< Genesis 26 >

1 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
Forsothe for hungur roos on the lond, aftir thilke bareynesse that bifelde in the daies of Abraham, Isaac yede forth to Abymelech, kyng of Palestyns, in Gerara.
2 Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
And the Lord apperide to hym, and seide, Go not doun in to Egipt, but reste thou in the lond which Y schal seie to thee,
3 Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
and be thou a pilgrym ther ynne; and Y schal be with thee, and Y schal blesse thee; for Y schal yyue alle these cuntrees to thee and to thi seed, and Y schal fille the ooth which Y bihiyte to Abraham, thi fadir.
4 Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
And Y schal multiplie thi seed as the sterris of heuene, and Y schal yyue alle these thingis to thin eyris, and alle folkis of erthe schulen be blessid in thi seed, for Abraham obeide to my vois,
5 nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
and kepte `my preceptis and comaundementis, and kepte cerymonyes and lawis.
6 Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
And so Ysaac dwellide in Geraris.
7 Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
And whanne he was axid of men of that place of his wijf, he answarde, Sche is my sistir; for he dredde to knowleche that sche was felouschipid to hym in matrymonye, and gesside lest peraduenture thei wolden sle him for the fairnesse of hir.
8 Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
And whanne ful many daies weren passid, and he dwellide there, Abymelech, kyng of Palestyns, bihelde bi a wyndow, and seiy hym pleiynge with Rebecca, his wijf.
9 Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
And whanne Isaac was clepid, the kyng seide, It is opyn, that sche is thi wijf; whi liedist thou, that sche was thi sistir? Isaac answerde, Y dredde, lest Y schulde die for hir.
10 Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
And Abymelech seide, Whi hast thou disseyued vs? Sum man of the puple myyte do letcherie with thi wijf, and thou haddist brouyt in greuous synne on vs. And the kyng comaundide to al the puple,
11 Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
and seide, He that touchith the wijf of this man schal die bi deeth.
12 Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
Forsothe Isaac sowide in that lond, and he foond an hundrid fold in that yeer; and the Lord blesside hym.
13 Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
And the man was maad riche, and he yede profitynge and encreessynge til he was maad ful greet.
14 Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
Also he hadde possessioun of scheep and grete beestis, and ful myche of meyne. For this thing Palestyns hadden enuye to hym,
15 Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
and thei stoppiden in that tyme and filliden with erthe alle the pittis whiche the seruauntis of Abraham his fadir hadden diggid,
16 Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
in so myche that Abymelech him silf seide to Ysaac, Go thou awei fro vs, for thou art maad greetly myytier than we.
17 Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
And he yede awei, that he schulde come to the stronde of Gerare, and dwelle there.
18 Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
And he diggide eft other pittis, whiche the seruauntis of Abraham his fadir hadden diggid, and whiche the Filisteis hadden stoppid sumtyme, whanne Abraham was deed; and he clepide tho pittis bi the same names, bi whiche his fadir hadde clepid bifore.
19 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
Thei diggiden in the stronde, and thei founden wellynge watir.
20 Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
But also strijf of scheepherdis of Gerare was there ayens the scheepherdis of Isaac, and thei seiden, The watir is oure; wherfor of that that bifelde he clepide the name of the pit fals chaleng.
21 Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
And thei diggiden anothir, and thei stryueden also for that, and Ysaac clepide that pit enemytes.
22 Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
And he yede forth fro thennus, and diggide another pit, for which thei stryueden not, therfor he clepid the name of that pit largenesse; and seide, Now God hath alargid vs, and hath maad to encreesse on erthe.
23 Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
Forsothe he stiede fro that place in to Bersabee,
24 Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
where the Lord God apperide to him in that nyyt; and seide, Y am God of Abraham, thi fadir; nyle thou drede, for Y am with thee, and Y schal blesse thee, and Y schal multiplie thi seed for my seruaunt Abraham.
25 Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
And so Ysaac bildide ther an auter to the Lord; and whanne the name of the Lord was inwardli clepid, he stretchide forth a tabernacle; and he comaundide hise seruauntis that thei schulden digge pittis.
26 Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
And whanne Abymelech, and Ochosat, hise frendis, and Ficol, duk of knyytis, hadden come fro Geraris to that place,
27 Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
Isaac spak to hem, What camen ye to me, a man whom ye hatiden, and puttiden awei fro you?
28 Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
Whiche answeriden, We seiyen that God is with thee, and therfor we seiden now, An ooth be bitwixe vs, and make we a couenaunt of pees,
29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
that thou do not ony yuel to vs, as we touchiden `not ony thing of thine, nethir diden that that hirtide thee, but with pees we leften thee encressid bi the blessyng of the Lord.
30 Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
Therfor Isaac made a feeste to hem; and after mete and drynk thei risen eerli,
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
and sworen ech to other; and Isaac lefte hem peisibli in to her place.
32 Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
Lo! forsothe in that dai the seruauntis of Ysaac camen, tellynge to him of the pit which thei hadden diggid, and seiden, We han foundun watir.
33 Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
Wherfor Ysaac clepide that pit abundaunce; and the name of the citee was set Bersabee til in to present dai.
34 Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
Esau forsothe fourti yeer eld weddide twei wyues, Judith, the douytir of Beeri Ethei, and Bethsamath, the douyter of Elon, of the same place;
35 Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.
whiche bothe offendiden the soule of Isaac and of Rebecca.

< Genesis 26 >