< Genesis 29 >

1 Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn.
Ya: igobe da asili, eso maba la: idi soge amoga asi.
2 Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi.
E da hano nasu uli dou gisi soge ganodini diala, amoga doaga: i. Amo uli dogoi gadenene, sibi gilisisu udiana dialebe ba: i. Sibi gilisisu da amo uli dogoiga hano nasu. Uli dogoi da gele bagadega ga: i dagoi.
3 Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.
Hou da agoane galu. Sibi gilisisu da uli dogoiga doaga: laloba, sibi ouligisu dunu da gele bagade amo bebesole, hano nasu amo sibima olelesu. Hano nanu, sibi ouligisu da uli dogoi gele bagadega bu ga: su.
4 Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?” Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”
Ya: igobe da sibi ouligisu dunuma amane adole ba: i, “Dilia da habidili misibila: ?” Ilia da bu adole i, “Ninia da Halane soge dunu.”
5 Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”
E da bu adole ba: i, “Dilia da La: iba: ne, Na: iho ea aowa amo dawa: bela: ?” “Ma! Ninia dawa: !” ilia amane sia: i.
6 Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”
Ya: igobe amane adole ba: i, “E da hahawane esalabala?” Ilia bu adole i, “E da hahawane esala! Ba: ma! Idiwi La: isele, La: iba: ne ea uda mano a: fini da ea sibi gilisisu oule manebe goea!”
7 Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”
Ya: igobe da amane sia: i, “Wali da esomogoa fawane. Amaiba: le, sibi amo diasuga gilisimu da hamedei. Dilia sibi ilima hano dili ianu, bu gisi sogega oule masunu da defea.”
8 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”
Ilia da bu adole i, “Amai da hame hamomu! Sibi gilisisu huluane da doaga: sea fawane, ninia da gele bagade bebesole, sibi ilima hano dili imunu.”
9 Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.
Ya: igobe da ilima sia: daloba, La: isele da ea sibi gilisisu oule misini, doaga: i dagoi.
10 Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi.
Ya: igobe da La: isele amo ea daiya La: iba: ne ea sibi oule manebe ba: loba, e da hano nasu uli dogoi amoga asili, gele bebesole, sibi ilima hano dili i.
11 Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.
Amalalu, e da La: isele amo nonogoi, amola hahawane bagadeba: le, dinanu.
12 Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.
E da La: iselema amane adole i, “Na da dia ada esoa: bi, Lebega ea mano.” La: isele da ea ada amo adomusa: hehenane asi.
13 Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un.
La: iba: ne da esoa: bi Ya: igobe misi dagoi amo nababeba: le, hehenane, ema doaga: le, nonogone, hi diasuga oule asi. Ya: igobe da ea hou huluane ema olelei.
14 Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.” Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,
Amalalu, La: iba: ne da amane sia: i, “Dafawane! Di da na fi dunu maga: me afae amoga hamoi.” Ya: igobe da oubi afae amoga ea diasuga esalu.
15 Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”
La: iba: ne da Ya: igobema amane sia: i, “Di da na fi dunuba: le na hawa: hamosu udigili hamomu da defea hame galebe. Di da bidi habodayane lama: bela: ?”
16 Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli.
La: iba: ne da uda mano aduna esala. Magobo mano da Lia amola eno da La: isele.
17 Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.
Lia ea si da gasa hame galu. Be La: isele ea da: i hodo da noga: iwane ba: i.
18 Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”
Ya: igobe da La: iselema bagade magesa: i. Amaiba: le e da La: iba: nema amane sia: i, “Na da La: isele amo lamusa: , ode fesuale dima hawa: hamomu da defeala: ?”
19 Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.”
La: iba: ne da bu adole i, “Na da dunu enoma imunu higa: i. Dima fawane imunu. Nama ouesaloma!”
20 Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.
Ya: igobe da ode fesuale La: isele lama: ne hawa: hamosu. E da ema bagade asigiba: le, amo ode da eso bagahame defele ba: i.
21 Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”
Amalalu, Ya: igobe da La: iba: nema amane sia: i, “Na ode da gidigi dagoi. Na da dia mano lamu galebe.”
22 Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n.
Amaiba: le, La: iba: ne da uda lasu lolo Nasu bagade hamoi. E da dunu huluane misa: ne sia: i.
23 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀.
Be gasia, e da La: isele fisili, Lia amo Ya: igobema oule misi. Amalalu, Ya: igobe da Lia amo gilisili golai.
24 Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.
(La: iba: ne da ea udigili hawa: hamosu a: fini Siliba amo Lia hi hawa: hamomusa: gini i dagoi.)
25 Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”
Golale hahabe, Ya: igobe da uda da ema gilisili golai da La: isele hame be Lia ba: i. E da La: iba: nema asili amane sia: i, “Di da abuli amo hou nama hamobela: ? Na da La: isele lamusa: hawa: hamoi dagoi. Di da abuliba: le nama ogogobela: ?”
26 Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
La: iba: ne da bu adole i, “Ninia hou guiguda: da ninia magobo uda mano bisili dunuga lama: ne iaha. Fa: no eno uda mano iaha.
27 Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”
Be uda lasu lolo nasu hi afae da dagosea, defea, na da La: isele amola dima imunu. Be amo lama: ne, di da na hawa: hamosu ode fesuale eno hamoma.”
28 Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya.
Ya: igobe da amo hamomu sia: i. Amalalu, hi afae aligili, La: iba: ne da ea mano La: isele amo ema i.
29 Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́.
(La: iba: ne da ea udigili hawa: hamosu a: fini ea dio amo Biliha amo La: isele fidimusa: i.)
30 Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.
Ya: igobe da La: isele amo gilisili golai. Ea magesa: i hou ema da ea asigi hou Lia ema baligi dagoi. Amalalu, e da La: iba: ne ea hawa: hamosu ode fesuale eno hamoi.
31 Nígbà tí Olúwa sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn.
Hina Gode da Ya: igobe ea hou amo La: iselema bagade asigi amola Liama fonobahadi asigi amo ba: beba: le, Gode da Liama mano lama: ne logo fodoi. Be La: isele da aligime esalu.
32 Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Olúwa ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”
Lia da abula agui, dunu mano lalelegei. E amane sia: i, “Hina Gode da na se nabasu ba: i dagoi. Wali nagoa da nama asigimu.” Amaiba: le, e da dio asuli amo Liubene (Se Nabasu Ba: i)
33 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé, “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”
Amalalu, e da bu eno abula agui ba: i. Dunu mano eno da lalelegele, Lia da amane sia: i, “Hina Gode da Ya: igobe da nama hame asigi amo nababeba: le, mano nama i.” Amaiba: le, amo manoma e da Simione (Nabasu dunu) dio asuli.
34 Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.
E da bu eno abula agui. Dunu mano eno lai. E amane sia: i, “Wali na da dunu mano udiana laiba: le, nagoa da nama la: gi dagoi ba: mu.” Amaiba: le, e da amo manoma Lifai (La: gi) dio asuli.
35 Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.
Amalalu, e da abula agui, dunu mano eno lai. E da amane sia: i, “Wali na da Hina Godema nodomu.” Amaiba: le, e da amo manoma Yuda (Nodosu) dio asuli. Amalalu, e da mano lasu yolesi.

< Genesis 29 >