< Genesis 29 >

1 Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn.
UJakobe wasephakamisa inyawo zakhe, waya elizweni labantwana bempumalanga.
2 Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi.
Wasebona, khangela-ke, umthombo emmangweni, khangela-ke lapho, imihlambi emithathu yezimvu yayilele kuwo, ngoba kulowomthombo banathisa imihlambi; kwakukhona ilitshe elikhulu emlonyeni womthombo.
3 Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.
Njalo yonke imihlambi yabuthelwa khona, sebeligiqile ilitshe lisuka emlonyeni womthombo banathisa izimvu, basebebuyisela ilitshe emlonyeni womthombo endaweni yalo.
4 Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?” Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”
UJakobe wasesithi kibo: Bazalwane bami, livela ngaphi? Basebesithi: Sivela eHarani.
5 Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”
Wasesithi kibo: Liyamazi yini uLabani indodana kaNahori? Basebesithi: Siyamazi.
6 Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”
Wasesithi kibo: Uyaphila yini? Basebesithi: Uphilile; khangela-ke, uRasheli indodakazi yakhe, uyeza lezimvu.
7 Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”
Wasesithi: Khangelani, kusesemini enkulu, kayisiso isikhathi sokuthi izifuyo zibuthaniswe; nathisani izimvu, lihambe lizidlise.
8 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”
Basebesithi: Singeke, kuze kubuthaniswe imihlambi yonke, bagiqe-ke ilitshe lisuke emlonyeni womthombo; khona sizanathisa izimvu.
9 Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.
Esakhuluma labo, uRasheli wafika lezimvu, ezingezikayise, ngoba wayengumelusikazi.
10 Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi.
Kwasekusithi uJakobe ebona uRasheli indodakazi kaLabani umalumakhe lezimvu zikaLabani umalumakhe, uJakobe wasondela, waligiqa ilitshe lasuka emlonyeni womthombo, wazinathisa izimvu zikaLabani umalumakhe.
11 Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.
UJakobe wasemanga uRasheli, waphakamisa ilizwi lakhe wakhala izinyembezi.
12 Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.
UJakobe wasemazisa uRasheli ukuthi ungumfowabo kayise lokuthi uyindodana kaRebeka. Wasegijima, wamazisa uyise.
13 Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un.
Kwasekusithi uLabani esezwile umbiko kaJakobe indodana kadadewabo, wagijima ukuyamhlangabeza, wamgona, wamanga, wamngenisa endlini yakhe. UJakobe waselandisela uLabani zonke lezizinto.
14 Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.” Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,
ULabani wasesithi kuye: Isibili ulithambo lami lenyama yami. Wahlala laye inyanga yonke.
15 Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”
ULabani wasesithi kuJakobe: Njengoba ungumfowethu, usuzangisebenzela mahala yini? Ngitshela ukuthi umholo wakho uzakuba yini?
16 Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli.
Njalo uLabani wayelamadodakazi amabili, ibizo lenkulu linguLeya lebizo lencinyane linguRasheli.
17 Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.
Kodwa uLeya wayelamehlo abuthakathaka, kodwa uRasheli wayemuhle ngesimo, njalo wayemuhle ngokukhangeleka.
18 Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”
UJakobe wasemthanda uRasheli. Wathi: Ngizakusebenzela iminyaka eyisikhombisa ngoRasheli indodakazi yakho encane.
19 Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.”
ULabani wasesithi: Kungcono ukuthi ngimnike wena kulokuthi ngimnike enye indoda; hlala lami.
20 Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.
UJakobe wasemsebenzela uRasheli iminyaka eyisikhombisa; yaba emehlweni akhe njengensuku ezinlutshwana, ngenxa yokumthanda kwakhe.
21 Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”
UJakobe wasesithi kuLabani: Ngipha umkami, ngoba insuku zami sezigcwalisekile, ukuthi ngingene kuye.
22 Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n.
ULabani wasebuthanisa wonke amadoda aleyondawo, wenza idili.
23 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀.
Kwasekusithi kusihlwa wathatha uLeya indodakazi yakhe wamusa kuye, wasengena kuye.
24 Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.
ULabani wasemnika uZilipa incekukazi yakhe, kuLeya indodakazi yakhe, abe yincekukazi.
25 Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”
Kwasekusithi ekuseni, khangela-ke, nguLeya; ngakho wathi kuLabani: Kuyini lokhu okwenze kimi? Kangimsebenzelanga uRasheli kuwe yini? Pho, ungikhohliseleni?
26 Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
ULabani wasesithi: Kakwenziwa njalo endaweni yakithi ukupha omncinyane ngaphambi kwengqabutho.
27 Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”
Gcwalisa iviki yalo, besesikunika lalowayana, ngomsebenzi ozawusebenza lami futhi eminye iminyaka eyisikhombisa.
28 Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya.
UJakobe wasesenza njalo; wagcwalisa iviki yalo; wasemnika uRasheli indodakazi yakhe ukuba ngumkakhe.
29 Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́.
ULabani wasenika uRasheli indodakazi yakhe uBiliha incekukazi yakhe, abe yincekukazi kuye.
30 Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.
Wasengena lakuRasheli; wamthanda njalo uRasheli kuloLeya, wasesebenza laye futhi eminye iminyaka eyisikhombisa.
31 Nígbà tí Olúwa sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn.
Lapho iNkosi isibona ukuthi uLeya wayezondwa, yavula isizalo sakhe, kodwa uRasheli wayeyinyumba.
32 Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Olúwa ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”
ULeya wasethatha isisu, wazala indodana, wayitha ibizo layo uRubeni, ngoba wathi: Ngoba iNkosi ibonile inhlupheko yami; ngakho khathesi indoda yami izangithanda.
33 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé, “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”
Wasebuya wathatha isisu, wazala indodana, wathi: Njengoba iNkosi izwile ukuthi ngiyazondwa, inginike lale; wayitha ibizo layo uSimeyoni.
34 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.
Wasebuya wathatha isisu, wazala indodana; wathi: Khathesi ngalesisikhathi indoda yami izazihlanganisa lami, ngoba ngiyizalele amadodana amathathu; ngalokhu wabiza ibizo layo uLevi.
35 Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.
Wasebuya wathatha isisu, wazala indodana; wathi: Ngalesisikhathi ngizadumisa iNkosi; ngakho wayitha ibizo layo uJuda; wasesima ukuzala.

< Genesis 29 >