< Genesis 26 >

1 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
Potem nastał głód na ziemi, po tym pierwszym głodzie, który był za dni Abrahama. Izaak udał się więc do Abimeleka, króla Filistynów, do Geraru.
2 Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
Wtedy PAN ukazał mu się i powiedział: Nie idź do Egiptu, [ale] mieszkaj w ziemi, którą ci wskażę.
3 Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
Bądź przybyszem w tej ziemi, a ja będę z tobą i będę ci błogosławił. Tobie bowiem i twemu potomstwu dam te wszystkie krainy i dotrzymam przysięgi, którą złożyłem twemu ojcu Abrahamowi.
4 Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
I rozmnożę twoje potomstwo jak gwiazdy na niebie, i dam twemu potomstwu wszystkie te krainy. A będą błogosławione w twoim potomstwie wszystkie narody ziemi;
5 nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
Dlatego że Abraham posłuchał mego głosu i strzegł mego nakazu, moich przykazań, moich ustaw i moich praw.
6 Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
Izaak zamieszkał więc w Gerarze.
7 Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
A gdy mężczyźni tego miejsca pytali o jego żonę, odpowiedział: To moja siostra. Bał się bowiem mówić: To moja żona, by mężczyźni tego miejsca nie zabili go z powodu Rebeki, bo była bardzo piękna.
8 Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
Gdy mieszkał tam już dłuższy czas, król Filistynów Abimelek wyjrzał przez okno i zobaczył, że Izaak pieścił swą żonę Rebekę.
9 Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
Abimelek wezwał więc Izaaka i powiedział: To jest na pewno twoja żona. Dlaczego mówiłeś: To moja siostra? Izaak mu odpowiedział: Bo mówiłem [sobie]: Abym nie umarł z jej powodu.
10 Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
Abimelek powiedział: Coś ty nam zrobił? Mało brakowało, a ktoś z ludu spałby z twoją żoną i tak sprowadziłbyś na nas grzech.
11 Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
Rozkazał więc Abimelek całemu ludowi: Kto by dotknął tego człowieka albo jego żony, na pewno umrze.
12 Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
Wówczas Izaak posiał w tej ziemi i zebrał w tym roku stokrotny plon, bo PAN mu błogosławił.
13 Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
I wzbogacił się ów człowiek, i rozwijał się coraz bardziej, aż stał się bardzo zamożny.
14 Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
Miał trzody owiec i stada wołów oraz wiele sług, tak że Filistyni mu zazdrościli.
15 Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
I wszystkie studnie, które wykopali słudzy jego ojca, za dni jego ojca Abrahama, Filistyni zasypali i napełnili je ziemią.
16 Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
I Abimelek powiedział do Izaaka: Odejdź od nas, bo jesteś dużo zamożniejszy od nas.
17 Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
Izaak odszedł więc stamtąd i rozbił namioty w dolinie Gerar, i tam zamieszkał.
18 Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
Potem Izaak na nowo odkopał studnie, które wykopali za dni jego ojca Abrahama, a które Filistyni zasypali po śmierci Abrahama, i nadał im [te same] nazwy, jakie nadał im jego ojciec.
19 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
Wtedy słudzy Izaaka kopali w tej dolinie i znaleźli tam studnię ze źródlaną wodą.
20 Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
Lecz pasterze z Geraru kłócili się z pasterzami Izaaka, mówiąc: To nasza woda. Nazwał więc tę studnię Esek, bo spierali się z nim.
21 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
Gdy wykopali drugą studnię, również kłócili się o nią. Dlatego nazwał ją Sitna.
22 Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
Potem przeniósł się stamtąd i wykopał kolejną studnię, o którą już nie było sporu. Nazwał ją więc Rechobot i mówił: Oto teraz PAN dał nam miejsce, abyśmy się rozmnażali na ziemi.
23 Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
I wyruszył stamtąd do Beer-Szeby.
24 Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
Tej nocy ukazał mu się PAN i powiedział: Ja [jestem] Bogiem twego ojca Abrahama. Nie bój się, bo jestem z tobą. Będę ci błogosławił i rozmnożę twoje potomstwo ze względu na mego sługę Abrahama.
25 Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
Zbudował więc tam ołtarz i wzywał imienia PANA, i rozbił tam swój namiot. Tam też słudzy Izaaka wykopali studnię.
26 Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
Wtedy przybyli do niego z Geraru Abimelek i Achuzat, jeden z jego przyjaciół, oraz dowódca jego wojska Pikol.
27 Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
Izaak zapytał ich: Po co przybyliście do mnie, skoro mnie nienawidzicie i wypędziliście mnie od siebie?
28 Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
A oni odpowiedzieli: Zobaczyliśmy naprawdę, że PAN jest z tobą, więc powiedzieliśmy: Niech będzie teraz przysięga między nami, między nami a tobą, i ustanowimy przymierze z tobą;
29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
Abyś nam nie czynił nic złego, jak i my też nie dotknęliśmy ciebie i tylko dobrze ci czyniliśmy, i pozwoliliśmy ci odejść w pokoju; [a] ty teraz jesteś błogosławiony przez PANA.
30 Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
Wtedy wyprawił im ucztę; jedli więc i pili.
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
Nazajutrz wstali wcześnie rano i złożyli sobie wzajemnie przysięgę. Potem Izaak pożegnał się z nimi i odeszli od niego w pokoju.
32 Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
Tego samego dnia słudzy Izaaka przyszli i opowiedzieli mu o studni, którą wykopali: Znaleźliśmy wodę.
33 Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
I nazwał ją Szibea. Dlatego to miasto nazywa się Beer-Szeba aż do dzisiaj.
34 Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
Gdy Ezaw miał czterdzieści lat, pojął sobie za żonę Judytę, córkę Beeriego Chetyty, i Bosmat, córkę Elona Chetyty.
35 Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.
Były one przyczyną utrapień Izaaka i Rebeki.

< Genesis 26 >