< Genesis 29 >

1 Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn.
Apoi Iacob a mers în călătoria sa şi a mers în ţara poporului din est.
2 Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi.
Şi a privit şi, iată, o fântână în câmp şi, iată, acolo erau trei turme de oi culcate lângă ea; căci din acea fântână adăpau turmele; şi o piatră mare era peste gura fântânii.
3 Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.
Şi acolo erau toate turmele adunate şi au rostogolit piatra de la gura fântânii şi au adăpat oile şi au pus piatra din nou peste gura fântânii la locul ei.
4 Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?” Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”
Şi Iacob le-a spus: Fraţii mei, de unde sunteţi voi? Iar ei au spus: Noi suntem din Haran.
5 Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”
Iar el le-a spus: Îl cunoaşteţi pe Laban, fiul lui Nahor? Iar ei au spus: Îl cunoaştem.
6 Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”
Iar el le-a spus: Este el bine? Iar ei au spus: Este bine şi, iată, Rahela, fiica lui, vine cu oile.
7 Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”
Iar el a spus: Iată, ziua este încă mare, nici nu este timpul ca vitele să fie adunate; adăpaţi oile şi mergeţi şi le paşteţi.
8 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”
Iar ei au spus: Nu putem, până când toate turmele sunt adunate şi când ei rostogolesc piatra de la gura fântânii, atunci adăpăm oile.
9 Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.
Şi în timp ce el încă vorbea cu ei, Rahela a venit cu oile tatălui ei, pentru că ea le păzea.
10 Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi.
Şi s-a întâmplat, când Iacob a văzut-o pe Rahela, fiica lui Laban, fratele mamei sale, şi oile lui Laban, fratele mamei sale, că Iacob s-a apropiat şi a rostogolit piatra de la gura fântânii şi a adăpat turma lui Laban, fratele mamei sale.
11 Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.
Şi Iacob a sărutat pe Rahela şi el şi-a ridicat vocea şi a plâns.
12 Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.
Şi Iacob a povestit Rahelei că el era fratele tatălui ei şi că el era fiul Rebecăi; şi ea a alergat şi a povestit tatălui ei.
13 Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un.
Şi s-a întâmplat, când Laban a auzit veştile despre Iacob, fiul surorii lui, că el a alergat să îl întâlnească şi l-a îmbrăţişat şi l-a sărutat şi l-a adus în casa lui. Şi el a povestit lui Laban toate aceste lucruri.
14 Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.” Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,
Şi Laban i-a spus: Tu eşti cu adevărat osul meu şi carnea mea. Şi a rămas cu el o lună de zile.
15 Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”
Şi Laban i-a spus lui Iacob: Pentru că tu eşti fratele meu ar trebui de aceea să îmi serveşti degeaba? Spune-mi, ce va fi plata ta.
16 Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli.
Şi Laban avea două fiice; numele celei mai în vârstă era Leea şi numele celei mai tinere era Rahela.
17 Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.
Leea era slabă de ochi; dar Rahela era frumoasă la statură şi plăcută la vedere.
18 Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”
Şi Iacob a iubit-o pe Rahela; şi a spus: Te voi servi şapte ani pentru Rahela, fiica ta mai tânără.
19 Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.”
Şi Laban a spus: Este mai bine să ţi-o dau ţie decât să o dau altui bărbat; rămâi la mine.
20 Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.
Şi Iacob a servit şapte ani pentru Rahela; şi aceştia i-au părut doar câteva zile, din cauza dragostei pe care o avea pentru ea.
21 Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”
Şi Iacob i-a spus lui Laban: Dă-mi soţia mea, pentru că zilele mi s-au împlinit, ca să intru la ea.
22 Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n.
Şi Laban a strâns împreună toţi bărbaţii locului şi a făcut un ospăţ.
23 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀.
Şi s-a întâmplat, în timpul serii, că el a luat pe Leea fiica sa, şi i-a adus-o; iar el a intrat la ea.
24 Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.
Şi Laban a dat fiicei sale, Leea, pe Zilpa, roaba lui, ca servitoare.
25 Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”
Şi s-a întâmplat, că dimineaţa, iată, era Leea; şi i-a spus lui Laban: Ce este aceasta ce mi-ai făcut? Nu ţi-am servit pentru Rahela? Şi de ce m-ai înşelat?
26 Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Şi Laban a spus: Nu trebuie să fie făcut astfel în ţara noastră, a da pe cea mai tânără înaintea celei întâi născute.
27 Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”
Împlineşte săptămâna ei şi ţi-o vom da şi pe aceasta pentru serviciul pe care mi-l vei face încă alţi şapte ani.
28 Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya.
Şi Iacob a făcut astfel şi a împlinit săptămâna ei; iar el i-a dat şi pe Rahela, fiica sa, de soţie.
29 Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́.
Şi Laban a dat Rahelei, fiica sa, pe Bilha, roaba lui, să fie roaba ei.
30 Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.
Iar el a intrat şi la Rahela şi a iubit pe Rahela şi mai mult decât pe Leea şi i-a servit încă alţi şapte ani.
31 Nígbà tí Olúwa sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn.
Şi când DOMNUL a văzut că Leea era urâtă de el, a deschis pântecele ei; dar Rahela era stearpă.
32 Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Olúwa ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”
Şi Leea a rămas însărcinată şi a născut un fiu şi i-a pus numele Ruben, căci ea a spus: Cu adevărat DOMNUL a privit la necazul meu; de aceea acum soţul meu mă va iubi.
33 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé, “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”
Şi a rămas însărcinată din nou şi a născut un fiu şi a spus: Pentru că DOMNUL a auzit că eu eram urâtă de soţul meu, mi-a dat de aceea şi acest fiu; şi i-a pus numele Simeon.
34 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.
Şi a rămas însărcinată din nou şi a născut un fiu şi a spus: Acum, de această dată, soţul meu va fi lipit de mine, pentru că i-am născut lui trei fii; de aceea numele lui a fost chemat Levi.
35 Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.
Şi a rămas însărcinată din nou şi a născut un fiu; şi a spus: Acum voi lăuda pe DOMNUL; de aceea i-a pus numele Iuda; şi a încetat să nască.

< Genesis 29 >