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ, ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”
long hoiah nang zoh baktih toengah, long ah nam laem let ai karoek to, na mikhmai ah angsatui long naah ni buh na caa vop tih; maiphu ah na oh pongah, maiphu ah nam laem let tih, tiah a naa.
20 Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.
Kahing kaminawk boih ih amno ah oh pongah, Adam mah a zu to Evi, tiah ahmin phui.
21 Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n.
Angraeng Sithaw mah Adam hoi a zu hanah, moihin kahni to sak pae moe, angkhuksak.
22 Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.”
Angraeng Sithaw mah, Khenah, kami loe kasae kahoih panoekhaih bang ah, aicae thung ih kami maeto baktiah oh toeng boeh; vaihi anih mah ban payangh ueloe, dungzan ah hing hanah thingthai to pakhrik pacoengah, caa moeng tih, tiah thuih.
23 Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá.
To pongah angmah tacawthaih long ah toksak hanah, Angraeng Sithaw mah kami to Eden takha thung hoiah haek ving.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.
Kami to haek pacoengah, hinghaih thingkung loklam to toep hanah, Cherubimnawk hoi ahnuk ahma angmet thaih hmai sumsen to Eden takha ni angyae bang ah a suek.

< Genesis 3 >