< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Тада Исак дозва Јакова, и благослови га, и заповеди му и рече: Немој да се ожениш којом између кћери хананејских.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Устани, иди у Падан-Арам у дом Ватуила оца матере своје, и оданде се ожени између кћери Лавана ујака свог.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
А Бог Свемогући да те благослови, и да ти да велику породицу и умножи те, да од тебе постане мноштво народа,
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
И да ти да благослов Аврамов, теби и семену твом с тобом, да наследиш земљу у којој си дошљак, коју Бог даде Авраму.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
Тако оправи Исак Јакова, и он пође у Падан-Арам к Лавану сину Ватуила Сирина, брату Ревеке матере Јаковљеве и Исавове.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
А Исав виде где Исак благослови Јакова и оправи га у Падан-Арам да се оданде ожени, и где благосиљајући га заповеди му и рече: Немој да се ожениш којом између кћери хананејских,
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
И где Јаков послуша оца свог и матер своју, и отиде у Падан-Арам;
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
И виде Исав да кћери хананејске нису по вољи Исаку оцу његовом.
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
Па отиде Исав к Исмаилу, и узе за жену преко жена својих Маелету, кћер Исмаила сина Аврамовог, сестру Навеотову.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
А Јаков отиде од Вирсавеје идући у Харан.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
И дође на једно место, и онде заноћи, јер сунце беше зашло; и узе камен на оном месту, и метну га себи под главу, и заспа на оном месту.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
И усни, а то лестве стајаху на земљи а врхом тицаху у небо, и гле, анђели Божји по њима се пењаху и силажаху;
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
И гле, на врху стајаше Господ, и рече: Ја сам Господ Бог Аврама оца твог и Бог Исаков; ту земљу на којој спаваш теби ћу дати и семену твом;
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
И семена ће твог бити као праха на земљи, те ћеш се раширити на запад и на исток и на север и на југ, и сви народи на земљи благословиће се у теби и у семену твом.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
И ево, ја сам с тобом, и чуваћу те куда год пођеш, и довешћу те натраг у ову земљу, јер те нећу оставити докле год не учиним шта ти рекох.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
А кад се Јаков пробуди од сна, рече: Зацело је Господ на овом месту; а ја не знах.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
И уплаши се, и рече: Како је страшно место ово! Овде је доиста кућа Божја, и ово су врата небеска.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
И уста Јаков ујутру рано, и узе камен што беше метнуо себи под главу, и утврди га за спомен и прели га уљем.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
И прозва оно место Ветиљ, а пре беше име оном граду Луз.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
И учини Јаков завет, говорећи: Ако Бог буде са мном и сачува ме на путу којим идем и да ми хлеба да једем и одела да се облачим,
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
И ако се вратим на миру у дом оца свог, Господ ће ми бити Бог;
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
А камен овај који утврдих за спомен биће дом Божји; и шта ми год даш, од свега ћу десето дати Теби.

< Genesis 28 >