< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Tondũ ũcio, Isaaka agĩĩta Jakubu akĩmũrathima na akĩmwatha, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkanahikie mũndũ-wa-nja wa kuuma gũkũ Kaanani.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
Ũkĩra ũthiĩ Padani-Aramu, kwa nyũmba ya Bethueli ithe wa nyũkwa. Wĩcarĩrie mũtumia kuuma kũrĩ airĩtu a Labani, mũrũ wa nyina na nyũkwa.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
Ngai Mwene-Hinya-Wothe arokũrathima na atũme ũciarane mũno na ũingĩhe o nginya ũgaatuĩka rũrĩrĩ rwa andũ aingĩ.
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
Ngai arokũhe kĩrathimo kĩrĩa aaheire Iburahĩmu hamwe na njiaro ciaku, nĩgeetha wĩgwatĩre bũrũri ũyũ ũratũũra rĩu ũrĩ ta mũgeni, o bũrũri ũyũ Ngai eerĩire Iburahĩmu.”
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
Isaaka akĩĩra Jakubu athiĩ, nake agĩthiĩ Padani-Aramu kwa Labani mũrũ wa Bethueli ũrĩa Mũsuriata, mũrũ wa nyina na Rebeka, nyina wa Jakubu na Esaũ.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
Na rĩrĩ, Esaũ nĩamenyire atĩ Isaaka nĩarathimĩte Jakubu na akamũtũma Padani-Aramu akahikanie kuo, na atĩ rĩrĩa aamũrathimire nĩamwathire, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkanahikie mũndũ-wa-nja wa kuuma gũkũ Kaanani.”
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
O na akĩmenya atĩ Jakubu nĩathĩkĩire ithe na nyina na nĩathiĩte Padani-Aramu.
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
Ningĩ Esaũ agĩkũũrana atĩ andũ-a-nja acio a Ahiti matiakenagia ithe, Isaaka;
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
nĩ ũndũ ũcio, agĩthiĩ gwa Ishumaeli na akĩhikia Mahalathu, mwarĩ wa nyina na Nebaiothu, mũirĩtu wa Ishumaeli mũriũ wa Iburahĩmu, akĩmuongerera harĩ atumia arĩa angĩ aarĩ nao.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
Jakubu oima Birishiba aathiire erekeire Harani.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
Na aakinya handũ hana-rĩ, akĩraarĩrĩra ho tondũ riũa nĩ rĩathũĩte. Akĩoya ihiga rĩmwe hau, agĩĩtiira narĩo mũtwe nĩguo akome.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
Nake akĩroota, akĩona ngathĩ ĩturumĩte thĩ, na mũthia wayo ũgakinya igũrũ matu-inĩ, nao araika a Ngai mambataga magĩikũrũkaga nayo.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
Jakubu akĩona Jehova arũgamĩte igũrũ rĩa ngathĩ ĩyo akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ niĩ Jehova, Ngai wa thoguo Iburahĩmu na Ngai wa Isaaka. Bũrũri ũyũ ũkomete nĩngakũhe, wee hamwe na njiaro ciaku.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
Njiaro ciaku ikaingĩha ta rũkũngũ rwa thĩ, na nĩũgatambũrũka na mwena wa ithũĩro, na mwena wa irathĩro, na wa gathigathini, o na wa gũthini. Andũ a mĩhĩrĩga yothe ya thĩ nĩmakarathimwo nĩ ũndũ waku, na nĩ ũndũ wa rũciaro rwaku.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
Na niĩ ndĩ hamwe nawe, na nĩndĩkũmenyagĩrĩra kũrĩa guothe ũrĩthiiaga, na nĩngagũcookia bũrũri ũyũ. Ndigagũtiganĩria nginya ngaahingia maũndũ marĩa ndakwĩrĩra.”
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
Rĩrĩa Jakubu ookĩrire, agĩĩciiria atĩrĩ, “Ti-itherũ Jehova arĩ handũ haha, na ndiikũũĩ.”
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
Agĩkĩigua guoya, akiuga atĩrĩ, “Kaĩ handũ haha nĩ ha kũmakania-ĩ! Haha nĩho nyũmba ya Ngai; na gĩkĩ nĩkĩo kĩhingo kĩa igũrũ-kwa-Ngai.”
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, Jakubu akĩoya ihiga rĩrĩa etiirĩte narĩo mũtwe, akĩrĩrũgamia ta gĩtugĩ, akĩrĩitĩrĩria maguta.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
Agĩcooka agĩĩta handũ hau Betheli, o na gũtuĩka mbere ĩyo itũũra rĩu rĩetagwo Luzu.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
Ningĩ Jakubu akĩĩhĩta na mwĩhĩtwa, akiuga atĩrĩ, “Ngai angĩkorwo hamwe na niĩ, na aamenyerere rũgendo-inĩ rũrũ ndĩrathiĩ, na aaheage irio cia kũrĩa na nguo cia kwĩhumba,
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
nĩguo ngaacooka nyũmba-inĩ ya baba na thayũ-rĩ, Jehova nĩagatuĩka Ngai wakwa,
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
narĩo ihiga rĩĩrĩ ndaarũgamia ta gĩtugĩ rĩgaatuĩka nyũmba ya Ngai, na kĩrĩa o gĩothe ũkaahe, nĩngakũhe gĩcunjĩ gĩa ikũmi.”

< Genesis 28 >