< Genesis 26 >

1 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
[Ⱪanaan] zeminida Ibraⱨimning waⱪtidiki aqarqiliⱪtin baxⱪa yǝnǝ bir ⱪetimliⱪ aqarqiliⱪ yüz bǝrdi. Xuning bilǝn Isⱨaⱪ Gǝrar xǝⱨirigǝ, Filistiylǝrning padixaⱨi Abimǝlǝkning ⱪexiƣa bardi.
2 Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
Pǝrwǝrdigar uningƣa kɵrünüp mundaⱪ dedi: — Sǝn Misirƣa qüxmǝy, bǝlki Mǝn sanga kɵrsitip beridiƣan yurtta turƣin.
3 Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
Moxu zemindin qiⱪmay musapir bolup turƣin; xuning bilǝn Mǝn sǝn bilǝn billǝ bolup, sanga bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilimǝn; qünki Mǝn sǝn wǝ nǝslinggǝ bu zeminlarning ⱨǝmmisini berip, atang Ibraⱨimƣa bǝrgǝn ⱪǝsimimni ada ⱪilimǝn;
4 Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
nǝslingni asmandiki yultuzlardǝk awutimǝn wǝ nǝslinggǝ bu zeminlarning ⱨǝmmisini berimǝn; yǝr yüzidiki barliⱪ ǝl-yurtlar nǝslingning [nami] bilǝn ɵzlirigǝ bǝht-bǝrikǝt tilǝydu;
5 nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
Qünki Ibraⱨim Mening awazimƣa ⱪulaⱪ selip, tapiliƣinim, ǝmrlirim, bǝlgilimilirim wǝ ⱪanunlirimni bǝja kǝltürdi, — dedi.
6 Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
Xuning bilǝn Isⱨaⱪ Gǝrarda turup ⱪaldi.
7 Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
Əmma u yǝrlik kixilǝr uning ayali toƣrisida sorisa u: — Bu mening singlim bolidu, — dedi; qünki Riwkaⱨ intayin qirayliⱪ bolƣaqⱪa, Isⱨaⱪ ɵz-ɵzigǝ: «Bu mening ayalim bolidu», desǝm, bu yǝrlik adǝmlǝr Riwkaⱨning sǝwǝbidin meni ɵltürüwetǝrmikin, — dǝp ⱪorⱪti.
8 Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
Lekin u xu yǝrdǝ uzaⱪ waⱪit turƣandin keyin xundaⱪ boldiki, Filistiylǝrning padixaⱨi Abimǝlǝk dǝrizidin ⱪariwidi, mana Isⱨaⱪ wǝ ayali Riwkaⱨ bir-birigǝ ǝrkilixip turatti.
9 Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
Andin Abimǝlǝk Isⱨaⱪni qaⱪirip: — Mana, u jǝzmǝn sening ayaling ikǝn! Sǝn nemǝ dǝp: «U mening singlim», deding? — dewidi, Isⱨaⱪ uningƣa: — Qünki mǝn ǝslidǝ uning sǝwǝbidin birsi meni ɵltürüwetǝrmikin, dǝp ǝnsirigǝnidim, — dedi.
10 Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
Abimǝlǝk uningƣa: Bu bizgǝ nemǝ ⱪilƣining? Tas ⱪaptu hǝlⱪ arisidin birǝrsi ayaling bilǝn birgǝ bolƣili?! Undaⱪ bolƣan bolsa sǝn bizni gunaⱨⱪa patⱪuzƣan bolatting! — dedi.
11 Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
Andin Abimǝlǝk ⱨǝmmǝ hǝlⱪⱪǝ buyrup: — Kimki bu kixigǝ wǝ yaki hotuniƣa ⱪol tǝgküzsǝ jǝzmǝn ɵltürülmǝy ⱪalmaydu, — dǝp yarliⱪ qüxürdi.
12 Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
Isⱨaⱪ u zeminda teriⱪqiliⱪ ⱪildi: u xu yili yǝrdin yüz ⱨǝssǝ ⱨosul aldi; Pǝrwǝrdigar uni bǝrikǝtligǝnidi.
13 Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
Bu kixi bax kɵtürüp, barƣanseri rawaj tepip, tolimu katta kixilǝrdin bolup ⱪaldi.
14 Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
Uning ⱪoy-kala padiliri wǝ ɵyidiki ⱪulliri intayin kɵpǝydi; Filistiylǝr uningƣa ⱨǝsǝt ⱪilƣili turdi.
15 Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
Bu sǝwǝbtin uning atisi Ibraⱨimning künliridǝ atisining ⱪulliri koliƣan ⱪuduⱪlarning ⱨǝmmisini Filistiylǝr etip, topa bilǝn tinduruwǝtti.
16 Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
Abimǝlǝk Isⱨaⱪⱪa: — Sǝn bizdin ziyadǝ küqiyip kǝtting, ǝmdi arimizdin qiⱪip kǝtkin, — dedi.
17 Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
Isⱨaⱪ u yǝrdin ketip, Gǝrar wadisiƣa qedir tikip, xu yǝrdǝ turup ⱪaldi.
18 Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
Ibraⱨim ⱨayat waⱪtida [ⱪulliri] birmunqǝ ⱪuduⱪlarni ⱪazƣanidi; biraⱪ Ibraⱨim ɵlgǝndin keyin, Filistiylǝr bularni topa bilǝn tinduruwǝtkǝnidi. Isⱨaⱪ bu ⱪuduⱪlarni ⱪaytidin kolitip, ularƣa atisi ilgiri ⱪoyƣan isimlarni yǝnǝ ⱪoydi.
19 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
Isⱨaⱪning ⱪulliri wadida ⱪuduⱪ kolawatⱪanda suliri urƣup qiⱪip aⱪidiƣan bir ⱪuduⱪni tepiwaldi.
20 Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
Lekin Gǝrardiki padiqilar Isⱨaⱪning padiqiliridin uni talixip: — Bu su bizningkidur, — dedi. Ular Isⱨaⱪ bilǝn jedǝllǝxkǝqkǝ, u bu ⱪuduⱪni «Esǝk» dǝp atidi.
21 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
Ular yǝnǝ baxⱪa bir ⱪuduⱪni kolidi, ular yǝnǝ bu ⱪuduⱪ toƣrisida jedǝllǝxti. Xuning bilǝn Isⱨaⱪ buning ismini «Sitnaⱨ» dǝp atidi.
22 Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
Andin u u yǝrdin ketip, baxⱪa yǝrgǝ berip, xu yǝrdimu yǝnǝ bir ⱪuduⱪ kolidi; ǝmdi Gǝrardikilǝr bu ⱪuduⱪni talaxmidi. Bu sǝwǝbtin u uning etini «Rǝⱨobot» ⱪoyup: «Əmdi Pǝrwǝrdigar biz üqün jay bǝrgǝnikǝn, bu zeminda mewilik bolimiz», — dedi.
23 Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
Andin u u yǝrdin qiⱪip Bǝǝr-Xebaƣa bardi.
24 Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
Pǝrwǝrdigar xu keqisi uningƣa kɵrünüp: — Mǝn bolsam atang Ibraⱨimning Hudasidurmǝn; ⱪorⱪmiƣin, qünki Mǝn sǝn bilǝn billimǝn, seni bǝht-bǝrikǝtlǝp, nǝslingni ⱪulum Ibraⱨimning sǝwǝbidin awutimǝn, — dedi.
25 Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
U xu yǝrdǝ bir ⱪurbangaⱨ yasap, Pǝrwǝrdigarning namiƣa nida ⱪilip ibadǝt ⱪildi. U xu yǝrdǝ qedirini tikti, Isⱨaⱪning ⱪulliri xu yǝrdǝ bir ⱪuduⱪ kolidi.
26 Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
Əmdi Abimǝlǝk, aƣinisi Aⱨuzzat bilǝn lǝxkǝrbexi Fikol birgǝ Gǝrardin qiⱪip, uning ⱪexiƣa bardi.
27 Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
Isⱨaⱪ ularƣa: — Manga ɵqmǝnlik ⱪilip, meni aranglardin ⱪoƣliwǝtkǝndin keyin, nemǝ üqün mening ⱪeximƣa kǝldinglar? — dedi.
28 Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
Ular jawabǝn: — Biz Pǝrwǝrdigarning sǝn bilǝn billǝ bolƣinini roxǝn bayⱪiduⱪ, xuning bilǝn biz sening toƣrangda: «Otturimizda bir kelixim bolsun, yǝni bizlǝr bilǝn sǝn bir-birimizgǝ ⱪǝsǝm berip ǝⱨdǝ ⱪilixayli» deduⱪ; xu wǝjidin sǝn bizgǝ ⱨeqⱪandaⱪ ziyan-zǝhmǝt yǝtküzmigǝysǝn; biz sanga ⱨeq tǝgmiginimizdǝk, xundaⱪla sanga yahxiliⱪtin baxⱪa ⱨeqbir nemǝ ⱪilmiƣinimizdǝk (bǝlki seni aman-esǝnlik iqidǝ yolungƣa ǝwǝtkǝniduⱪ) sǝnmu xundaⱪ ⱪilƣaysǝn. Mana ⱨazir sǝn Pǝrwǝrdigar tǝripidin bǝht-bǝrikǝt kɵrüwatisǝn! — deyixti.
29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
Xuning bilǝn u ularƣa bir ziyapǝt ⱪilip bǝrdi. Ular bolsa yǝp-iqti.
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
Ətisi tang sǝⱨǝrdǝ ular ⱪopup bir-birigǝ ⱪǝsǝm ⱪilixti; andin Isⱨaⱪ ularni yolƣa selip ⱪoydi; ular uning ⱪexidin aman-esǝn kǝtti.
32 Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
U küni xundaⱪ boldiki, Isⱨaⱪning ⱪulliri kelip, uningƣa ɵzi koliƣan ⱪuduⱪ toƣrisida hǝwǝr berip: «Biz su taptuⱪ!» dedi.
33 Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
U uning namini «Xibaⱨ» ⱪoydi. Bu sǝwǝbtin bu xǝⱨǝrning ismi bügüngiqǝ «Bǝǝr-Xeba» dǝp atilip kǝlmǝktǝ.
34 Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
Əsaw ⱪiriⱪ yaxⱪa kirgǝndǝ, Ⱨittiylardin bolƣan Bǝǝrining ⱪizi Yǝⱨudit bilǝn Ⱨittiylardin bolƣan Elonning ⱪizi Basimatni hotunluⱪⱪa aldi.
35 Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.
Əmma bular Isⱨaⱪ bilǝn Riwkaⱨning kɵngligǝ azab elip kǝldi.

< Genesis 26 >