< Genesis 29 >

1 Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn.
Tedy Jakób wstawszy, poszedł do ziemi, mieszkających na wschód słońca.
2 Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi.
I ujrzał studnią na polu, i trzy stada owiec leżących przy niej; bo z onej studni napawano stada, a kamień wielki był na wierzchu onej studni.
3 Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.
Albowiem schodziły się tam wszystkie stada, i odwalono kamień z wierzchu studni, a napawano stada; potem zaś kładziono kamień na wierzch studni na miejsce jego.
4 Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?” Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”
Tedy rzekł do nich Jakób: Bracia moi, skądeście? i odpowiedzieli: Z Haranu jesteśmy.
5 Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”
I rzekł do nich Jakób: A znacie Labana, syna Nachorowego? odpowiedzieli: Znamy.
6 Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”
Zatem rzekł do nich: A dobrze się ma? a oni odpowiedzieli: Dobrze; a oto, Rachel córka jego idzie z stadem.
7 Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”
Tedy rzekł: Oto, jeszcze dosyć dnia, i nie czas zganiać stada; napójcież owce, a idźcie, popaście ich.
8 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”
A oni odpowiedzieli: Nie możemy, ażby się zebrały wszystkie stada, i odwalony był kamień z wierzchu studni, abyśmy napoili stada.
9 Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.
A gdy to jeszcze mówił z nimi, Rachel nadeszła z owcami ojca swego, bo je ona pasła.
10 Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi.
I gdy ujrzał Jakób Rachelę, córkę Labana, brata matki swojej, z owcami Labana, brata matki swej: tedy przystąpił Jakób, i odwalił kamień z wierzchu studni, a napoił owce Labana, brata matki swojej.
11 Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.
I pocałował Jakób Rachelę, i podniósłszy głos swój płakał.
12 Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.
I oznajmił Jakób Racheli, że jest bratem ojca jej, a iż jest synem Rebeki: a ona bieżawszy opowiedziała to ojcu swemu.
13 Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un.
A gdy usłyszał Laban wieść o Jakóbie, synu siostry swojej, wybieżał przeciwko niemu, i obłapił go, a pocałowawszy, wwiódł do domu swego. A on Labanowi powiedział o wszystkiem.
14 Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.” Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,
I rzekł mu Laban: Zaisteś ty jest kość moja, i ciało moje. I mieszkał u niego przez cały miesiąc.
15 Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”
Potem rzekł Laban do Jakóba: Izali, żeś mi brat, służyć mi będziesz darmo? powiedz mi, jaką ma być zapłata twoja.
16 Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli.
A miał Laban dwie córki: imię starszej Lija, a imię młodszej Rachel.
17 Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.
Ale Lija była chorych oczu, a Rachel zaś pięknego oblicza, i wdzięczna na wejrzeniu.
18 Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”
Miłował tedy Jakób Rachelę, i rzekł: Będęć służył siedem lat za Rachelę, córkę twoję młodszą.
19 Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.”
Odpowiedział Laban: Lepiej że ją tobie dam, niźlibym ją miał dać mężowi innemu: mieszkajże ze mną.
20 Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.
I służył Jakób za Rachelę siedem lat, i zdał mu się ten czas jako kilka dni, przeto że ją miłował.
21 Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”
Potem rzekł Jakób do Labana: Daj mi żonę moję, ponieważ się wypełniły dni moje, abym wszedł do niej.
22 Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n.
Tedy wezwawszy Laban wszystkich mężów miejsca onego, sprawił ucztę.
23 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀.
A gdy był wieczór, wziął Liję, córkę swoję, i wwiódł ją do niego, a Jakób wszedł do niej.
24 Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.
Dał też Laban i Zelfę, dziewkę swoję, Lii, córce swej, za służebnicę.
25 Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”
A gdy było rano, poznał Jakób, że to Lija, i rzekł do Labana: Cóżeś mi to uczynił? Izalim ja nie za Rachelę tobie służył? czemużeś mię tedy oszukał?
26 Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
I odpowiedział Laban: Nie jest to w zwyczaju u nas, aby miano wydawać za mąż młodszą przed starszą.
27 Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”
Wytrwaj z tą tydzień, a dam ci i tę za służbę, którą mi będziesz służył jeszcze drugie siedem lat.
28 Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya.
I uczynił tak Jakób, i wypełnił z tą tydzień; potem dał mu Laban Rachelę, córkę swoję, za żonę.
29 Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́.
Dał też Laban Racheli, córce swej, Balę dziewkę swoję; dał jej za służebnicę.
30 Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.
Tedy też wszedł Jakób do Racheli, i miłował Rachelę bardziej niż Liję, a służył mu jeszcze drugie siedem lat.
31 Nígbà tí Olúwa sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn.
A widząc Pan, że nienawidził Liję, otworzył żywot jej; a Rachel niepłodna była.
32 Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Olúwa ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”
Tedy począwszy Lija porodziła syna, i nazwała imię jego Ruben, bo rzekła: Zaiste wejrzał Pan na utrapienie moje; a tak teraz miłować mię będzie mąż mój.
33 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé, “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”
I zasię poczęła, i porodziła syna, a rzekła: Zaiste usłyszał Pan, żem ja była w nienawiści, przetoż dał mi też i tego; i nazwała imię jego Symeon.
34 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.
Potem jeszcze poczęła, i porodziła syna, i rzekła: I tym razem przyłączy się mąż mój do mnie, bom mu urodziła trzech synów; przetoż nazwała imię jego Lewi.
35 Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.
Nad to jeszcze poczęła, i porodziła syna, i rzekła: Teraz już chwalić będę Pana; przetoż nazwała imię jego Juda, i przestała rodzić.

< Genesis 29 >