< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Un Ābrahāms bija vecs un labi piedzīvojis, un Tas Kungs Ābrahāmu bija svētījis ar visām lietām.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
Tad Ābrahāms sacīja uz savu kalpu, to vecāko savā namā, kas valdīja pār visu, kas viņam bija:
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
Liec jel savu roku apakš manas ciskas, tad es tev likšu zvērēt pie Tā Kunga, tā debes' Dieva un tā zemes Dieva, ka tev manam dēlam nebūs sievu ņemt no Kanaāniešu meitām, kuru vidū es dzīvoju,
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
Bet ka tev būs iet uz manu zemi un pie maniem radiem un manam dēlam Īzakam sievu ņemt.
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
Tad tas kalps uz viņu sacīja: ja tā sieva negribēs man nākt līdzi uz šo zemi, vai man tad tavu dēlu atkal būs aizvest uz to zemi, no kurienes tu izgājis?
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Un Ābrahāms uz to sacīja: sargies, ka tu manu dēlu uz turieni nevedi atpakaļ.
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
Tas Kungs, tas debes' Dievs, kas mani ņēmis no mana tēva nama un no manas dzimtenes un kas ar mani runājis un kas man zvērējis sacīdams: tavam dzimumam Es došu šo zemi, - Tas sūtīs Savu eņģeli tavā priekšā, ka tu manam dēlam vari ņemt sievu no turienes.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Bet ja tā sieva tev negribēs iet līdz, tad tu būsi vaļā no šī mana zvēresta; tikai neved manu dēlu atpakaļ uz turieni.
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Un tas kalps lika savu roku apakš Ābrahāma, sava kunga, ciskas, un tam zvērēja par šo lietu.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
Tad tas kalps ņēma desmit kamieļus no sava kunga kamieļiem un aizgāja, un visāda viņa kunga manta bija viņa rokā; un viņš cēlās un gāja uz Mezopotamiju, uz Nahora pilsētu.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
Un viņš tiem kamieļiem lika apmesties ārā priekš pilsētas pie vienas ūdens akas ap vakara laiku, tai laikā, kad tās smēlējas ārā nāca, un viņš sacīja:
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
Kungs, Tu mana kunga Ābrahāma Dievs, lai man šodien izdodas un dari žēlastību pie mana kunga Ābrahāma.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Redzi, es stāvu pie ūdens akas, un šīs pilsētas ļaužu meitas nāks ārā ūdeni smelt.
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
Tad lai notiek, ka tā jauna meita, uz ko es sacīšu, pasniedz jel savu trauku, ka es varu dzert, - un tā sacīs, dzer, es tavus kamieļus arīdzan dzirdināšu, - ka tā ir tā, ko Tu Savam kalpam Īzakam novēlējis, un ka es pie tā varu atzīt, ka Tu žēlastību esi parādījis manam kungam.
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Un notikās, pirms nekā tas bija pabeidzis runāt, redzi, tad nāca Rebeka ārā, kas bija dzimusi Betuēlim, Milkas, Ābrahāma brāļa, Nahora, sievas dēlam; un tai bija viņas trauks uz pleca.
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
Un tai meitiņai bija ļoti skaists vaigs; tā bija jumprava un neviens vīrs to nebija atzinis; tā nokāpa akā un piepildīja savu trauku un atkal uzkāpa.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
Tad tas kalps steidzās viņai pretī un sacīja: ļauj man jel kādu ūdens malciņu no tava trauka nodzerties.
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
Un tā sacīja: dzer, mans kungs! Un tā steidzās un nolaida to trauku uz savu roku un deva tam dzert.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
Un kad tā viņam bija devusi dzert, tad tā sacīja: es smelšu arī priekš taviem kamieļiem, kamēr tie būs padzirdīti.
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
Un tā steidzās un izlēja savu trauku dzirdināmā silē, un tecēja atkal uz aku smelt un smēla visiem viņa kamieļiem.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Un tas vīrs izbrīnījās par to, klusu ciezdams, ka viņš samanītu, vai Tas Kungs viņa ceļam licis labi izdoties, vai ne.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Un kad tie kamieļi bija padzērušies, tad tas vīrs ņēma vienu zelta pieres sprādzi, - tā svēra pussēķeli - un divus apliekamus roku gredzenus priekš viņas rokām, - tie svēra desmit sēķeļus.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
Un viņš sacīja: meitiņa, kam meita tu esi? Pasaki man jel to: vai priekš mums tava tēva namā vietas, tur naktsmāju dabūt?
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Un tā uz viņu sacīja: es esmu Betuēļa, Milkas dēla, meita, ko tā Nahoram dzemdējusi.
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
Un tā vēl uz viņu sacīja: tur ir arī diezgan salmu un barības pie mums, ir mājošanas vieta.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
Tad tas vīrs Tā Kunga priekšā nomezdamies to pielūdza
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
Un sacīja: slavēts lai ir Tas Kungs, mana kunga Ābrahāma Dievs, kas nav atrāvis Savu žēlastību un patiesību no mana kunga! Jo Tas Kungs mani ir vadījis to ceļu uz mana kunga brāļa namu.
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
Un tā meitiņa tecēja un to pasacīja savas mātes namā.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Un Rebekai bija brālis, Lābans vārdā, un Lābans steidzās pie tā vīra ārā uz aku.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
Un kad viņš to pieres sprādzi un tos roku gredzenus pie savas māsas rokām redzēja un savas māsas Rebekas vārdus dzirdēja, kas sacīja: tā tas vīrs uz mani runājis, - tad tas nāca pie tā vīra, un redzi, tas stāvēja pie tiem kamieļiem pie akas.
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
Un viņš sacīja: nāc iekšā, Tā Kunga svētītais, kam tu stāvi ārā? Jo es esmu namu sataisījis un vieta ir priekš taviem kamieļiem.
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
Tad tas vīrs nāca namā, un tie nosegloja tos kamieļus, un deva tiem kamieļiem salmus un barību un ūdeni, mazgāt viņa kājas un to vīru kājas, kas viņam bija līdz.
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
Un tie viņam cēla priekšā barību; bet viņš sacīja: es neēdīšu, pirms nebūšu runājis savus vārdus. Un tas sacīja: runā.
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
Tad viņš sacīja: es esmu Ābrahāma kalps,
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Un Tas Kungs bagāti ir svētījis manu kungu, un tas ir augumā audzis, un viņš tam ir devis avis un vēršus un sudrabu un zeltu un kalpus un kalpones un kamieļus un ēzeļus.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
Un Sāra, mana kunga sieva, manam kungam ir dzemdējusi dēlu savā vecumā, un tam viņš ir devis visu, kas viņam pieder.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
Un mans kungs man ir licis zvērēt sacīdams: tev manam dēlam nebūs ņemt no tām Kanaāniešu meitām, kuru zemē es dzīvoju.
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
Bet tev būs iet uz mana tēva namu un pie maniem radiem un manam dēlam sievu ņemt.
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
Tad es sacīju uz savu kungu: ja tā sieva man neies līdz.
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
Un viņš uz mani sacīja: Tas Kungs, kura priekšā es esmu staigājis, sūtīs Savu eņģeli ar tevi, un liks labi izdoties tavam ceļam, ka tu manam dēlam ņemi sievu no manas cilts un no mana tēva nama.
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
Tad tu būsi vaļā no mana zvēresta, kad tu iesi pie maniem radiem, un ja viņi tev nedos, tad tu būsi vaļā no mana zvēresta.
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Un es nācu šodien pie tās akas un sacīju: Kungs, Tu mana kunga Ābrahāma Dievs, ja Tu, lūdzams, manam ceļam esi licis labi izdoties, kur es eju,
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
Redzi, es stāvu pie tās ūdens akas: kad nu viena jauna meita nāks smelt, un es viņai sacīšu: dod man jel maķenīt ūdens dzert no tava trauka,
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
Un tā uz mani sacīs: dzer ir tu un ir taviem kamieļiem es smelšu, - ka šī ir tā sieva, ko Tas Kungs mana kunga dēlam novēlējis.
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
Pirms es savā sirdī pabeidzu runāt, redzi, tad Rebeka nāca ārā ar ūdens trauku uz pleca, un tā nokāpa akā un smēla, un es uz to sacīju: dod man lūdzama padzerties.
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
Tad viņa traucās un nocēla savu trauku no sava pleca zemē un sacīja: dzer, un es tavus kamieļus arīdzan dzirdināšu; tad es dzēru, un tie kamieļi arīdzan tapa dzirdināti.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
Un es viņu vaicāju un sacīju: kam meita tu esi? Un tā sacīja: Betuēla, Nahora dēla, meita, ko Milka tam dzemdējusi. Tad es liku to pieres sprādzi uz viņas vaigu un tos roku gredzenus ap viņas rokām.
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
Un es nometos un pielūdzu To Kungu un slavēju To Kungu, mana kunga Ābrahāma Dievu, kas mani to īsteno ceļu bija vadījis, mana kunga brāļa meitu viņa dēlam ņemt par sievu.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Un nu, ja jūs esat tie, kas žēlastību un uzticību pie mana kunga grib parādīt, tad sakāt man to; un ja ne, tad sakāt man ir to; tad es griezīšos, vai pa labo roku vai pa kreiso.
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Tad Lābans un Betuēls atbildēja un sacīja: šī lieta ir no Tā Kunga nākusi, mēs nedz ļauna nedz laba nevaram uz tevi runāt.
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Redzi, Rebeka ir tavā priekšā, ņem to un ej; lai tā ir tava kunga dēla sieva, kā Tas Kungs ir sacījis.
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
Un kad Ābrahāma kalps viņu vārdus dzirdēja, tad viņš Tā Kunga priekšā pie zemes mezdamies To pielūdza.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
Un tas kalps izņēma sudraba un zelta lietas un drēbes, un deva Rebekai un viņas brālim, un viņas mātei tas arī deva dārgas dāvanas.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
Tad tie ēda un dzēra, viņš un tie vīri, kas viņam bija līdz, un palika tur pa nakti. Un tie cēlās rītā, un viņš sacīja: atlaidiet mani pie mana kunga.
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
Tad viņas brālis un viņas māte sacīja: lai tā meitiņa kādas desmit dienas paliek pie mums; pēc tu vari iet.
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
Bet viņš uz tiem sacīja: neaizkavējiet mani, Tas Kungs manam ceļam licis labi izdoties; atlaidiet mani, ka es eju pie sava kunga.
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
Tad tie sacīja: sauksim to meitiņu un jautāsim viņu.
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
Tad tie sauca Rebeku un uz to sacīja: vai tu gribi iet ar šo vīru? Un tā sacīja: es iešu.
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
Tad tie atlaida Rebeku, savu māsu, un viņas emmu, un Ābrahāma kalpu un viņa vīrus.
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
Un tie svētīja Rebeku un uz to sacīja: tu, mūsu māsa, audzi par tūkstošu tūkstošiem, un tavs dzimums lai pārvalda savu ienaidnieku vārtus.
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Un Rebeka cēlās ar savām meitām un sēdās uz kamieļiem un gāja tam vīram līdz, un tas kalps ņēma Rebeku un aizgāja.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
Un Īzaks nāca to ceļu no Lekaj-Roī akas, jo tas mita dienvidu(Negebas) zemē.
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
Bet Īzaks bija izgājis uz lauku Dievu pielūgt ap vakara laiku. Un tas pacēla savas acis un skatījās, un redzi, kamieļi nāca.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
Un Rebeka pacēla savas acis un redzēja Īzaku un nolaidās no kamieļa.
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
Un tā sacīja uz to kalpu: kas tas par vīru, kas tur pa lauku mums nāk pretī? Un tas kalps sacīja: tas ir mans kungs. Tad tā ņēma vaiga apsegu un apsedzās.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Un tas kalps Īzakam visu izteica, ko tas bija darījis.
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
Un Īzaks veda Rebeku savas mātes Sāras dzīvoklī, un viņš to ņēma un tā viņam palika par sievu, un viņš to mīlēja. Tā Īzaks tapa iepriecināts pēc savas mātes nāves.

< Genesis 24 >