< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Előhívatá azért Izsák Jákóbot, és megáldá őt, és megparancsolá néki és mondá: Ne végy feleséget a Kananeusok leányai közűl.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Kelj fel, menj el Mésopotámiába, Bethuélnek a te anyád atyjának házához, és onnan végy magadnak feleséget, Lábánnak a te anyád bátyjának leányai közűl.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
A mindenható Isten pedig áldjon meg, szaporítson és sokasítson meg téged, hogy népek sokaságává légy;
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
És adja néked az Ábrahám áldását, tenéked, és a te magodnak te veled egybe; hogy örökség szerint bírjad a földet, melyen jövevény voltál, melyet az Isten adott vala Ábrahámnak.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
Elbocsátá azért Izsák Jákóbot, hogy menjen Mésopotámiába Lábánhoz a Siriabeli Bethuél fiához, Rebekának, Jákób és Ézsaú anyjának bátyjához.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
És látá Ézsaú, hogy Izsák megáldotta Jákóbot, és elbocsátotta őt Mésopotámiába, hogy onnan vegyen magának feleséget; és hogy mikor áldja vala, parancsola néki, és monda: Ne végy feleséget a Kananeusok leányai közűl;
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
És hogy Jákób hallgata atyja és anyja szavára, és el is ment Mésopotámiába;
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
És látá Ézsaú, hogy a Kananeusok leányai nem tetszenek Izsáknak az ő atyjának:
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
Elméne Ézsaú Ismáelhez, és feleségűl vevé még az ő feleségeihez Ismáelnek az Ábrahám fiának leányát Mahaláthot, Nebajóthnak húgát.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
Jákób pedig kiindula Beérsebából, és Hárán felé tartott.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
És juta egy helyre, holott meghála, mivelhogy a nap lement vala: és vőn egyet annak a helynek kövei közűl, és feje alá tevé; és lefeküvék azon a helyen.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
És álmot láta: Ímé egy lajtorja vala a földön felállítva, melynek teteje az eget éri vala, és ímé az Istennek Angyalai fel- és alájárnak vala azon.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
És ímé az Úr áll vala azon és szóla: Én vagyok az Úr, Ábrahámnak a te atyádnak Istene, és Izsáknak Istene; ezt a földet a melyen fekszel néked adom és a te magodnak.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
És a te magod olyan lészen mint a földnek pora, és terjeszkedel nyugotra és keletre, északra és délre, és te benned és a te magodban áldatnak meg a föld minden nemzetségei.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
És ímé én veled vagyok, hogy megőrizzelek téged valahova menéndesz, és visszahozzalak e földre; mert el nem hagylak téged, míg be nem teljesítem a mit néked mondtam.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
Jákób pedig fölébredvén álmából, monda: Bizonyára az Úr van e helyen, és én nem tudtam.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
Megrémüle annak okáért és monda: Mily rettenetes ez a hely; nem egyéb ez, hanem Istennek háza, és az égnek kapuja.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
És felkele Jákób reggel, és vevé azt a követ, melyet feje alá tett vala, és oszlopul állítá fel azt, és olajat önte annak tetejére;
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
És nevezé annak a helynek nevét Béthelnek, az előtt pedig Lúz vala annak a városnak neve.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
És fogadást tőn Jákób, mondá: Ha az Isten velem leénd, és megőriz engem ezen az úton, a melyen most járok, és ha ételűl kenyeret s öltözetűl ruhát adánd nékem;
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
És békességgel térek vissza az én atyámnak házához: akkor az Úr leénd az én Istenem;
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
És ez a kő, a melyet oszlopul állítottam fel, Isten háza lészen, és valamit adándasz nékem, annak tizedét néked adom.

< Genesis 28 >