< Genesis 27 >
1 Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Quando Isaac era velho, e seus olhos estavam escuros, para que ele não pudesse ver, chamou Esaú de seu filho mais velho, e disse-lhe: “Meu filho...”. Ele lhe disse: “Aqui estou eu”.
2 Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
Ele disse: “Veja agora, eu sou velho. Eu não sei o dia da minha morte.
3 Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
Agora, portanto, por favor, pegue suas armas, sua aljava e seu arco, e vá para o campo, e traga-me carne de veado.
4 Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
Faça-me comida saborosa, como eu amo, e traga-a até mim, para que eu possa comer, e para que minha alma possa abençoá-lo antes que eu morra”.
5 Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
Rebekah ouviu quando Isaac falou com Esaú seu filho. Esaú foi para o campo para caçar veado e trazê-lo.
6 Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
Rebekah falou com Jacó seu filho, dizendo: “Eis que ouvi seu pai falar com Esaú seu irmão, dizendo:
7 ‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
'Traga-me carne de veado, e faça-me comida saborosa, para que eu possa comer, e abençoá-lo antes de Yahweh antes de minha morte'.
8 Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
Agora, portanto, meu filho, obedece à minha voz segundo o que eu te ordeno.
9 Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
Vá agora para o rebanho e traga-me dois bons cabritos de lá. Eu os farei comida saborosa para seu pai, tal como ele ama.
10 Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
Você o trará a seu pai, para que ele possa comer, a fim de que ele o abençoe antes de sua morte”.
11 Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
Jacob disse a Rebekah sua mãe: “Eis que Esaú meu irmão é um homem peludo, e eu sou um homem liso.
12 bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
E se meu pai me tocar? Eu lhe parecerei como um enganador, e traria uma maldição sobre mim mesmo, e não uma bênção”.
13 Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
Sua mãe lhe disse: “Que sua maldição caia sobre mim, meu filho”. Obedeça apenas à minha voz, e vá buscá-los para mim”.
14 Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
Ele foi, e os pegou, e os trouxe para sua mãe. Sua mãe fazia comidas saborosas, como as que seu pai amava.
15 Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
Rebekah pegou as boas roupas de Esaú, seu filho mais velho, que estavam com ela em casa, e as colocou em Jacob, seu filho mais novo.
16 Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
She colocou as peles das cabras jovens em suas mãos, e na lisa do pescoço dele.
17 Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
Ela deu a comida saborosa e o pão, que ela havia preparado, na mão de seu filho Jacob.
18 Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
Ele veio até seu pai e disse: “Meu pai...”. Ele disse: “Aqui estou eu”. Quem é você, meu filho?”
19 Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
Jacob disse a seu pai: “Eu sou Esaú, seu primogênito”. Fiz o que me pediu para fazer. Por favor, levanta-te, senta-te e come do meu veado, para que tua alma me abençoe”.
20 Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
Isaac disse a seu filho: “Como você o encontrou tão rapidamente, meu filho”? Ele disse: “Porque Yahweh seu Deus me deu o sucesso”.
21 Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
Isaac disse a Jacob: “Por favor, aproxime-se, para que eu possa sentir você, meu filho, quer você seja realmente meu filho Esaú ou não”.
22 Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
Jacob se aproximou de Isaac, seu pai. Ele o sentiu e disse: “A voz é a voz de Jacó, mas as mãos são as mãos de Esaú”.
23 Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
Ele não o reconheceu, porque suas mãos eram peludas, como as mãos de seu irmão Esaú. Por isso, ele o abençoou.
24 ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
Ele disse: “Você é realmente meu filho Esaú?”. Ele disse: “Eu sou”.
25 Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
Ele disse: “Traga-o perto de mim, e eu comerei do veado de meu filho, para que minha alma o abençoe”. Ele o trouxe para perto dele, e comeu. Trouxe-lhe vinho, e ele bebeu.
26 Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
Seu pai Isaac lhe disse: “Aproxime-se agora, e me beije, meu filho”.
27 Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
Ele se aproximou e o beijou. Ele sentiu o cheiro de suas roupas e o abençoou, e disse, “Eis o cheiro de meu filho é como o cheiro de um campo que Yahweh abençoou.
28 Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
Deus lhe dê do orvalho do céu, da gordura da terra, e abundância de grãos e vinho novo.
29 Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
Let as pessoas o servem, e as nações se curvam diante de você. Seja senhor de seus irmãos. Deixe que os filhos de sua mãe se curvem diante de você. Malditos sejam todos aqueles que o amaldiçoam. Abençoados sejam todos aqueles que vos abençoam”.
30 Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
Assim que Isaac terminou de abençoar Jacob, e Jacob tinha acabado de sair da presença de Isaac, seu pai, Esaú, seu irmão, veio de sua caçada.
31 Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
Ele também fez comida saborosa, e a trouxe para seu pai. Ele disse a seu pai: “Que meu pai se levante e coma do veado de seu filho, para que sua alma me abençoe”.
32 Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
Isaac seu pai lhe disse: “Quem é você?” Ele disse: “Eu sou seu filho, seu primogênito, Esaú”.
33 Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
Isaac tremeu violentamente, e disse: “Quem, então, é aquele que tomou o veado e o trouxe até mim, e eu comi de tudo antes de você vir, e o abençoei? Sim, ele será abençoado”.
34 Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
Quando Esaú ouviu as palavras de seu pai, ele chorou com um grito extremamente grande e amargo, e disse a seu pai: “Abençoe-me, a mim também, meu pai”.
35 Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
Ele disse: “Seu irmão veio com engano, e lhe tirou a bênção”.
36 Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
Ele disse: “Ele não se chama corretamente Jacob? Pois ele me suplantou nestas duas vezes. Ele me tirou o direito de nascença. Veja, agora ele me tirou a bênção”. Ele disse: “Você não reservou uma bênção para mim?”.
37 Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
Isaac respondeu a Esaú: “Eis que eu o fiz vosso senhor, e todos os seus irmãos lhe dei por servos”. Eu o sustentei com grãos e vinho novo”. O que farei então por ti, meu filho”?
38 Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
Esau disse a seu pai: “Você tem apenas uma bênção, meu pai? Abençoe-me, a mim também, meu pai”. Esaú levantou sua voz, e chorou.
39 Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
Isaac, seu pai, lhe respondeu, “Eis que sua morada será da gordura da terra”, e do orvalho do céu vindo de cima.
40 Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
Você viverá pela sua espada, e servirá a seu irmão. Isso acontecerá, quando você se soltará, que você vai sacudir seu jugo do pescoço”.
41 Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
Esau odiava Jacob por causa da bênção com a qual seu pai o abençoou. Esaú disse em seu coração: “Os dias de luto por meu pai estão próximos”. Então eu vou matar meu irmão Jacob”.
42 Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
As palavras de Esaú, seu filho mais velho, foram ditas a Rebekah. Ela enviou e chamou Jacó, seu filho mais novo, e lhe disse: “Eis que seu irmão Esaú se conforta com você planejando matá-lo”.
43 Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
Agora, portanto, meu filho, obedeça à minha voz. Levanta-te, foge para Laban, meu irmão, em Haran.
44 Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
Fique com ele alguns dias, até que a fúria de seu irmão se afaste -
45 Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
até que a raiva de seu irmão se afaste de você, e ele esqueça o que você fez com ele. Então eu enviarei e o buscarei de lá. Por que eu deveria estar de luto por vocês dois em um dia”?
46 Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”
Rebekah disse a Isaac: “Estou cansada de minha vida por causa das filhas de Heth. Se Jacó toma uma esposa das filhas de Heth, como estas, das filhas da terra, de que me servirá minha vida?”.