< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
And so Isaac clepide Jacob, and blesside hym, and comaundide to hym, and seide, Nyle thou take a wijf of the kyn of Canaan; but go thou,
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
and walke forth in to Mesopotanye of Sirie, to the hows of Batuel, fadir of thi modir, and take to thee of thennus a wijf of the douytris of Laban, thin vncle.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
Sotheli Almyyti God blesse thee, and make thee to encreesse, and multiplie thee, that thou be in to cumpanyes of puplis;
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
and God yyue to thee the blessyngis of Abraham, and to thi seed aftir thee, that thou welde the lond of thi pilgrymage, which he bihiyte to thi grauntsir.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
And whanne Ysaac hadde left hym, he yede forth, and cam in to Mesopotanye of Sirie, to Laban, the sone of Batuel of Sirie, the brother of Rebecca, his modir.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
Forsothe Esau seiy that his fadir hadde blessid Jacob, and hadde sent him in to Mesopotanye of Sirie, that he schulde wedde a wijf of thennus, and that aftir the blessyng he comaundide to Jacob, and seide, Thou schalt not take a wijf of the douytris of Canaan;
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
and that Jacob obeiede to his fadir `and modir, and yede in to Sirie;
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
also Esau preuyde that his fadir bihelde not gladli the douytris of Canaan.
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
And he yede to Ismael, and weddide a wijf, with out these whiche he hadde bifore, Melech, the douyter of Ismael, sone of Abraham, the sistir of Nabaioth.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
Therfor Jacob yede out of Bersabee, and yede to Aran.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
And whanne he hadde come to sum place, and wolde reste ther inne aftir the goynge doun of the sunne, he took of the stoonus that laien ther, and he puttide vndur his heed, and slepte in the same place.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
And he seiye in sleep a laddir stondynge on the erthe, and the cop ther of touchinge heuene; and he seiy Goddis aungels stiynge vp and goynge doun ther bi,
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
and the Lord fastned to the laddir, seiynge to hym, Y am the Lord God of Abraham, thi fadir, and God of Isaac; Y schal yyue to thee and to thi seed the lond in which thou slepist.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
And thi seed schal be as the dust of erthe, thou schalt be alargid to the eest, and west, and north, and south; and alle lynagis of erthe schulen be blessid in thee and in thi seed.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
And Y schal be thi kepere, whidur euer thou schalt go; and Y schal lede thee ayen in to this lond, and Y schal not leeue no but Y schal fil alle thingis whiche Y seide.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
And whanne Jacob hadde wakyd of sleep, he seide, Verili the Lord is in this place, and Y wiste not.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
And he seide dredynge, Hou worschipful is this place! Here is noon other thing no but the hows of God, and the yate of heuene.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
Therfor Jacob roos eerli, and took the stoon which he hadde put vndur his heed, and reiside in to a title, and helde oile aboue.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
And he clepide the name of that citee Bethel, which was clepid Lusa bifore.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
Also he auowide a vow, and seide, If God is with me, and kepith me in the weie in which Y go, and yyueth to me looues to ete, and clothis to be clothid,
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
and Y turne ayen in prosperite to the hows of my fadir, the Lord schal be in to God to me.
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
And this stoon, which Y reiside in to a title, schal be clepid the hows of God, and Y schal offre tithis to thee of alle thingis whiche thou schalt yyue to me.

< Genesis 28 >