< Genesis 25 >
1 Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
Abraham loe zu maeto lak let, anih ih ahmin loe Keturah.
2 Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
Anih mah Zimran, Jokshan, Medan, Median, Ishbak hoi Shuah to sak pae.
3 Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
Jokshan mah Sheba hoi Dedan to sak. Dedan ih caanawk loe Asshur kaminawk, Letush kaminawk hoi Leum kaminawk ah oh o.
4 Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
Midian caanawk loe Ephah, Epher, Hanok, Abidah hoi Eldaah. Hae kaminawk boih loe Keturah mah sak ih caanawk ah oh o.
5 Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
Abraham loe a tawnh ih hmuennawk boih Issak hanah paek.
6 Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
Toe a hing naah angmah zula ih caanawk hanah tangqumnawk to a paek moe, nihcae to a capa Issak hma hoi ni angyae bangah patoeh boih.
7 Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
Abraham loe mitong boeh moe, saning cumvai qui sarih, pangato hing.
8 Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
To tiah mitong moe, hinghaih qui apet pacoengah a duek, to pacoengah angmah ih kaminawk khaeah caeh.
9 Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
A caa Issak hoi Ishmael mah Mamre vangpui pha ai nathuem ih, Hit kami Zohar capa Ephron ih lawk thungah kaom, Makpelah thlung khaw thungah aphum hoi.
10 inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
To lawk loe Abraham mah Hit kaminawk khaeah qanh; Abraham hoi a zu Sarah loe to ahmuen ah aphum hoi hmaek.
11 Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
Abraham duek pacoengah, Sithaw mah Issak to tahamhoihaih paek; Issak loe Beer Lahai Roi taengah khosak.
12 Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
Sarah ih tamna Izip tanuh, Hagar mah Abraham han sak pae ih, Abraham capa Ishmael ih caanawk kawng loe hae tiah oh.
13 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
Ishmael caanawk ih ahmin loe, angmacae acaeng anghumhaih ahmin baktih toengah, calu ah Nebajoth, Keder, Adbeel, Mibsam;
15 Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
Hadar, Tema, Jetur, Naphish hoi Kedemah;
16 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
hae kaminawk loe Ishmael ih caa ah oh o, to tiah ahmin kaom kaminawk loe, angmacae ih vangpui, angmacae misa abuephaih baktih toengah, acaeng hatlai hnetto ukkung ah oh o roep.
17 Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ishamael loe saning cumvai qui thum, sarihto hing; a hinghaih qui apet moe, duek pacoengah, angmah ih kaminawk khaeah angkuem.
18 Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
Anih ih caanawk loe Assyria prae caehhaih loklam, Havilah hoi Izip prae ni angyae bang ih Shur vangpui khoek to khosak o; anih loe angmah ih nawkamyanawk boih hma ah duek.
19 Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
Abraham capa, Issak kawng loe hae tiah oh; Abraham mah Issak to sak;
20 Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
Issak loe Padan Aram ahmuen ah kaom, Syria acaeng Bethuel ih canu, Syria acaeng Laban ih tanuh, Rebekah to zu ah lak naah, saning qui palito oh boeh.
21 Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
A zu loe caa kaak pongah, Issak mah a zu hanah Angraeng khaeah lawkthuih pae; Angraeng mah lawkthuihaih lok to tahngaih pae pongah, a zu Rebekah loe zokpomh.
22 Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
A zok thung ih nawkta loe maeto hoi maeto ang-et hoi khing; to naah amno mah, Tipongah hae tiah oh vai? tiah poek. To pongah lokdueng hanah Angraeng khaeah a caeh.
23 Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
Angraeng mah anih khaeah, Na zok thungah kami acaeng hnetto oh; na zok thung hoiah tuinuen kalah acaeng hnetto tacawt tih; acaeng maeto loe kalah acaeng maeto pongah thacak kue ueloe, kacoeh mah kanawk ih tok to sah pae tih, tiah a naa.
24 Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
Nawkta zahhaih tue phak naah, anih zok thung ih nawkta loe angphae.
25 Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
Tacawt hmaloe loe ngan to thim dung, a tak loe amui cing ah oh; to pongah anih to Esau, tiah ahmin phui.
26 Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
To pacoengah amnawk to tapen; a ban hoiah Esau ih khok tahmawh to patawnh; to pongah anih to Jakob, tiah ahmin sak; Rebakah mah nihnik to sak naah, Issak loe saning qui tarukto oh boeh.
27 Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
Nawkta hnik loe qoeng hoi tahang, Esau loe moi kat kop kami, moi zoep thaih kami ah oh; toe Jakob loe kaom duem kami ah oh moe, kahni imthung ah oh.
28 Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
Issak loe taw ih moi to caak pongah Esau to palung, toe Rebekah mah loe Jakob to palung.
29 Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
Nito naah loe Jakob mah caak koi maeto thongh, to naah Esau loe taw hoiah angzoh moe, zok amthlam parai pongah,
30 Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
Esau mah Jakob khaeah, Na thongh ih kamling huep caak koi to na paek thoem ah, zok amthlam parai boeh, tiah a naa. To pongah anih ih ahmin to Edom, tiah sak.
31 Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
To naah Jakob mah, Calu ah na ohhaih to vaihniah kai khaeah na zaw ah, tiah a naa.
32 Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
To naah Esau mah, Khenah, ka duek tom boeh; calu ah ohhaih loe timaw atho oh? tiah a thuih.
33 Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
Jakob mah vaihniah kai khaeah lokkamhaih sah ah, tiah a naa. Esau mah anih khaeah lokkamhaih sak pacoengah, calu ah ohhaih to Jakob khaeah a zawh.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.
To pacoengah Jakob mah takaw hoi peh to Esau hanah paek; anih mah caak moe, naek pacoengah, angthawk moe, a caeh. To tiah Esau mah calu ah ohhaih to khet patoek.