< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Ibraⱨim ⱪerip, yexi bir yǝrgǝ berip ⱪalƣanidi; Pǝrwǝrdigar Ibraⱨimƣa ⱨǝr tǝrǝptǝ bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilƣanidi.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
Ibraⱨim ɵyidiki ǝng mɵtiwǝr hizmǝtkari, ɵzining pütün mal-mülkini baxⱪuridiƣan ƣojidarƣa: — Ⱪolungni yotamning astiƣa ⱪoyƣin;
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
Mǝn seni asmanlarning Hudasi xundaⱪla yǝrning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigarning nami bilǝn ⱪǝsǝm ⱪildurimǝnki, sǝn mǝn ⱨazir turuwatⱪan bu Ⱪanaaniylarning arisidin oƣlumƣa ⱪiz elip bǝrmǝy,
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
Bǝlki ɵz yurtumƣa, xundaⱪla ɵz uruⱪ-tuƣⱪanlirimning ⱪexiƣa berip, oƣlum Isⱨaⱪⱪa hotun elip bǝrgǝysǝn, — dedi.
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
Hizmǝtkari uningƣa: — Mubada u ⱪiz mǝn bilǝn bu yurtⱪa kǝlgili unimisa, undaⱪta ɵzliri qiⱪⱪan xu yurtⱪa oƣullirini yandurup apiramdimǝn? — dedi.
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Ibraⱨim uningƣa jawab berip: — Ⱨezi bol, oƣlumni ⱨǝrgiz xu yǝrgǝ yandurup barmiƣin!
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
Meni atamning ɵyi bilǝn tuƣulƣan yurtumdin yetǝklǝp elip kǝlgüqi, yǝni manga sɵz ⱪilip: — «Sening nǝslinggǝ bu yurtni berimǝn», dǝp manga ⱪǝsǝm ⱪilƣan, asmanning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigar Ɵz Pǝrixtisini aldingƣa ǝwǝtidu; xuning bilǝn sǝn u yǝrdin oƣlumƣa ⱪiz elip kelǝlǝysǝn.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Xundaⱪtimu, ǝgǝr ⱪiz sǝn bilǝn bu yǝrgǝ kǝlgili unimisa, mǝn sanga ⱪilduridiƣan ⱪǝsǝmdin halas bolisǝn; ǝmma oƣlumni u yǝrgǝ ⱨǝrgiz yandurup barmiƣin, — dedi.
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Xuning bilǝn hizmǝtkar ⱪolini hojisi Ibraⱨimning yotisining astiƣa ⱪoyup turup, bu toƣrida uningƣa ⱪǝsǝm ⱪildi.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
Andin hizmǝtkar bu toƣrida hojisining tɵgiliridin onni, xundaⱪla hojisining ⱨǝrhil esil nǝrsilirini elip yolƣa qiⱪti; u Aram-Naⱨaraim rayoniƣa sǝpǝr ⱪilip, Naⱨorning xǝⱨirigǝ yetip kǝldi.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
U xǝⱨǝrning sirtidiki bir ⱪuduⱪning yenida tɵgilirini qɵkündurdi: bu kǝqⱪurun, ⱪiz-ayallarning su tartⱪili qiⱪidiƣan qeƣi idi.
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
U dua ⱪilip: — Əy hojam Ibraⱨimning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigar, ɵtünimǝnki, bügün mening iximni ongƣa tartⱪaysǝn, hojam Ibraⱨimƣa xapaǝt kɵrsǝtkǝysǝn.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Mana mǝn bu yǝrdǝ ⱪuduⱪning bexida turuwatimǝn wǝ xǝⱨǝr hǝlⱪining ⱪizliri bu yǝrgǝ su tartⱪili keliwatidu.
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
Əmdi xundaⱪ bolsunki, mǝn ⱪaysi ⱪizƣa: «Komzikingni qüxürsǝng, mǝn su iqiwalsam boptikǝn!» desǝm, u jawab berip: «Mana iqkin, mǝn tɵgiliringnimu suƣirip ⱪoyay», desǝ, u ⱪiz sǝn ⱪulung Isⱨaⱪⱪa bekitkiningning ɵzi bolsun. Buningdin sening hojam Ibraⱨimƣa xapaǝt ⱪilƣiningni bilǝlǝymǝn, — dedi.
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
U tehi sɵzini tügǝtmǝyla, mana Riwkaⱨ kozini mürisidǝ kɵtürüp qiⱪip kǝldi; u bolsa Ibraⱨimning inisi Naⱨorning ayali Milkaⱨtin tuƣulƣan oƣli Betuǝlning ⱪizi idi;
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
Ⱪiz intayin qirayliⱪ bolup, ⱨeq ǝr kixi tǝgmigǝn pak ⱪiz idi. U ⱪuduⱪning boyiƣa qüxüp, komzikini toldurup andin qiⱪti.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
Hizmǝtkar uning aldiƣa yügürüp berip: — Ɵtünüp ⱪalay, komzikingtin azƣina su otliwalay, dedi.
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
U jawab berip: — Iqkǝyla, ǝy hojam! dǝpla, komzǝkni dǝrⱨal ⱪoliƣa elip, uning su iqixi üqün sundi.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
U süyidin uningƣa ⱪanƣuqǝ iqküzgǝndin keyin: — Tɵgilirigimu ⱪanƣuqǝ su iqküzüp ⱪoyay, — dedi.
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
Xuning bilǝn u dǝrⱨal komzǝktiki suni olaⱪⱪa tɵküwetip, yǝnǝ ⱪuduⱪⱪa su tartⱪili yügürüp bardi; u uning ⱨǝmmǝ tɵgilirigǝ su tartip bǝrdi.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
U kixi uningƣa kɵzini tikkiniqǝ jimjit turup, Pǝrwǝrdigarning yolini ong ⱪilƣan, ⱪilmiƣanliⱪini bilix üqün kütüwatatti.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Tɵgilǝr su iqip ⱪanƣanda, xundaⱪ boldiki, ⱨeliⱪi kixi yerim xǝkǝllik bir altun burun ⱨalⱪisi bilǝn ikki ⱪoliƣa on xǝkǝllik altun bilǝzükni qiⱪirip ⱪizƣa berip uningƣa:
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
Sǝn kimning ⱪizi bolisǝn? Manga dǝp bǝrsǝng! Atangning ɵyidǝ bizgǝ ⱪonƣudǝk jay barmu? — dǝp soridi.
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Ⱪiz uningƣa: — Mǝn Milkaⱨning Naⱨorƣa tuƣup bǝrgǝn oƣli Betuǝlning ⱪizi bolimǝn, — dedi,
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
yǝnǝ uningƣa: — Bizningkidǝ saman bilǝn boƣuz kǝngri, [silǝrgǝ] ⱪonƣili jaymu bar, — dedi.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
Xuan bu adǝm engixip Pǝrwǝrdigarning aldida sǝjdǝ ⱪilip:
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
Ɵz xapaiti bilǝn ⱨojamdin wapadarliⱪini ayimiƣan, hojam Ibraⱨimning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigarƣa Ⱨǝmdusana oⱪulƣay! Pǝrwǝrdigar bu sǝpirimdǝ meni hojamning ⱪerindaxliri turƣan ɵygǝ baxlap kǝldi! — dedi.
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
Ⱪiz yügürüp berip, bularning ⱨǝmmisini anisining ɵydikilǝrgǝ eytip bǝrdi.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Əmdi Riwkaⱨning Laban degǝn bir akisi bar idi. Laban ⱪuduⱪning bexiƣa, u adǝmning ⱪexiƣa yügürüp qiⱪti.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
Qünki u singlisining burun ⱨalⱪisini wǝ ⱪolliridiki bilǝzüklǝrni kɵrüp, ⱨǝmdǝ singlisining: u adǝm manga mundaⱪ-mundaⱪ dedi, deginini anglap, u adǝmning ⱪexiƣa bardi. Mana, u kixi ⱪuduⱪning yenida tɵgilǝrning ⱪexida turatti.
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
Laban uningƣa: — Əy Pǝrwǝrdigarning bǝht-bǝrikiti ata ⱪilinƣuqi, kirgǝyla! Nemǝ üqün taxⱪirida turdila? Mǝn ɵyni tǝyyarlap ⱪoydum, tɵgilǝrgimu jay raslidim, — dedi.
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
U adǝm ɵygǝ kirdi; Laban tɵgilǝrdin yükni qüxürüp, tɵgilǝrgǝ saman bilǝn boƣuz berip, u kixining ⱨǝm uning ⱨǝmraⱨlirining putlirini yuƣili su elip kǝldi;
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
andin u kixining aldiƣa taam ⱪoyuldi; lekin u: — Mǝn gepimni demǝy turup taam yemǝymǝn, — dedi. Laban jawab berip: — Eytⱪayla, dedi.
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
U: — Mǝn bolsam Ibraⱨimning hizmǝtkarimǝn;
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Pǝrwǝrdigar hojamƣa kɵp bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilƣaqⱪa, u uluƣ bir kixi boldi. U uningƣa ⱪoy bilǝn kala, kümüx bilǝn altun, ⱪul bilǝn dedǝklǝrni, tɵgǝ bilǝn exǝklǝrni bǝrdi.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
Hojamning ayali Saraⱨ ⱪeriƣanda hojamƣa bir oƣul tuƣup bǝrgǝnidi. Hojam [oƣliƣa] ɵzining barliⱪini atidi.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
Hojam meni ⱪǝsǝm ⱪildurup: «Sǝn mǝn turuwatⱪan zemindiki Ⱪanaaniylarning ⱪizliridin oƣlumƣa hotun elip bǝrmǝ,
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
bǝlki jǝzmǝn atamning ɵyigǝ, ɵz tuƣⱪanlirimning ⱪexiƣa berip, oƣlumƣa hotun elip bǝrgǝysǝn», — dedi.
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
U waⱪitta mǝn hojamƣa: «U ⱪiz mǝn bilǝn kǝlgili unimisiqu?» — desǝm,
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
u manga jawab berip: «Tutⱪan yollirim uningƣa oquⱪ bolƣan Pǝrwǝrdigarim Ɵz Pǝrixtisini sening bilǝn ǝwǝtip, yolungni ong ⱪilidu. Bu tǝriⱪidǝ sǝn mening ailidikilirim arisidin, atamning jǝmǝti iqidin oƣlumƣa hotun elip berisǝn.
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
Xundaⱪ ⱪilip ailǝmdikilǝrning ⱪexiƣa yetip barƣiningda, sǝn mǝn ⱪildurƣan ⱪǝsǝmdin halas bolisǝn; ular sanga ⱪizni bǝrmisimu ohxaxla ⱪǝsǝmdin halas bolisǝn», — degǝnidi.
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Xunga mǝn bügün bu ⱪuduⱪning ⱪexiƣa kelip: — Əy, hojam Ibraⱨimning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigar, ǝgǝr sǝn bu sǝpirimni ong ⱪilsang: —
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
mana mǝn su ⱪuduⱪining yenida turuwatimǝn; wǝ xundaⱪ bolsunki, su tartⱪili kǝlgǝn ⱪizƣa: «Komzikingdin manga bir otlam su bǝrgǝn bolsang», desǝm,
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
u manga: «Sǝn iqkin, tɵgiliringgimu su tartip berǝy», dǝp jawab bǝrsǝ, undaⱪta bu ⱪiz dǝl Pǝrwǝrdigar Ɵzi hojamning oƣli üqün bekitkǝn ⱪiz bolsun, dǝp dua ⱪilƣanidim.
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
Kɵnglümdǝ tehi sɵzüm tügimǝyla, mana, Riwkaⱨ komzǝkni mürisidǝ kɵtürüp qiⱪip, ⱪuduⱪning boyiƣa qüxüp su tartti; mǝn uningƣa: — Iltipat ⱪilip, manga su iqkili ⱪoysang, dewidim,
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
u dǝrⱨal komzikini mürisidin qüxürüp: «Iqkǝyla, tɵgilirinimu suƣirip ⱪoyay», dedi. Xuning bilǝn mǝn iqtim; u tɵgilirimnimu suƣirip ⱪoydi.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
Andin mǝn uningdin: — Kimning ⱪizi bolisǝn, dǝp sorisam, u jawab berip: — Mǝn Naⱨorning Milkaⱨdin tuƣulƣan oƣli Betuǝlning ⱪizi bolimǝn, — dedi. Xu qaƣda mǝn uning burniƣa ⱨalⱪa, ⱪolliriƣa bilǝzüklǝrni selip ⱪoydum;
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
andin engixip Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪildim; hojamning ⱪerindixining ⱪizini uning oƣli üqün elip ketixkǝ mening yolumni ong ⱪilƣini üqün, hojamning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigarƣa ⱨǝmdusana eyttim.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Əmdi silǝr hojamƣa ihlas ⱪilip xapaǝt kɵrsitǝyli desǝnglar, buni manga dǝnglar. Əgǝr halimisanglar, unimu manga eytinglar, mǝn ong tǝrǝpkǝ yaki sol tǝrǝpkǝ barimǝn, — dedi.
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Əmdi Laban bilǝn Betuǝl jawab berip: — Bu ix Pǝrwǝrdigardin bolƣaq, siligǝ ya undaⱪ ya bundaⱪ deyǝlmǝymiz.
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Mana, Riwkaⱨ aldilirida turidu; uni elip kǝtkǝyla. U Pǝrwǝrdigarning deginidǝk ɵz hojilirining oƣliƣa hotun bolsun, — dedi.
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
Ibraⱨimning hizmǝtkari ularning sɵzlirini anglap, yǝrgǝ engixip, Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪildi.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
Andin, hizmǝtkar kümüx buyumlarni, altun buyumlarni wǝ kiyim-keqǝklǝrni qiⱪirip, bularni Riwkaⱨⱪa bǝrdi; u yǝnǝ ⱪizning akisi wǝ anisiƣimu ⱪimmǝtlik ⱨǝdiyǝlǝrni sundi.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
Andin u wǝ ⱨǝmraⱨliri bilǝn billǝ yǝp-iqip, xu yǝrdǝ ⱪonup ⱪaldi. Ətisi sǝⱨǝrdǝ ⱪopup, u ularƣa: meni hojamning ⱪexiƣa yolƣa selip ⱪoyunglar, dewidi,
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
Ⱪizning akisi bilǝn anisi uningƣa: — Ⱪiz birⱪanqǝ kün yaki on kün yenimizda tursun; andin barsun, — dedi.
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
Əmma u ularƣa: — Pǝrwǝrdigar mening sǝpirimni ong ⱪilƣanikǝn, meni tosmanglar; hojamning ⱪexiƣa berixim üqün meni yolƣa selip ⱪoyunglar, — dedi.
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
Ular uningƣa: — Ⱪizni qaⱪirip, uning aƣzidin anglap baⱪayli, dǝp
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
Riwkaⱨni qaⱪirip uningdin: — Bu adǝm bilǝn baramsǝn? dǝp soriwidi, u: — Baray, dǝp jawab bǝrdi.
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
Xuning bilǝn ular singlisi Riwkaⱨni, uning inik’anisi, Ibraⱨimning hizmǝtkari wǝ adǝmliri bilǝn ⱪoxup yolƣa selip ⱪoydi.
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
U waⱪitta ular Riwkaⱨⱪa bǝht tilǝp: — Əy singlimiz, mingliƣan on mingliƣan adǝmlǝrning anisi bolƣaysǝn! Nǝsling düxmǝnlirining dǝrwaziliriƣa igǝ bolƣay! — dedi.
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Xuning bilǝn Riwkaⱨ bilǝn uning dedǝkliri ornidin turup, tɵgilǝrgǝ minip, u kixigǝ ǝgixip mangdi. Xundaⱪ ⱪilip hizmǝtkar Riwkaⱨni elip yolƣa qiⱪti.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
Isⱨaⱪ Bǝǝr-laⱨay-roy degǝn jaydin bayila ⱪaytip kǝlgǝnidi; qünki u jǝnubtiki Nǝgǝwdǝ turatti;
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
Isⱨaⱪ kǝqⱪurun istiⱪamǝtkǝ dalaƣa qiⱪⱪanidi; u bexini kɵtürüp ⱪarisa, mana tɵgilǝr keliwatatti.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
Riwkaⱨ bexini kɵtürüp, Isⱨaⱪni kɵrdi; u dǝrⱨal tɵgidin qüxüp, hizmǝtkardin: — Sǝⱨrada bizning aldimizƣa qiⱪiwatⱪan bu kixi kim bolidu? — dǝp soridi. Hizmǝtkar: — Bu hojamdur! dedi. Riwkaⱨ dǝrⱨal qümbilini tartip yüzini yepiwaldi.
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Hizmǝtkar ǝmdi ⱪilƣan ⱨǝmmǝ ixlirini Isⱨaⱪⱪa eytip bǝrdi.
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
Isⱨaⱪ ⱪizni anisi Saraⱨning qediriƣa baxlap kirdi; u Riwkaⱨni ɵz ǝmrigǝ aldi; u uning hotuni boldi. U uni yahxi kɵrüp ⱪaldi; bu tǝriⱪidǝ Isⱨaⱪ anisining wapatidin keyin tǝsǝlli tapti.

< Genesis 24 >