< Genesis 27 >

1 Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Şi s-a întâmplat, pe când Isaac era bătrân şi ochii săi erau atât de slabi încât nu mai putea să vadă, că a chemat pe Esau, fiul său cel mai în vârstă, şi i-a spus: Fiul meu; iar el i-a spus: Iată-mă.
2 Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
Şi a spus: Iată acum, sunt bătrân, nu ştiu ziua morţii mele;
3 Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
De aceea acum, ia, te rog, armele tale, tolba ta şi arcul tău şi du-te afară în câmp şi ia-mi ceva vânat;
4 Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
Şi fă-mi mâncare gustoasă, aşa cum îmi place, şi adu-o la mine ca să mănânc; ca sufletul meu să te binecuvânteze înainte să mor.
5 Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
Şi Rebeca a auzit când Isaac a vorbit lui Esau, fiul său. Şi Esau a mers la câmp să vâneze vânat şi să îl aducă.
6 Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
Şi Rebeca i-a vorbit lui Iacob, fiul ei, spunând: Iată, am auzit pe tatăl tău vorbindu-i lui Esau, fratele tău, spunând:
7 ‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
Adu-mi vânat şi fă-mi mâncare gustoasă ca să mănânc şi să te binecuvântez înaintea DOMNULUI înaintea morţii mele.
8 Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
Acum, aşadar, fiul meu, ascultă de vocea mea, conform cu ceea ce îţi poruncesc.
9 Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
Du-te acum la turmă şi ia şi adu-mi de acolo doi iezi buni de la capre; şi îi voi face mâncare gustoasă pentru tatăl tău, aşa cum îi place;
10 Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
Şi o vei duce la tatăl tău, ca să mănânce şi să te binecuvânteze înaintea morţii sale.
11 Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
Şi Iacob a spus Rebecăi, mama lui: Iată, Esau fratele meu este un bărbat păros, iar eu sunt un bărbat alunecos;
12 bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
Tatăl meu poate mă va pipăi şi am să îi par ca un înşelător; şi voi aduce un blestem asupra mea şi nu o binecuvântare.
13 Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
Şi mama lui i-a spus: Asupra mea fie blestemul tău, fiul meu; ascultă doar de vocea mea şi du-te, adu-mi iezii.
14 Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
Şi s-a dus şi i-a luat şi i-a adus la mama lui; şi mama lui a făcut mâncare gustoasă, aşa cum îi plăcea tatălui său.
15 Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
Şi Rebeca a luat haine bune care erau cu ea în casă, de la fiul ei mai în vârstă, Esau, şi le-a pus peste Iacob, fiul ei mai tânăr;
16 Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
Şi ea a pus pieile iezilor de capre peste mâinile lui şi peste partea alunecoasă a gâtului său;
17 Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
Şi a dat mâncarea gustoasă şi pâinea, pe care le-a pregătit, în mâna fiului ei, Iacob.
18 Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
Şi el a venit la tatăl său şi a spus: Tată; iar el a spus: Iată-mă, cine eşti tu, fiul meu?
19 Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
Şi Iacob i-a spus tatălui său: Eu sunt Esau, întâiul tău născut; am făcut după cum m-ai rugat; ridică-te, te rog, şezi şi mănâncă din vânatul meu, ca sufletul tău să mă binecuvânteze.
20 Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
Şi Isaac a spus fiului său: Cum se face că ai găsit vânat aşa repede, fiul meu? Iar el a spus: Pentru că DOMNUL Dumnezeul tău l-a adus la mine.
21 Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
Şi Isaac i-a spus lui Iacob: Vino aproape, te rog, să te pipăi, fiul meu, dacă eşti sau nu adevăratul meu fiu Esau.
22 Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
Şi Iacob s-a apropiat de Isaac, tatăl său; iar el l-a pipăit şi a spus: Vocea este vocea lui Iacob, dar mâinile sunt mâinile lui Esau.
23 Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
Şi nu l-a recunoscut, din cauză că mâinile lui erau păroase, ca mâinile fratelui său Esau, aşa că l-a binecuvântat.
24 ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
Şi a spus: Eşti tu adevăratul meu fiu Esau? Iar el a spus: Eu sunt.
25 Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
Iar el a spus: Adu-o aproape de mine şi voi mânca din vânatul fiului meu, ca sufletul meu să te binecuvânteze. Şi a adus-o aproape de el şi a mâncat; şi i-a adus vin şi a băut.
26 Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
Şi tatăl său Isaac i-a spus: Vino aproape acum şi sărută-mă, fiul meu.
27 Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
Şi a venit aproape şi l-a sărutat; şi a mirosit mirosul hainelor lui şi l-a binecuvântat şi a spus: Vezi, mirosul fiului meu este ca mirosul unui câmp pe care DOMNUL l-a binecuvântat;
28 Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
De aceea Dumnezeu să îţi dea din roua cerului şi din grăsimea pământului şi abundenţă de grâne şi vin;
29 Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
Să te servească poporul şi naţiuni să ţi se prosterneze, fii domn peste fraţii tăi şi fiii mamei tale să ţi se prosterneze; blestemat fie cel ce te blestemă şi binecuvântat fie cel ce te binecuvântează.
30 Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
Şi s-a întâmplat, îndată ce Isaac a terminat de binecuvântat pe Iacob şi Iacob tocmai ce ieşise dinaintea lui Isaac, tatăl său, că Esau, fratele său, a venit de la vânătoarea sa.
31 Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
Şi el de asemenea a făcut mâncare gustoasă şi a adus-o tatălui său şi a spus tatălui său: Să se ridice tatăl meu şi să mănânce din vânatul fiului său, ca sufletul tău să mă binecuvânteze.
32 Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
Şi Isaac tatăl său i-a spus: Cine eşti tu? Iar el a spus: Eu sunt fiul tău, întâiul tău născut Esau.
33 Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
Şi Isaac s-a cutremurat peste măsură de mult şi a spus: Cine? Unde este cel ce a luat vânat şi l-a adus la mine şi am mâncat din tot înainte de a veni tu şi l-am binecuvântat? Da şi va fi binecuvântat.
34 Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
Şi când Esau a auzit cuvintele tatălui său, a strigat cu un strigăt mare şi grozav de amar şi a spus tatălui său: Binecuvântează-mă şi pe mine tată.
35 Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
Iar el a spus: Fratele tău a venit cu viclenie şi ţi-a luat binecuvântarea.
36 Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
Iar el a spus: Nu pe drept este numit el Iacob? Pentru că m-a înlocuit în aceste două dăţi, a luat dreptul meu de întâi născut; şi acum, iată, a luat şi binecuvântarea mea. Şi a spus: Nu ai păstrat o binecuvântare pentru mine?
37 Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
Şi Isaac a răspuns şi i-a zis lui Esau: Iată, l-am făcut domnul tău şi pe toţi fraţii lui i-am dat ca servitori; şi cu grâne şi vin l-am susţinut şi ce să îţi fac acum, fiul meu?
38 Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
Şi Esau a spus tatălui său: Ai doar o singură binecuvântare, tată? Binecuvântează-mă şi pe mine tată. Şi Esau şi-a înălţat vocea şi a plâns.
39 Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
Şi Isaac, tatăl lui, a răspuns şi i-a zis: Iată, locuinţa ta va fi grăsimea pământului şi din roua cerului de sus.
40 Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
Şi prin sabia ta vei trăi şi vei servi fratelui tău; şi se va întâmpla când vei avea stăpânirea, că vei desface jugul lui de pe gâtul tău.
41 Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
Şi Esau a urât pe Iacob din cauza binecuvântării cu care tatăl său l-a binecuvântat; şi Esau a spus în inima sa: Zilele de jelire pentru tatăl meu sunt aproape; atunci voi ucide pe fratele meu Iacob.
42 Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
Şi aceste cuvinte ale lui Esau, fiul ei mai în vârstă, au fost spuse Rebecăi; şi ea a trimis şi a chemat pe Iacob, fiul ei mai tânăr, şi i-a spus: Iată, fratele tău, Esau, se mângâie referitor la tine, hotărât să te ucidă.
43 Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
De aceea acum, fiul meu, ascultă de vocea mea; şi ridică-te, fugi la Laban, fratele meu, la Haran.
44 Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
Şi rămâi cu el câteva zile, până ce furia fratelui tău se întoarce;
45 Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
Până ce mânia fratelui tău se întoarce de la tine şi uită ce i-ai făcut; atunci voi trimite şi te voi aduce de acolo; şi de ce să fiu lipsită de voi doi într-o singură zi?
46 Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”
Şi Rebeca i-a spus lui Isaac: M-am săturat de viaţa mea din cauza fiicelor lui Het; dacă Iacob ia o soţie dintre fiicele lui Het, ca acestea dintre fiicele ţării, la ce bun îmi va fi viaţa?

< Genesis 27 >