< Genesis 25 >
1 Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
Forsothe Abraham weddide another wijf, Ceture bi name,
2 Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
which childide to him Samram, and Jexan, and Madan, and Madian, and Jesboth, and Sue.
3 Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
Also Jexan gendride Saba and Dadan. Forsothe the sones of Dadan weren Asurym, and Lathusym, and Laomym.
4 Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
And sotheli of Madian was borun Efa, and Ofer, and Enoth, and Abida, and Heldaa; alle these weren the sones of Cethure.
5 Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
And Abraham yaf alle thingis whiche he hadde in possessioun to Isaac;
6 Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
sotheli he yaf yiftis to the sones of concubyns; and Abraham, while he lyuede yit, departide hem fro Ysaac, his sone, to the eest coost.
7 Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
Forsothe the daies of lijf of Abraham weren an hundrid and `fyue and seuenti yeer;
8 Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
and he failide, and diede in good eelde, and of greet age, and ful of daies, and he was gaderid to his puple.
9 Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
And Ysaac and Ismael, his sones, birieden him in the double denne, which is set in the feeld of Efron, sone of Seor Ethei,
10 inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
euene ayens Mambre, which denne he bouyte of the sones of Heth; and he was biried there, and Sare his wijf.
11 Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
And aftir the deeth of Abraham God blesside Isaac his sone, which dwellide bisidis the pit bi name of hym that lyueth and seeth.
12 Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
These ben the generaciouns of Ismael, sone of Abraham, whom Agar Egipcian, seruauntesse of Sare, childide to Abraham;
13 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
and these ben the names of the sones of Ismael, in her names and generaciouns. The firste gendride of Ismael was Nabaioth, aftirward Cedar, and Abdeel, and Mabsan,
and Masma, and Duma, and Massa,
15 Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
and Adad, and Thema, and Ithur, and Nafir, and Cedma.
16 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
These weren the sones of Ismael, and these weren names by castels and townes of hem, twelue princes of her lynagis.
17 Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
And the yeeris of lijf of Ismael weren maad an hundrid and seuene and thretti, and he failide, and diede, and was put to his puple.
18 Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
Forsothe he enhabitide fro Euila til to Sur, that biholdith Egipt, as me entrith in to Assiriens; he diede bifore alle his britheren.
19 Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
Also these ben the generaciouns of Ysaac sone of Abraham. Abraham gendride Isaac,
20 Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
and whanne Isaac was of fourti yeer, he weddide a wijf, Rebecca, douyter of Batuel, of Sirie of Mesopotanye, the sistir of Laban.
21 Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
And Isaac bisouyte the Lord for his wijf, for sche was bareyn; and the Lord herde him, and yaf conseiuyng to Rebecca.
22 Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
But the litle children weren hurtlid togidre in hir wombe; and sche seide, If it was so to comynge to me, what nede was it to conseyue? And sche yede and axide counsel of the Lord,
23 Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
which answerde, and seide, Twei folkis ben in thi wombe, and twei puplis schulen be departid fro thi wombe, and a puple schal ouercome a puple, and the more schal serue the lesse.
24 Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
Thanne the tyme of childberyng cam, and lo! twei children weren foundun in hir wombe.
25 Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
He that yede out first was reed, and al rouy in the manere of a skyn; and his name was clepid Esau.
26 Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
Anoon the tothir yede out, and helde with the hond the heele of the brother; and therfore he clepide him Jacob. Isaac was sixti yeer eeld, whanne the litle children weren borun.
27 Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
And whanne thei weren woxun, Esau was maad a man kunnynge of huntyng, and a man erthe tilier; forsothe Jacob was a symple man, and dwellide in tabernaclis.
28 Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
Isaac louyde Esau, for he eet of the huntyng of Esau; and Rebecca louyde Jacob.
29 Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
Sotheli Jacob sethide potage; and whanne Esau cam weri fro the feld,
30 Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
he seide to Jacob, Yyue thou to me of this reed sething, for Y am ful weri; for which cause his name was clepid Edom.
31 Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
And Jacob seide to him, Sille to me the riyt of the first gendrid childe.
32 Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
He answerde, Lo! Y die, what schulen the firste gendrid thingis profite to me?
33 Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
Jacob seide, therfor swere thou to me. Therfor Esau swoor, and selde the firste gendrid thingis.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.
And so whanne he hadde take breed and potage, Esau eet and drank, and yede forth, and chargide litil that he hadde seld the riyt of the firste gendrid child.