< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
És szólította Izsák Jákobot, megáldotta őt, megparancsolta neki és mondta neki: Ne vegyél feleséget Kánaán leányai közül.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Kerekedj föl, menj el Páddán-Áromba Beszúélnek, anyád atyjának házába és vegyél magadnak onnan feleséget Lábánnak, anyád fivérének leányai közül.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
És Isten, a Mindenható áldjon meg, szaporítson meg, sokasítson meg és legyél népek gyülekezetévé!
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
És adja neked Ábrahám áldását, neked és magzatodnak veled együtt, hogy elfoglaljad tartózkodásod országát, melyet Isten adott Ábrahámnak.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
És elküldte Izsák Jákobot és ez elment Páddán-Áromba, Lábánhoz, az arámi Beszúél fiához, aki fivére volt Rebekának, Jákob és Ézsau anyjának.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
És látta Ézsau, hogy Izsák megáldotta Jákobot, és elküldte őt Páddán-Áromba, hogy vegyen magának onnan feleséget, midőn megáldotta őt és megparancsolta neki, mondván: Ne vegyél feleséget Kánaán leányai közül!
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
Jákob pedig hallgatott atyjára és anyjára, és elment Páddán-Áromba.
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
Látta tehát Ézsau, hogy visszatetszők Kánaán leányai Izsáknak, az ő atyjának szemeiben,
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
azért elment Ézsau Ismáelhez, és elvette Máchálászt, Ismáelnek, Ábrahám fiának a leányát, Nevójósz nővérét, feleségei mellé, magának feleségei mellé, magának feleségül.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
És elment Jákob Beér-Sevából és ment Choronba.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
Elérkezett egy helyre és meghált ott, mert lement a nap, vett a helység köveiből és feje alá tette; és lefeküdt azon a helyen.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
És álmodta, hogy íme létra van állítva a földre, teteje pedig az eget éri; és íme, Isten angyalai föl és alá járnak rajta.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
És íme, az Örökkévaló állt fölötte és mondta: Én vagyok az Örökkévaló, Ábrahámnak, a te atyádnak Istene és Izsák Istene; a földet, melyen te fekszel, neked adom és magzatodnak.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
És magzatod lesz, mint a föld pora és kiterjeszkedsz nyugatra és keletre, északra és délre, és megáldatnak általad a föld összes nemzetségei, meg magzatod által.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
És íme, én veled vagyok és megőrizlek, bárhol jársz és visszahozlak erre a földre, mert nem hagylak el, amíg meg nem tettem, amit neked mondtam.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
És fölébredt Jákob az álmából és mondta: Valóban az Örökkévaló van ezen a helyen és én nem tudtam.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
Félt és mondta: Milyen félelmetes ez a hely; nem más ez, mint Isten háza és ez az ég kapuja.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
És fölkelt Jákob kora reggel, vette a követ, melyet feje alá tett és tette azt oszlopnak és öntött olajat a tetejére.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
És elnevezte azt a helyet Bész-Élnek (Isten háza); azonban Lúz volt a város neve azelőtt.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
És fogadást tett Jákob, mondván: Ha Isten velem lesz, megőriz ezen az úton, melyen én járok és ad nekem kenyeret enni, ruhát felölteni;
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
és visszatérek majd békében atyám házába, akkor az Örökkévaló lesz nekem Istenem,
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
ez a kő pedig, melyet oszlopnak tettem, legyen Isten háza és mindennek, amit nekem adsz, tizedét neked adom.

< Genesis 28 >