< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Na rĩrĩ, Iburahĩmu aarĩ mũkũrũ na agatindĩka mĩaka. Nake Jehova nĩamũrathimĩte maũndũ-inĩ make mothe.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
Nake akĩĩra ndungata ĩrĩa yarĩ nene mũciĩ-inĩ wake, o ĩrĩa yarũgamĩrĩire indo ciothe iria aarĩ nacio atĩrĩ, “Ta iga guoko gwaku rungu rwa kĩero gĩakwa.
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
Nĩngwenda wĩhĩte na rĩĩtwa rĩa Jehova, o we Ngai wa igũrũ na Ngai wa thĩ, atĩ ndũgethera mũrũ wakwa mũtumia kuuma kũrĩ airĩtu a Akaanani aya ndũũraga thĩinĩ wao,
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
no nĩũgathiĩ bũrũri-inĩ wakwa na kũrĩ andũ a nyũmba iitũ, na wethere mũrũ wakwa Isaaka mũtumia kũu.”
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
Ndungata ĩyo ĩkĩmũũria atĩrĩ, “Ĩ mũndũ-wa-nja ũcio angĩkaarega gũũka na niĩ bũrũri-inĩ ũyũ? Ngaacookia mũrũguo bũrũri ũrĩa woimire?”
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Iburahĩmu akĩmwĩra atĩrĩ, “Menyerera, ndũkanacookie mũrũ wakwa kũu!
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
Jehova, o we Ngai wa igũrũ ũrĩa wandutire kuuma nyũmba ya baba na kuuma bũrũri ũrĩa ndaciarĩirwo na akĩnjarĩria na akĩnjĩĩra na mwĩhĩtwa atĩrĩ, ‘Rũciaro rwaku nĩngarũhe bũrũri ũyũ’ we nĩwe ũgaatũma mũraika wake mbere yaku nĩguo ũkoonera mũrũ wakwa mũtumia kuuma kuo.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Mũndũ-wa-nja ũcio angĩkaarega gũũka nawe-rĩ, ndũkoohwo nĩ mwĩhĩtwa ũyũ wakwa; no ndũkanacookie mũrũ wakwa kũu.”
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Nĩ ũndũ ũcio ndungata ĩyo ĩkĩiga guoko kwayo rungu rwa kĩero kĩa Iburahĩmu ũcio mwathi wayo, na ĩkĩĩhĩta na mwĩhĩtwa harĩ we kũringana na ũhoro ũcio.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
Ndungata ĩyo ĩgĩcooka ĩkĩoya ngamĩĩra ikũmi cia mwathi wayo na ĩkiumagara ĩkuĩte mĩthemba yothe ya indo njega kuuma kũrĩ mwathi wayo. Ĩgĩthiĩ ĩgĩkinya itũũra rĩrĩa Nahoru aatũũraga mwena wa gathigathini-ithũĩro wa Mesopotamia.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
Nayo ĩgĩtũma ngamĩĩra ikome nja ya itũũra hakuhĩ na gĩthima kĩa maaĩ; kwarĩ kĩhwaĩ-inĩ rĩrĩa andũ-a-nja maathiiaga gũtaha maaĩ.
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
Ĩgĩcooka ĩkĩhooya, ĩkiuga atĩrĩ, “Wee Jehova, Ngai wa Iburahĩmu mwathi wakwa, tũma ngaacĩre ũmũthĩ na ũtuge mwathi wakwa Iburahĩmu.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Rora, ndũgamĩte haha gĩthima-inĩ kĩa maaĩ, nao airĩtu a ene itũũra nĩ maroka gũtaha maaĩ.
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
Kũrotuĩka atĩrĩ, atĩ rĩrĩa ndĩrĩĩra mũirĩtu atĩrĩ, ‘Ndakũhooya, he ndigithũ yaku nyue maaĩ,’ nake oige atĩrĩ, ‘Nyua na nĩngũtahĩra o na ngamĩĩra ciaku,’ reke ũcio atuĩke nĩwe ũthuurĩire ndungata yaku Isaaka. Na ũndũ ũcio ũtũme niĩ menye atĩ nĩũtugĩte mwathi wakwa.”
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Ĩtanarĩkia kũhooya-rĩ, Rebeka agĩũka akuuĩte ndigithũ kĩande-inĩ. Aarĩ mũirĩtu wa Bethueli mũrũ wa Milika, ũrĩa warĩ mũtumia wa Nahoru mũrũ wa nyina na Iburahĩmu.
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
Mũirĩtu ũcio aarĩ mũthaka mũno, mũirĩtu gathirange; gũtirĩ mũndũ mũrũme wakomete nake. Agĩikũrũka gĩthima-inĩ kĩa maaĩ, akĩiyũria ndigithũ yake maaĩ, agĩcooka akĩambata rĩngĩ.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
Nayo ndungata ĩyo ĩkĩhiũha ĩkamũtũnge, na ĩkĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha, he tũũĩ tũnini twa kũnyua kuuma ndigithũ-inĩ yaku.”
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
Nake agĩcookia atĩrĩ, “Mwathi wakwa, nyua,” nake akĩruta ndigithũ mũtwe na ihenya, akĩmĩnyiita na moko, na akĩmũhe maaĩ.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
Na aarĩkia kũmũhe maaĩ ma kũnyua, agĩcooka akiuga atĩrĩ, “Nĩngũtahĩra ngamĩĩra ciaku, o nacio o nginya ciiganie kũnyua.”
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
Agĩkĩonoreria maaĩ marĩa maarĩ ndigithũ yake mũharatĩ-inĩ na ihenya, agĩcooka agĩtengʼera gĩthima-inĩ gũtaha maaĩ mangĩ, agĩtaha ma kũigana ngamĩĩra ciake ciothe.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Mũndũ ũcio akĩmwĩrorera atekwaria, nĩguo amenye kana Jehova nĩagacĩrithĩtie rũgendo rwake kana ndaarũgacĩrithĩtie.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Rĩrĩa ngamĩĩra ciarĩkirie kũnyua maaĩ-rĩ, mũndũ ũcio akĩruta gĩcũhĩ kĩa iniũrũ gĩa thahabu kĩa ũritũ wa nuthu cekeri, na bangiri igĩrĩ cia thahabu cia ũritũ wa cekeri ikũmi, akĩmwĩkĩra.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
Agĩcooka akĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũrĩ mwarĩ wa ũ? Ndagũthaitha ta njĩĩra atĩrĩ, mũciĩ gwa thoguo-rĩ, he handũ tũngĩrarĩrĩra?”
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ndĩ mwarĩ wa Bethueli, mũriũ ũrĩa Milika aaciarĩire Nahoru.”
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
Ningĩ akĩmwĩra atĩrĩ, “Tũrĩ na riya na nyeki nyingĩ, o na handũ wee ũngĩrarĩrĩra.”
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
Mũndũ ũcio akĩinamĩrĩra thĩ, akĩhooya Jehova,
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
akiuga atĩrĩ, “Jehova arogaathwo, o we Ngai wa Iburahĩmu mwathi wakwa, o ũcio ũtatigĩte kuonania ũtugi na wĩhokeku wake kũrĩ mwathi wakwa. Hakwa-rĩ, Jehova nĩandongoretie rũgendo-inĩ, akanginyia kwa andũ a nyũmba ya mwathi wakwa.”
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
Nake mũirĩtu ũcio agĩtengʼera, agĩthiĩ akĩhe andũ a nyũmba ya nyina ndeto icio.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Na rĩrĩ, Rebeka aarĩ na mũrũ wa nyina wetagwo Labani, nake akiumagara ahiũhĩte, agĩthiĩ kũrĩ mũndũ ũcio hau gĩthima-inĩ kĩa maaĩ.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
Rĩrĩa onire gĩcũhĩ kĩu kĩa iniũrũ na bangiri irĩ moko-inĩ ma mwarĩ wa nyina, na aigua Rebeka akiuga ũrĩa mũndũ ũcio aamwĩrĩte-rĩ, agĩthiĩ kũrĩ mũndũ ũcio, akĩmũkora arũgamĩte harĩ ngamĩĩra ciake hakuhĩ na gĩthima kĩa maaĩ.
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
Akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka tũthiĩ mũciĩ, wee ũrathimĩtwo nĩ Jehova. Ũrũgamĩte haha nja nĩkĩ? Nĩhaarĩirie nyũmba yaku na handũ ha ngamĩĩra.”
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
Nĩ ũndũ ũcio mũndũ ũcio agĩtoonya nyũmba, nacio ngamĩĩra ikĩaũrwo mĩrigo. Ngamĩĩra ikĩreherwo riya na nyeki, nake mũndũ ũcio na andũ arĩa aarĩ nao makĩreherwo maaĩ ma gwĩthamba magũrũ.
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
Ningĩ akĩreherwo irio, nowe akiuga atĩrĩ, “Niĩ ndingĩrĩa, itambĩte kũmwĩra ũndũ ũrĩa ũndehete gũkũ.” Nake Labani akĩmwĩra atĩrĩ, “Gĩtwĩre.”
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
Nake agĩkiuga atĩrĩ, “Niĩ ndĩ ndungata ya Iburahĩmu.”
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
“Jehova nĩarathimĩte mwathi wakwa mũno, na nĩ atongete mũno. Nĩamũheete ngʼondu na ngʼombe, betha na thahabu, ndungata cia arũme na cia andũ-a-nja, na ngamĩĩra o na ndigiri.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
Nake Sara mũtumia wa mwathi wakwa nĩamũciarĩire kĩmwana arĩ o mũkũrũ, nake nĩakĩheete indo ciake ciothe.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
Nake mwathi wakwa agĩtũma ndĩĩhĩte akĩnjĩĩra atĩrĩ, ‘Ndũkanethere mũriũ wakwa mũtumia kuuma kũrĩ airĩtu a Akaanani, a gũkũ bũrũri ũyũ ndũũraga,
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
no ũthiĩ kũrĩ nyũmba ya baba na kũrĩ mũhĩrĩga wakwa, na ũrutĩre mũriũ wakwa mũtumia kuo.’
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
“Ningĩ ngĩũria mwathi wakwa atĩrĩ, ‘Ĩ mũndũ-wa-nja ũcio angĩrega gũũka na niĩ?’
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
“Nake akĩnjookeria atĩrĩ, ‘Jehova ũrĩa ndũire thiiaga mbere yake, nĩagatũma mũraika wake athiĩ nawe, na atũme rũgendo rwaku rũgaacĩre, nĩgeetha ũkaarutĩra mũriũ wakwa mũtumia kuuma kũrĩ mũhĩrĩga wakwa na kuuma kũrĩ andũ a nyũmba ya baba.
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
Ningĩ wathiĩ kũrĩ mũhĩrĩga wakwa-rĩ, nĩũkohorwo kuuma kũrĩ mwĩhĩtwa wakwa; o na mangĩkaarega kũmũnengerana kũrĩ we, nĩũkohorwo kuuma kũrĩ mwĩhĩtwa ũcio wakwa.’”
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Agĩthiĩ na mbere, akiuga atĩrĩ, “Ũmũthĩ rĩrĩa nginyire gĩthima-inĩ kĩa maaĩ, njugire atĩrĩ, ‘Wee Jehova Ngai wa Iburahĩmu mwathi wakwa, ũngĩenda, ndagũthaitha, gaacĩrithia rũgendo rũrũ njũkĩte.
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
Ta kĩone, nũngiĩ haha gĩthima-inĩ kĩa maaĩ; mũirĩtu angĩũka gũtaha maaĩ na niĩ ndĩmwĩre atĩrĩ, “Ĩtĩkĩra nyue tũũĩ tũnini kuuma ndigithũ-inĩ yaku,”
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
nake angĩnjĩĩra atĩrĩ, “Nyua na nĩngũtahĩra ngamĩĩra ciaku o nacio,” nĩagĩtuĩke nĩwe mũndũ-wa-nja ũrĩa Jehova athuurĩire mũriũ wa mwathi wakwa.’
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
“Itanarĩkia kũhooya ũguo na ngoro-rĩ, Rebeka oka arĩ na ndigithũ yake kĩande. Nake aikũrũka gĩthima-inĩ kĩa maaĩ, aataha maaĩ na niĩ ndamwĩra atĩrĩ, ‘Ndagũthaitha he maaĩ nyue.’
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
“Aaruta ndigithũ yake kĩande o naihenya anjĩĩra atĩrĩ, ‘Nyua, na nĩngũnyuithia o na ngamĩĩra ciaku.’ Nĩ ũndũ ũcio ndanyua maaĩ na ahe ngamĩĩra o nacio.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
“Na niĩ ndamũũria atĩrĩ, ‘Ũrĩ mwarĩ wa ũ?’ “Nake anjookeria atĩrĩ, ‘Ndĩ mwarĩ wa Bethueli mũrũ wa Nahoru, ũrĩa Milika aamũciarĩire.’ “Na niĩ ndakĩmwĩkĩra gĩcũhĩ iniũrũ, na bangiri moko,
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
ndacooka ndainamĩrĩra ndahooya Jehova. Ndagatha Jehova, o we Ngai wa Iburahĩmu mwathi wakwa, ũrĩa ũndongoretie na njĩra ĩrĩa njagĩrĩru nyonere mũrũ wa mwathi wakwa mwarĩ wa mũriũ wa mũrũ wa nyina nake.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Na rĩrĩ, angĩkorwo nĩ mũkuonania ũtugi na wĩhokeku kũrĩ mwathi wakwa, njĩĩrai; na angĩkorwo tiguo, mũnjĩĩre nĩgeetha na niĩ menye na kũrĩa ngũrora.”
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Labani na Bethueli magĩcookia atĩrĩ, “Ũndũ ũyũ uumĩte kũrĩ Jehova; ithuĩ tũngĩgĩkwĩra atĩa?
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Rebeka nĩwe ũyũ; muoe mũthiĩ agatuĩke mũtumia wa mũriũ wa mwathi waku, o ta ũrĩa Jehova oigĩte.”
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
Rĩrĩa ndungata ya Iburahĩmu yaiguire ũrĩa moigire, ĩkĩinamĩrĩra, ĩgĩturumithia ũthiũ wayo thĩ mbere ya Jehova.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
Ningĩ ndungata ĩyo ĩkĩruta thahabu, na mathaga ma betha na nguo, na ĩgĩcihe Rebeka; ĩgĩcooka ĩkĩhe Labani mũrũ wa nyina, o na nyina, iheo cia goro.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
Ndungata ĩyo na andũ arĩa yarĩ nao makĩrĩa na makĩnyua, na makĩraara kũu ũtukũ ũcio. Na rĩrĩa mookĩrire mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, ĩkiuga atĩrĩ, “Rekei ndĩthiĩre kũrĩ mwathi wakwa.”
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
No Labani mũrũ wa nyina na mũirĩtu, o na nyina, makiuga atĩrĩ, “Reke mũirĩtu ũyũ aikare na ithuĩ ta matukũ ikũmi; mũcooke mũthiĩ.”
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
No yo ĩkĩmeera atĩrĩ, “Tigai kũngiria thiĩ, kuona atĩ Jehova nĩagacĩrithĩtie rũgendo rwakwa. Rekei ndĩthiĩre kũrĩ mwathi wakwa.”
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
Nao makiuga atĩrĩ, “Rekei twĩte mũirĩtu tũmũũrie ũhoro ũcio.”
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
Nĩ ũndũ ũcio magĩĩta Rebeka, makĩmũũria atĩrĩ, “Nĩũgũthiĩ na mũndũ ũyũ?” Nake akiuga atĩrĩ, “Nĩngũthiĩ.”
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
Nĩ ũndũ ũcio magĩtĩkĩria Rebeka mwarĩ wa nyina ũcio ethiĩre, hamwe na mũmũrori, na ndungata ya Iburahĩmu na andũ ake.
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
Nao magĩkĩrathima Rebeka makĩmwĩra atĩrĩ, “Mwarĩ wa maitũ, ũroingĩha ũtuĩke nyina wa ngiri maita ngiri, naruo rũciaro rwaku rũroĩgwatĩra ihingo cia thũ ciao.”
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Nake Rebeka na ndungata ciake, cia andũ-a-nja, makĩĩhaarĩria na makĩhaica ngamĩĩra, na magĩthiĩ na mũndũ ũcio. Nĩ ũndũ ũcio ndungata ĩyo ĩkĩoya Rebeka ĩgĩĩthiĩra.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
Na rĩrĩ, Isaaka nĩoimĩte Biri-Lahai-Roi, nĩ ũndũ aatũũraga Negevu.
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
Hwaĩ-inĩ ũmwe-rĩ, nĩathiire na kũu mũgũnda-inĩ agecũũranganie, na aatiira maitho, akĩona ngamĩĩra ciũkĩte.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
O nake Rebeka agĩtiira maitho akĩona Isaaka. Akiuma ngamĩĩra igũrũ,
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
na akĩũria ndungata ĩyo atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa ũrĩ kũũrĩa mũgũnda ũroka gũtũtũnga nũũ?” Ndungata ĩyo ĩgĩcookia atĩrĩ, “Nĩ mwathi wakwa.” Nake Rebeka akĩoya taama wake akĩĩhumbĩra.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Nayo ndungata ĩyo ĩkĩĩra Isaaka ũrĩa wothe yekĩte.
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
Nake Isaaka agĩtoonyia Rebeka hema-inĩ ya nyina Sara, akĩmũhikia. Nĩ ũndũ ũcio agĩtuĩka mũtumia wake, na akĩmwenda; nake Isaaka akĩhoorerio ihooru rĩa gĩkuũ kĩa nyina.

< Genesis 24 >