< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Исаак а кемат пе Иаков, л-а бинекувынтат ши й-а дат порунка ачаста: „Сэ ну-ць ей невастэ динтре фетеле луй Канаан.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Скоалэ-те, ду-те ла Падан-Арам, ын каса луй Бетуел, татэл мамей тале, ши я-ць де аколо о невастэ динтре фетеле луй Лабан, фрателе мамей тале.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
Думнезеул чел Атотпутерник сэ те бинекувынтезе, сэ те факэ сэ крешть ши сэ те ынмулцешть, ка сэ ажунӂь о чатэ де нороаде!
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
Сэ-ць дя бинекувынтаря луй Авраам, цие ши семинцей тале ку тине, ка сэ стэпынешть цара ын каре локуешть ка стрэин ши пе каре а дат-о луй Авраам.”
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
Ши Исаак а тримис пе Иаков, каре с-а дус ла Падан-Арам, ла Лабан, фиул луй Бетуел, Арамеул, фрателе Ребекэй, мама луй Иаков ши а луй Есау.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
Есау а вэзут кэ Исаак бинекувынтасе пе Иаков ши-л тримисесе ла Падан-Арам, ка сэ-шь я невастэ де аколо, ши кэ, бинекувынтынду-л, ый дэдусе порунка ачаста: „Сэ ну-ць ей невастэ динтре фетеле луй Канаан.”
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
А вэзут кэ Иаков аскултасе де татэл сэу ши де мама са ши плекасе ла Падан-Арам.
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
Есау а ынцелес астфел кэ фетеле луй Канаан ну-й плэчяу татэлуй сэу Исаак.
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
Ши Есау с-а дус ла Исмаел. Ел а май луат де невастэ, пе лынгэ невестеле пе каре ле авя, пе Махалат, фата луй Исмаел, фиул луй Авраам, ши сора луй Небаиот.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
Иаков а плекат дин Беер-Шеба ши шь-а луат друмул спре Харан.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
А ажунс ынтр-ун лок унде а рэмас песте ноапте, кэч асфинцисе соареле. А луат о пятрэ де аколо, а пус-о кэпэтый ши с-а кулкат ын локул ачела.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
Ши а висат о скарэ резематэ де пэмынт, ал кэрей вырф ажунӂя пынэ ла чер. Ынӂерий луй Думнезеу се суяу ши се коборау пе скара ачея.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
Ши Домнул стэтя дясупра ей ши зичя: „Еу сунт Домнул Думнезеул татэлуй тэу Авраам ши Думнезеул луй Исаак. Пэмынтул пе каре ешть кулкат ци-л вой да цие ши семинцей тале.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
Сэмынца та ва фи ка пулберя пэмынтулуй; те вей ынтинде ла апус ши ла рэсэрит, ла мязэноапте ши ла мязэзи ши тоате фамилииле пэмынтулуй вор фи бинекувынтате ын тине ши ын сэмынца та.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
Ятэ, Еу сунт ку тине; те вой пэзи претутиндень пе унде вей мерӂе ши те вой адуче ынапой ын цара ачаста, кэч ну те вой пэрэси пынэ ну вой ымплини че-ць спун.”
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
Иаков с-а трезит дин сомн ши а зис: „Ку адевэрат, Домнул есте ын локул ачеста, ши еу н-ам штиут.”
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
Й-а фост фрикэ ши а зис: „Кыт де ынфрикошат есте локул ачеста! Аич есте каса луй Думнезеу, аич есте поарта черурилор!”
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
Ши Иаков с-а скулат дис-де-диминяцэ, а луат пятра пе каре о пусесе кэпэтый, а пус-о ка стылп де адучере аминте ши а турнат унтделемн пе вырфул ей.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
А дат локулуй ачестуя нумеле Бетел, дар май ынаинте четатя се кема Луз.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
Иаков а фэкут о журуинцэ ши а зис: „Дакэ ва фи Думнезеу ку мине ши мэ ва пэзи ын тимпул кэлэторией пе каре о фак, дакэ-мь ва да пыне сэ мэнынк ши хайне сэ мэ ымбрак
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
ши дакэ мэ вой ынтоарче ын паче ын каса татэлуй меу, атунч Домнул ва фи Думнезеул меу;
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
пятра ачаста пе каре ам пус-о ка стылп де адучере аминте ва фи каса луй Думнезеу ши Ыць вой да а зечя парте дин тот че-мь вей да.”

< Genesis 28 >