< Genesis 29 >

1 Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn.
Wtedy Jakub wyruszył w drogę i poszedł do ziemi ludów Wschodu.
2 Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi.
I spojrzał, a oto w polu studnia i trzy stada owiec leżących przy niej. Z tej studni pojono bowiem stada, a wielki kamień [przykrywał] wierzch tej studni.
3 Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.
A gdy schodziły się wszystkie stada, odsuwano kamień z wierzchu studni i pojono owce. Potem znów zasuwano kamień na wierzch studni na jego miejsce.
4 Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?” Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”
Jakub zapytał ich: Moi bracia, skąd jesteście? I odpowiedzieli: Jesteśmy z Charanu.
5 Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”
Zapytał ich: Czy znacie Labana, syna Nachora? Odpowiedzieli: Znamy.
6 Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”
Potem zapytał: Czy dobrze się miewa? A oni odpowiedzieli: Dobrze. Oto właśnie jego córka Rachela nadchodzi ze stadem.
7 Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”
Wtedy powiedział: Oto jeszcze jest jasny dzień i nie czas zganiać stada. Napójcie owce i idźcie, popaście je.
8 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”
Oni odpowiedzieli: Nie możemy, dopóki nie zbiorą się wszystkie stada i nie odsuną kamienia z wierzchu studni. Wtedy napoimy stada.
9 Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.
A gdy jeszcze tak z nimi rozmawiał, nadeszła Rachela z owcami swego ojca, bo [je] pasła.
10 Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi.
I gdy Jakub ujrzał Rachelę, córkę Labana, brata swej matki, z owcami Labana, brata swej matki, podszedł, odsunął kamień z wierzchu studni i napoił owce Labana, brata swojej matki.
11 Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.
Potem Jakub pocałował Rachelę i głośno zapłakał.
12 Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.
I Jakub powiedział Racheli, że jest bratem jej ojca i że jest synem Rebeki. Ona pobiegła więc i oznajmiła to swemu ojcu.
13 Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un.
A gdy Laban usłyszał wieść o Jakubie, synu swojej siostry, wybiegł mu naprzeciw, objął go, ucałował i zaprowadził do swego domu. A [on] opowiedział Labanowi o wszystkim.
14 Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.” Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,
Wtedy Laban powiedział mu: Ty naprawdę [jesteś] z moich kości i z mojego ciała. I [Jakub] mieszkał u niego przez cały miesiąc.
15 Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”
Potem Laban powiedział do Jakuba: Czyż dlatego, że jesteś moim bratem, będziesz mi służyć za darmo? Powiedz mi, jaka [ma być] twoja zapłata.
16 Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli.
A Laban miał dwie córki: starsza miała na imię Lea, młodsza zaś Rachela.
17 Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.
Lea miała czułe oczy, Rachela zaś była piękna i miła dla oka.
18 Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”
Jakub kochał Rachelę i powiedział: Będę ci służył siedem lat za twoją młodszą córkę Rachelę.
19 Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.”
Laban odpowiedział: Lepiej mi ją dać tobie niż innemu mężczyźnie. Zamieszkaj ze mną.
20 Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.
I Jakub służył za Rachelę siedem lat, które wydawały mu się jak kilka dni, bo ją kochał.
21 Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”
Potem Jakub powiedział do Labana: Daj mi moją żonę, bo wypełniły się moje dni, abym z nią obcował.
22 Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n.
Wtedy Laban zebrał wszystkich mężczyzn tego miejsca i wyprawił ucztę.
23 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀.
A gdy nastał wieczór, wziął swoją córkę Leę i wprowadził ją do [Jakuba], a on obcował z nią.
24 Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.
Laban dał też swoją służącą Zilpę swej córce Lei za służącą.
25 Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”
Rano okazało się, że to była Lea. Powiedział więc do Labana: Cóż mi zrobiłeś? Czy nie za Rachelę ci służyłem? Dlaczego mnie oszukałeś?
26 Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Laban odpowiedział: Nie ma u nas zwyczaju, aby młodszą wydawać za mąż przed starszą.
27 Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”
Dopełnij jej tydzień, a dam ci i tę za służbę, którą mi odsłużysz drugie siedem lat.
28 Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya.
I Jakub tak zrobił, i dopełnił jej tydzień. Potem [Laban] dał mu swoją córkę Rachelę za żonę.
29 Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́.
Laban dał też swoją służącą Bilhę swej córce Racheli za służącą.
30 Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.
Wtedy [Jakub] obcował też z Rachelą i kochał Rachelę bardziej niż Leę, [i] służył mu jeszcze drugie siedem lat.
31 Nígbà tí Olúwa sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn.
A gdy PAN widział, że Lea była znienawidzona, otworzył jej łono. Rachela zaś [była] bezpłodna.
32 Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Olúwa ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”
Lea poczęła więc i urodziła syna, i nadała mu imię Ruben. Powiedziała bowiem: PAN naprawdę wejrzał na moje utrapienie. Dlatego teraz mój mąż będzie mnie kochać.
33 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé, “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”
Gdy znów poczęła i urodziła syna, powiedziała: PAN usłyszał, że byłam znienawidzona. Dlatego dał mi także tego [syna]. I nadała mu imię Symeon.
34 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.
Potem znów poczęła i urodziła syna, i powiedziała: Tym razem mój mąż przywiąże się do mnie, bo urodziłam mu trzech synów. Dlatego nadała mu imię Lewi.
35 Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.
Gdy jeszcze raz poczęła i urodziła syna, powiedziała: Teraz już będę chwalić PANA. Dlatego nadała mu imię Juda. I przestała rodzić.

< Genesis 29 >