< Genesis 25 >

1 Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
És Ábrahám ismét vett magának feleséget és a neve volt Ketúro.
2 Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
És ez szülte neki Zimront, Joksont, Medont és Midjont, Jisbokot és Súáchot.
3 Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
Jokson pedig nemzette Sevót és Dedont; Dedon fiai pedig voltak: Ássúrim, Letúsim és Leummim.
4 Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
Midjon fiai pedig: Éfó, Éfer, Chánóch, Ávido és Eldoo; mindezek Ketúro fiai.
5 Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
És odaadta Ábrahám mindenét, amije volt, Izsáknak.
6 Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
Az ágyasok fiainak pedig, akik Ábraháméi voltak, adott Ábrahám ajándékokat és elküldte őket Izsák, az ő fia mellől még az ő életében, kelet felé, a keleti országba.
7 Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
És ezek Ábrahám életéveinek napjai, amelyeket élt: százhetvenöt év.
8 Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
Kimúlt és meghalt Ábrahám szép vénségben, öregen és élettelten és eltakaríttatott népéhez.
9 Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
És eltemtték őt Izsák és Ismáel, az ő fiai a Máchpéla barlangjába, Efrón, Cóchár fiának, a chittinek mezejébe, amely Mámré előtt van;
10 inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
abba a mezőbe, melyet megvett Ábrahám Chész fiaitól; oda temettetett Ábrahám és Sára, az ő felesége.
11 Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
És volt Ábrahám halála után, Isten megáldotta Izsákot, az ő fiát; Izsák pedig lakott Lácháj-Rói kútja mellett.
12 Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
Ezek pedig nemzetségei Ismáelnek, Ábrahám fiának, akit szült Hágár, az egyiptomi nő, Sára szolgálója, Ábrahámnak.
13 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
És ezek a nevei Ismáel fiainak, neveikkel nemzetségeik szerint: Ismáel elsőszülötte: Nevojósz, Kédor, Ádbeél és Mivszom;
14 Miṣima, Duma, Massa,
Mismo, Dúmo és Másszo;
15 Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
Chádár, Témo, Jetúr, Nófis és Kédmo.
16 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
Ezek Ismáel fiai és ezek a neveik, az ő tanyáikon és váraikban, tizenkét fejedelem, nemzetségeik szerint.
17 Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
És ezek Ismáelnek életévei: százharminchét év; ő kimúlt és meghalt és eltakaríttatott népéhez.
18 Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
És laktak Chávilotól Súrig, mely Egyiptom előtt van, egész Ássúrig; összes testvérei előtt telepedett meg.
19 Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
És ezek nemzetségei Izsáknak, Ábrahám fiának: Ábrahám nemzette Izsákot.
20 Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
És Izsák negyven éves volt, midőn elvette Rebekát, az arámi Beszúél leányát, Páddán-Áromból az arámi Lábánnak nővérét, magának feleségül.
21 Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
És fohászkodott Izsák az Örökkévalóhoz feleségéért, mert magtalan volt és az Örökkévaló meghallgatta fohászát és fogant Rebeka, az ő felesége.
22 Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
De tolakodtak a gyermekek az ő bensejében. És ő mondta: Ha így van, minek vagyok én? És elment, hogy megkérdezze az Örökkévalót.
23 Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
És mondta neki az Örökkévaló: Két nép van méhedben és két nemzet válik ki bensődből; az egyik nemzet erősebb lesz a másik nemzetnél és az időseb szolgál majd az ifjabbnak.
24 Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
És beteltek napjai, hogy szüljön és íme, ikrek voltak méhében.
25 Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
És kijött az első, vörhenyes, egészben olyan, mint egy szőrös köpeny, és elnevezték Ézsaunak.
26 Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
Azután kijött az ő testvére és keze belefogódott Ézsau sarkába és elnevezték Jákobnak; Izsák pedig hatvan éves volt, midőn (Rebeka) szülte őket.
27 Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
És felnőttek a fiúk és lett Ézsau vadászathoz értő ember, a mező embere, Jákob pedig jámbor ember, sátorlakó.
28 Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
És szerette Izsák Ézsaut, mert a vad szája íze szerint volt, Rebeka pedig Jákobot szerette.
29 Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
És főzött Jákob főzeléket; Ézsau pedig jött a mezőről és fáradt volt.
30 Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
És mondta Ézsau Jákobnak: Adj ennem, kérlek, ebből a vörösből, mert fáradt vagyok; azért nevezték el Edómnak.
31 Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
Jákob pedig mondta: Add el nekem ezen a napon a te elsőszülöttségedet.
32 Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
És mondta Ézsau: Íme, én megyek a halál elé, minek is nekem az elsőszülöttség?
33 Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
De Jákob mondta: Esküdj meg nekem ezen a napon, és ő megesküdött neki; és eladta elsőszülöttségét Jákobnak.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.
Jákob pedig adott Ézsaunak kenyeret és lencsefőzeléket; ez evett, ivott, fölkelt és elment. Így vetette meg Ézsau az elsőszülöttséget.

< Genesis 25 >