< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Abraham var nu gammal och kommen till hög ålder, och HERREN hade välsignat Abraham i alla stycken.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
Då sade han till sin äldste hustjänare, den som förestod all hans egendom: "Lägg din hand under min länd;
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
jag vill av dig taga en ed vid HERREN, himmelens Gud och jordens Gud, att du icke till hustru åt min son skall taga en dotter till någon av kananéerna bland vilka jag bor,
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
utan att du skall gå till mitt eget land och till min släkt och där taga hustru åt min son Isak."
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
Tjänaren sade till honom: "Men om så händer, att kvinnan icke vill följa mig hit till landet, måste jag då föra din son tillbaka till det land som du har kommit ifrån?"
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Abraham svarade honom: "Tag dig till vara för att föra min son dit tillbaka.
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
HERREN, himmelens Gud, som har fört mig bort ifrån min faders hus och ifrån mitt fädernesland, han som har talat till mig och svurit och sagt: 'Åt din säd skall jag giva detta land', han skall sända sin ängel framför dig, så att du därifrån skall kunna få en hustru åt min son.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Men om kvinnan icke vill följa dig, så är du fri ifrån denna din ed till mig. Allenast må du icke föra min son dit tillbaka."
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Då lade tjänaren sin hand under sin herre Abrahams länd och lovade honom detta med ed.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
Och tjänaren tog tio av sin herres kameler och drog åstad med allahanda dyrbara gåvor från sin herre; han stod upp och drog åstad till Nahors stad i Aram-Naharaim.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
Där lät han kamelerna lägra sig utanför staden, vid en vattenbrunn; och det led mot aftonen, den tid då kvinnorna plägade komma ut för att hämta vatten.
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
Och han sade: "HERRE, min herre Abrahams Gud, låt mig i dag få ett lyckosamt möte, och gör nåd med min herre Abraham.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Se, jag står här vid vattenkällan, och stadsbornas döttrar komma hitut för att hämta vatten.
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
Om jag nu säger till en flicka: 'Håll hit din kruka, och låt mig få dricka' och hon då svarar: 'Drick; dina kameler vill jag ock vattna', må hon då vara den som du har utsett åt din tjänare Isak, så skall jag därav veta att du har gjort nåd med min herre."
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Och se, innan han hade slutat att tala, kom Rebecka ditut, en dotter till Betuel, som var son till Milka, Abrahams broder Nahors hustru; och hon bar sin kruka på axeln.
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
Och flickan var mycket fager att skåda, en jungfru som ingen man hade känt. Hon gick nu ned till källan och fyllde sin kruka och steg så upp igen.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
Då skyndade tjänaren emot henne och sade: "Låt mig få dricka litet vatten ur din kruka."
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
Hon svarade: "Drick, min herre" och lyfte strax ned krukan på sin hand och gav honom att dricka.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
Och sedan hon hade givit honom att dricka, sade hon: "Jag vill ock ösa upp vatten åt dina kameler, till dess att de alla hava fått dricka."
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
Och hon tömde strax sin kruka i vattenhon och skyndade åter till brunnen för att hämta vatten och öste så upp åt alla hans kameler.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Men mannen såg på henne under tystnad och undrade om HERREN hade gjort hans resa lyckosam eller icke.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Och när alla kamelerna hade druckit, tog mannen fram en näsring av guld, en halv sikel i vikt, och två armband av guld, tio siklar i vikt,
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
och frågade: "Vems dotter är du? Säg mig det. Och säg mig om vi kunna få natthärbärge i din faders hus?"
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Hon svarade honom: "Jag är dotter till Betuel, Milkas son, som av henne föddes åt Nahor."
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
Och hon sade ytterligare till honom: "Vi hava rikligt med både halm och foder; natthärbärge kan du ock få."
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
Då böjde mannen sig ned och tillbad HERREN
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
och sade: "Lovad vare HERREN, min herre Abrahams Gud, som icke har tagit sin nåd och trofasthet ifrån min herre! Mig har HERREN ledsagat på vägen, hem till min herres fränder."
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
Och flickan skyndade åstad och berättade allt detta i sin moders hus.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Men Rebecka hade en broder som hette Laban. Och Laban skyndade åstad till mannen därute vid källan.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
När han nämligen såg näsringen och armbanden som hans syster bar, och när han hörde huru hans syster Rebecka berättade: 'Så och så talade mannen till mig', då begav han sig ut till mannen, där denne stod hos kamelerna vid källan.
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
Och han sade: "Kom in, du HERRENS välsignade; varför står du härute? Jag har berett plats i huset, och rum finnes för kamelerna."
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
Så kom då mannen in i huset; och man lastade av kamelerna, och tog fram halm och foder åt kamelerna, och vatten till att två hans och hans följeslagares fötter.
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
Och man satte fram mat för honom; men han sade: "Jag vill icke äta, förrän jag har framfört mitt ärende." Laban svarade: "Så tala då."
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
Då sade han: "Jag är Abrahams tjänare.
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Och HERREN har rikligen välsignat min herre, så att han har blivit en mäktig man; han har givit honom får och fäkreatur, silver och guld, tjänare och tjänarinnor, kameler och åsnor.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
Och Sara, min herres hustru, har fött åt min herre en son på sin ålderdom, och åt denne har han givit allt vad han äger.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
Och min herre har tagit en ed av mig och sagt: 'Till hustru åt min son skall du icke taga en dotter till någon av kananéerna i vilkas land jag bor,
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
utan du skall gå till min faders hus och till min släkt och där taga hustru åt min son.'
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
Då sade jag till min herre: 'Men om nu kvinnan icke vill följa med mig?'
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
Han svarade mig: 'HERREN, inför vilken jag har vandrat, skall sända sin ängel med dig och göra din resa lyckosam, så att du åt min son får en hustru av min släkt och av min faders hus;
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
i sådant fall skall du vara löst från din ed till mig, när du har kommit till min släkt. Också om de icke giva henne åt dig, skall du vara fri ifrån eden till mig.'
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Så kom jag i dag till källan, och jag sade: HERRE, min herre Abrahams Gud, om du vill låta den resa på vilken jag är stadd bliva lyckosam,
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
må det då ske, när jag nu står här vid vattenkällan, att om en ung kvinna kommer ut för att hämta vatten och jag säger till henne: 'Låt mig få dricka litet vatten ur din kruka'
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
och hon då svarar mig: 'Drick du; åt dina kameler vill jag ock ösa upp vatten' -- må hon då vara den kvinna som HERREN har utsett åt min herres son.
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
Och innan jag hade slutat att så tala för mig själv, se, då kom Rebecka ut med sin kruka på axeln och gick ned till källan för att hämta vatten. Då sade jag till henne: 'Låt mig få dricka.'
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
Och strax lyfte hon ned sin kruka från axeln och sade: 'Drick; dina kameler vill jag ock vattna.' Så drack jag, och hon vattnade också kamelerna.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
Och jag frågade henne och sade: 'Vems dotter är du?' Hon svarade: 'Jag är dotter till Betuel, Nahors son, som föddes åt honom av Milka.' Då satte jag ringen i hennes näsa och armbanden på hennes armar.
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
Och jag böjde mig ned och tillbad HERREN och lovade HERREN, min herre Abrahams Gud, som hade ledsagat mig på den rätta vägen, så att jag åt hans son skulle få min herres frändes dotter.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Om I nu viljen visa min herre kärlek och trofasthet, så sägen mig det; varom icke, så sägen mig ock det, för att jag då må vända mig åt annat håll, till höger eller till vänster."
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Då svarade Laban och Betuel och sade: "Från HERREN har detta utgått; vi kunna i den saken intet säga till dig, varken ont eller gott.
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Se, där står Rebecka inför dig, tag henne och drag åstad; må hon bliva hustru åt din herres son, såsom HERREN har sagt."
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
När Abrahams tjänare hörde deras ord, föll han ned på jorden och tillbad HERREN.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
Sedan tog tjänaren fram smycken av silver och guld, så ock kläder, och gav detta åt Rebecka. Jämväl åt hennes broder och hennes moder gav han dyrbara skänker.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
Och de åto och drucko, han och hans följeslagare, och stannade sedan där över natten. Men om morgonen, när de hade stått upp, sade han: "Låten mig nu fara till min herre."
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
Då sade hennes broder och hennes moder: "Låt flickan stanna hos oss några dagar, tio eller så; sedan må du fara."
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
Men han svarade dem: "Uppehållen mig icke, eftersom HERREN har gjort min resa lyckosam. Låten mig fara; jag vill resa hem till min herre."
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
Då sade de: "Vi vilja kalla hit flickan och fråga henne själv."
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
Och de kallade Rebecka till sig och sade till henne: "Vill du resa med denne man?" Hon svarade: "Ja."
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
Då bestämde de att deras syster Rebecka jämte sin amma skulle fara med Abrahams tjänare och dennes män.
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
Och de välsignade Rebecka och sade till henne: "Av dig, du vår syster, komme tusen gånger tio tusen, och må dina avkomlingar intaga sina fienders portar."
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Och Rebecka och hennes tärnor stodo upp och satte sig på kamelerna och följde med mannen; så tog tjänaren Rebecka med sig och for sin väg.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
Men Isak var på väg hem från Beer-Lahai-Roi, ty han bodde i Sydlandet.
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
Och mot aftonen hade Isak gått ut på fältet i sorgsna tankar. När han då lyfte upp sina ögon, fick han se kameler komma.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
Då nu också Rebecka lyfte upp sina ögon och fick se Isak, steg hon med hast ned från kamelen;
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
och hon frågade tjänaren: "Vem är den mannen som kommer emot oss där på fältet?" Tjänaren svarade: "Det är min herre." Då tog hon sin slöja och höljde sig i den.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Och tjänaren förtäljde för Isak huru han hade uträttat allt.
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
Och Isak förde henne in i sin moder Saras tält; och han tog Rebecka till sig, och hon blev hans hustru, och han hade henne kär. Så blev Isak tröstad i sorgen efter sin moder.

< Genesis 24 >