< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Tad Īzaks aicināja Jēkabu un to svētīja un tam pavēlēja un uz to sacīja: tev nebūs sievu ņemt no Kanaāniešu meitām.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Celies, ej uz Mezopotamiju, Betuēļa, savas mātes tēva, namā, un ņem sev sievu no turienes, no Lābana, savas mātes brāļa, meitām.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
Un tas visuvarenais Dievs lai tevi svētī un lai tevi dara auglīgu un lai tevi vairo, ka topi par lielu ļaužu pulku.
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
Un lai viņš tev dod Ābrahāma svētību, tev un tavam dzimumam ar tevi, ka tu vari iemantot to zemi, kur tu esi piemitis, ko Dievs Ābrahāmam ir devis.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
Tā Īzaks atlaida Jēkabu, un tas gāja uz Mezopotamiu pie Lābana, Betuēļa, tā Sīrieša, dēla, Rebekas, Jēkaba un Ēsava mātes, brāļa.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
Kad nu Ēsavs redzēja, ka Īzaks Jēkabu bija svētījis un uz Mezopotamiu sūtījis, no turienes sievu ņemt, un ka viņš to svētījot tam bija pavēlējis sacīdams: tev nebūs sievu ņemt no Kanaāniešu meitām,
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
Un ka Jēkabs savam tēvam un savai mātei bija paklausījis un uz Mezopotamiu aizgājis,
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
Un kad Ēsavs arī redzēja, ka Īzaks, viņa tēvs, tās Kanaāniešu meitas neieredzēja, -
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
Tad Ēsavs gāja pie Ismaēla un ņēma klāt pie savām sievām sev par sievu Maālatu, Ismaēla, Ābrahāma dēla, meitu, Nebajota māsu. -
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
Un Jēkabs aizgāja no Bēršebas un gāja uz Hāranu.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
Un tam gadījās nonākt kādā vietā, tur viņš palika par nakti, jo saule bija nogājusi; un tas ņēma vienu no tās vietas akmeņiem un lika to sev pagalvē un apgūlās tanī vietā.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
Un tas sapņoja, un redzi, trepes bija celtas virs zemes, un viņu virsgals aiztika debesis, un redzi, Dieva eņģeļi pa tām uzkāpa un nokāpa.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
Un redzi, Tas Kungs stāvēja virsgalā un sacīja: Es esmu Tas Kungs, tava tēva Ābrahāma Dievs un Īzaka Dievs; to zemi, kur tu guli, Es došu tev un tavam dzimumam.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
Un tavs dzimums būs kā zemes pīšļi, un tu izplētīsies pret vakariem un pret rītiem, uz ziemeļa pusi un uz dienasvidus pusi, un caur tevi un tavu sēklu visas zemes ciltis taps svētītas.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
Un redzi, Es esmu ar tevi un pasargāšu tevi visur, kur tu noiesi, un pārvedīšu tevi atkal uz šo zemi; jo Es tevi negribu atstāt, tiekams Es izdarīšu, ko Es uz tevi esmu runājis.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
Kad nu Jēkabs no sava miega atmodās, tad tas sacīja: tiešām, Tas Kungs ir šinī vietā, un es to neesmu zinājis.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
Un viņš bijās un sacīja: cik bijājama ir šī vieta! Še ir tiešām Dieva nams un še ir debesu vārti.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
Un Jēkabs cēlās rītā agri un ņēma to akmeni, kas tam bija pagalvē bijis, un to uzcēla par zīmi un tam uzlēja eļļu virsū.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
Un viņš nosauca tās vietas vārdu Bēteli (Dieva nams); bet papriekš tai pilsētai bija Lūza vārds.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
Un Jēkabs solīdamies solījās un sacīja: ja Dievs Tas Kungs būs ar mani un mani pasargās uz šā ceļa, ko es staigāju, un man dos maizi ēst un drēbes ģērbties,
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
Un man liks ar mieru pāriet sava tēva namā, tad Tas Kungs lai man ir par Dievu.
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
Un šim akmenim, ko esmu uzcēlis par zīmi, būs tapt par Dieva namu, un no visa, ko Tu man dosi, es Tev došu desmito tiesu.

< Genesis 28 >