< Genesis 26 >

1 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
Agatekna ko'ma Abrahamu knafi fore hu'neankna huno ana mopafina fore higeno, Aisaki'a Gerari kumate Filistia kini ne' Abimelekintega vu'ne.
2 Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
Ra Anumzamo'a agrite efore huno amanage huno asmi'ne. Nagrama kasmisua mopare manigahananki, Isipia ovuo.
3 Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
Ama mopafi mani'nege'na, Nagra asomu hunegantane'na kagri'ene kagehe'ine ama mopa mika nerami'na, Nagrama huvempa negafa Abrahamuma hunte'noa kea eri knare ha'neno.
4 Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
Nagra kagehe'ina zamazeri ra ha'nenke'za monafi hanafi kna hanage'na, Nagra ama mopa kagehe'i zamisugeno, kagehe'impinti miko kokankoka vahe'mo'za asomura erigahaze.
5 nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
Na'ankure kema huankea Abrahamu'a amagenenteno Nagri kasegene tra ke'nianena avariri'ne.
6 Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
Ana higeno Aisaki'a Gerari mopare mani'ne.
7 Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
Ana kumate vahe'mo'za Aisakina nenaronku antahi kageno agra a'nimo'e huno huzankura koro nehuno Nensaro'e hu'ne. Hagi agrama agesama antahiana Rebeka'a vahe'mofo anunu hu'are mani'negeno, ana kumate vahe'mo'za ahezanku anage hu'ne.
8 Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
Za'za kna anampi umaniteno, Aisaki'a nenaro Rebeka agazafe'negeno, Abimeleki'a Filistia kini ne'mo nomofo zaho eri kampinti ke'ne.
9 Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
Anante Abimeleki'a, Aisakina ke higeno egeno, amanage huno asami'ne, Antahio, tamage huno ami kagri a' mani'ne! Nahigenka kagra nensaro'e hunka hu'nane? Higeno Aisaki'a amanage huno asmi'ne, Na'ankure agriteku hu'za vahe'mo'za nahe fri'zanku anagea hu'noe.
10 Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
Higeno Abimeleki'a amanage hu'ne, Amazana naza hunerantane? Mago vahe'mo'ma neganaro'ene maseresina, kagra mago knaza eri tamisine.
11 Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
Anage huteno Abimeleki'a hakare vahe mago kasege antezmanteno amanage hu'ne, aza'o ama nero, nenarono avako'ma hanimofona ahe frigahaze.
12 Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
Hagi Aisaki'a ana mopafina avimaza hozafima hankre'neana ana kafufina 100'a agatereno hamare'ne. Ana higeno Ra Anumzamo'a asomu hunte'ne.
13 Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
Ana higeno Aisaki'a feno ne' fore nehuno, mago'ene ra huno tusi'a feno anteno, mika feno ante agatere'nea ne' mani'ne.
14 Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
Aisaki'a sipisipi zagane, memeki zagane, Bulimakaone, eri'za vahe'ene, rama'a ante'nege'za, Filistia vahe'mo'za zamasigu hunte'naze.
15 Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
Ana hige'za mika tinkerima agri nefa Abrahamu eri'za vahe'mo'zama ko'ma kafimante'nazana, Filisti'a vahe'mo'za mopa kate'za refite'naze.
16 Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
Hagi henka Abimeleki'a amanage huno Aisakina asmi'ne, Kagra tagrira tagaterenka hanave'nentake hananki, tagri'pintira atrenka vuo.
17 Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
Hazageno Aisaki'a atreno Gerari agupofi seli no omegino anantega mani'ne.
18 Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
Hagi Aisaki'a eteno korapa Abrahamu kafinte'nea tinkeriramina eri so'e hu'ne. Na'ankure nefa'ma fritege'za Filistia vahe'mo'za refite'naza tinkeri raminkino, kafiteno nefa'ma ami'nea agi'aramina erikasefa huno antetere hu'ne.
19 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
Aisaki eri'za vahe'mo'za ana agupofi tinkeri nesageno, anampinti ti hanatino mareri'ne.
20 Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
Hianagi Gerari afu kva vahe'mo'za, Aisaki afu kva vahera frage huzmante'za amanage hu'naze. Ama tagri tine! Hazageno Aisaki'a agi'a Eseki'e huno ante'ne. Na'ankure zamagra frage hunante'nazagu hu'ne.
21 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
Aisaki eri'za vahe'mo'za mago'ane ru tinkeri nesageno, esaza hu'za Gerari vahe'mo'za fra vazizmente'naze. Fra vazizageno negeno, Aisaki'a ana tinkerimofona Sitne huno agia ante'ne.
22 Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
Aisaki'a ana tinkeria atreno ru tinkeri ome kafige'za, hafra huontageno, ana tinkerimofo agi'a Rehoboti'e huno nenteno anage hu'ne, na'ankure Ra Anumzamo'a tazahuno kankamuna retro hurante'neankita, ama ana mopare manineta, maka zampina knare hugahune.
23 Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
Hagi Aisaki'a ana kumara atreno marerino Berseba kumate uhanati'ne.
24 Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
Ana'ma uhanatia kenegera Ra Anumzamo'a efore humino amanage huno asami'ne, Nagra Abrahamu nafaka'amofo Anumzane, e'igu korora osuo. Nagra kagrane mani'nena asomura hunegantena henka'a kagripinti kegehe'za fore hanamoki'zminena zamazeri hakare hugahue. Na'ankure Abrahamu'a Nagri eri'za vahe mani'negu anara hugahue.
25 Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
Hutegeno Aisaki'a ana kumatera Kresramana vu ita trohuno, Ra Anumzamofo agi hanta vazino ana kumateke seli no azeri onetige'za, Aisaki eri'za vahe'mo'za mago tinkeri kafi'naze.
26 Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
Hagi Abimeleki'a Aisaki ome kenaku Gerari nevuno, magora knare antahintahi nemia ne' agi'a Ahusati'e, hanki magora sondia vahe'amofo kva ne' Fikoligizni neznavreno vu'ne.
27 Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
Aisaki'a amanage huno zamantahige'ne, Ko'ma mopa tamifintira tamavesra hunanteta nahe nati'nazanki, tamagra na'anku nagritega neaze?
28 Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
Higeno ana kemofo nona'a anage hu'naze, Ra Anumzamo'a kagrane mani'neno kaza nehigeta negeta, tagra anage nehune, Kagri ene tagri ene amu'notifina tamage hunka huvempa naneke hugeta kagrane, tagranena hagerfita mani'maneno.
29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
Kagra, tagrira tazeri havizana osugahane. Tagra kazeri havizana kagrira osuta, trimpa frune hugantonkenka e'nane. Menina Ra Anumzamo knare huneganteno asomura hunegante.
30 Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
Hazageno ana kezmia nentahino, Aisaki'a ra kave kre zamentege'za tine ana ne'zana ne'naze.
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
Nanterame oti'za raruma hu'za manisaza huvempagea hute'za, anante Aisaki'a huno, Tamarimpa frune viho, huno huzmantege'za vu'naze.
32 Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
Ana'ma huzamantege'za vaza zupa, Aisaki eri'za vahe'mo'za amanage hu'za eme asmi'naze. Hago mago tinkerima kafinompintira tina fore hie.
33 Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
Ana tinkerimofo agi'a Sibae huno ante'ne. Meninena ana kumamo'a rahige'za Berseba kumare hu'za nehaze.
34 Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
Iso'a 40'a zagegafu maniteno, Hiti ne'mofo mofa' eri'ne, agi'a Juditi'e, nefa'a Beri'e. Hanki mago a'amofo agi'a Basematikino Hiti ne' Eloni mofare.
35 Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.
Ana a'tremokizni mani'zamo Aisakine Rebekagiznia zanarimpa zanata zanami'ne.

< Genesis 26 >