< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Forsothe Abraham was eld, and of many daies, and the Lord hadde blessid hym in alle thingis.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
And he seide to the eldere seruaunt of his hows, that was souereyn on alle thingis that he hadde, Put thou thin hond vndur myn hipe,
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
that Y coniure thee bi the Lord God of heuene and of erthe, that thou take not a wijf to my sone of the douytris of Chanaan, among whiche Y dwelle;
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
but that thou go to my lond and kynrede, and therof take a wijf to my sone Ysaac.
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
The seruaunt aunswerde, If the womman nyle come with me in to this lond, whether Y owe lede ayen thi sone to the place, fro which thou yedist out?
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Abraham seide, Be war, lest ony tyme thou lede ayen thidur my sone;
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
the Lord of heuene that took me fro the hows of my fadir, and fro the lond of my birthe, which spak to me, and swoor, and seide, Y schal yyue this lond to thi seed, he schal sende his aungel bifore thee, and thou schalt take fro thennus a wijf to my sone; forsothe if the womman nyle sue thee,
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
thou schalt not be holdun bi the ooth; netheles lede not ayen my sone thidur.
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Therfore the seruaunt puttide his hond vndur the hipe of Abraham, his lord, and swoor to him on this word.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
And he took ten camels of the floc of his lord, and yede forth, and bar with him of alle the goodis of his lord; and he yede forth, and cam to Mesopotanye, to the citee of Nachor.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
And whanne he hadde maad the camels to reste with out the citee, bisidis the pit of watir, in the euentid, in that tyme in which wymmen ben wont to go out to drawe watir,
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
he seide, Lord God of my lord Abraham, Y biseche, meete with me to dai, and do mersi with my lord Abraham.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Lo! Y stonde nyy the welle of watir, and the douytris of enhabiters of this citee schulen go out to drawe watir;
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
therfor the damysel to which Y schal seie, Bowe doun thi watir pot that Y drynke, and schal answere, Drynke thou, but also Y schal yyue drynke to thi camels, thilke it is which thou hast maad redi to thi seruaunt Ysaac; and bi this Y schal vndirstonde that thou hast do mersi with my lord Abraham.
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
And he hadde not yit fillid the wordis with ynne hym silf, and lo! Rebecca, the douytir of Batuel, sone of Melcha, wijf of Nachor, brothir of Abraham, yede out, hauynge a watir pot in hir schuldre;
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
a damysel ful comeli, and faireste virgyn, and vnknowun of man. Sotheli sche cam doun to the welle, and fillide the watir pot, and turnide ayen.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
And the seruaunt mette hir, and seide, Yyue thou to me a litil of the watir of thi pot to drynke.
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
Which answerde, Drynke thou, my lord. And anoon sche dide doun the watir pot on hir schuldre, and yaf drynk to hym.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
And whanne he hadde drunke, sche addide, But also Y schal drawe watir to thi camelis, til alle drynken.
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
And sche helde out the watir pot in trouyis, and ran ayen to the pit, to drawe watir, and sche yaf watir drawun to alle the camels.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Sotheli he bihelde hir priueli, and wolde wite whether the Lord hadde sped his wei, ethir nay.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Therfor after that the camels drunken, the man brouyte forth goldun eere ryngis, weiynge twei siclis, and as many bies of the arm, in the weiyte of ten siclis.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
And he seide to hir, Whos douyter art thou? schewe thou to me, is ony place in the hows of thi fadir to dwelle?
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Which answerde, Y am the douyter of Batuel, sone of Nachor, whom Melcha childide to him.
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
And sche addide, seiynge, Also ful myche of prouendre and of hey is at vs, and a large place to dwelle.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
The man bowide hym silf,
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
and worschipide the Lord, and seide, Blessid be the Lord God of my lord Abraham, which God took not aweie his mersy and treuthe fro my lord, and ledde me bi riyt weie in to the hous of the brother of my lord.
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
And so the damesel ran, and telde in the hous of hir modir alle thingis whiche sche hadde herd.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Sotheli Rebecca hadde a brothir, Laban bi name, whiche yede out hastili to the man, where he was with out forth.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
And whanne he hadde seyn the eere ryngis and byes of the arm in the hondis of his sister, and hadde herd alle the wordis of hir tellynge, the man spak to me these thingis, he cam to the man that stood bisidis the camels, and nyy the welle of watir,
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
and seide to him, Entre thou, the blessid of the Lord; whi stondist thou with outforth? I haue maad redi the hows, and a place to thi camels.
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
And he brouyte hym in to the ynne, and unsadlide the camels, and yaf prouendre, and hey, and watir to waische the feet of camels, and of men that camen with hym.
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
And breed was set forth in his siyt, which seide, Y schal not ete til Y speke my wordis. He answerde to the man, Speke thou.
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
And the man seide, Y am the seruaunt of Abraham,
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
and the Lord hath blessid my lord greetli, and he is maad greet; and God yaf to hym scheep, and oxun, siluer, and gold, seruauntis, and handmaides, camels, and assis.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
And Sare, `the wijf of my lord, childide a sone to my lord in his eelde, and he yaf alle thingis that he hadde to that sone.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
And my lord chargide me greetli, and seide, Thou schalt not take to my sone a wijf of the douytris of Canaan, in whos lond Y dwelle,
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
but thou schalt go to the hous of my fadir, and of myn kynrede thou schalt take a wijf to my sone.
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
Forsothe Y answerde to my lord, What if the womman nyle come with me?
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
He seide, The Lord in whose siyt Y go, schal sende his aungel with thee, and he schal dresse thi weie; and thou schalt take a wijf to my sone of my kynrede, and of my fadris hows.
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
Thou schalt be innocent fro my curs, whanne thou comest to my kynesmen, and thei yyuen not `the womman to thee.
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Therfor Y cam to day to the welle of watir, and Y seide, Lord God of my lord Abraham, if thou hast dressid my weie in which Y go now, lo!
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
Y stonde bisidis the welle of watir, and the maide that schal go out to drawe watir herith me, yyue thou to me a litil of water to drynke of thi pot,
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
and seith to me, And thou drynke, and Y schal drawe watir to thi camels, thilke is the womman which the Lord hath maad redi to the sone of my lord.
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
While Y turnede in thouyte these thingis with me, Rebecca apperide, comynge with a pot which sche bare in the schuldre; and sche yede doun to the welle, and drowe watir. And Y seide to hir, Yyue thou a litil to me to drynke; and sche hastide,
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
and dide doun the pot of the schuldre, and seide to me, And thou drynke, and Y schal yyue drynke to thi camels; Y drank, and watride the camels.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
And Y axide hir, and seide, Whos douytir art thou? Which answerde, Y am the douytir of Batuel, sone of Nachor, whom Melcha childide to him. And so Y hangide eere ryngis to ourne hir face, and Y puttide bies of the arm in hir hondis,
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
and lowliche Y worschipide the Lord, and Y blessid the Lord God of my lord Abraham, which God ledde me bi riyt weie, that Y schulde take the douytir of the brothir of my lord to his sone.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Wherfor if ye don mercy and treuthe with `my lord, schewe ye to me; ellis if othir thing plesith, also seie ye this, that Y go to the riyt side ethir to the left side.
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Laban and Batuel answeriden, The word is gon out of the Lord; we moun not speke ony other thing with thee without his plesaunce.
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Lo! Rebecca is bifore thee; take thou hir, and go forth, and be sche wijf of the sone of thi lord, as the Lord spak.
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
And whanne the child of Abraham hadde herd this, he felde doun, and worschipide the Lord in erthe.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
And whanne vessels of siluer, and of gold, and clothis weren brouyt forth, he yaf tho to Rebecca for yifte, and he yaf yiftis to hir britheren, and modir.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
And whanne a feeste was maad, thei eeten and drunken to gider, and dwelliden there. Forsothe the child roos eerli, and spak, Delyuere ye me, that Y go to my lord.
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
Hir britheren and modir answerden, The damesele dwelle nameli ten daies at vs, and aftirward sche schal go forth.
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
The child seide, Nyle ye holde me, for the Lord hath dressid my weie; delyuere ye me, that I go to my lord.
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
And thei seiden, Clepe we the damysele, and axe we hir wille.
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
And whanne sche was clepid, and cam, thei axiden, Wolt thou go with this man?
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
And sche seide, Y schal go. Therfor they delyueriden hir, and hir nurse, and the seruaunt of Abraham, and hise felowis, and wischiden prosperitees to her sister,
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
and seiden, Thou art oure sister, encreesse thou in to a thousand thousandis, and thi seed gete the yatis of hise enemyes.
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Therfor Rebecca and hir damesels stieden on the camels, and sueden the man, which turnede ayen hasteli to his lord.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
In that tyme Ysaac walkide bi the weie that ledith to the pit, whos name is of hym that lyueth and seeth; for he dwellide in the south lond.
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
And he yede out to thenke in the feeld, for the dai was `bowid thanne; and whanne he hadde reisid the iyen, he seiy camels comynge afer.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
And whanne Ysaac was seyn, Rebecca liyte doun of the camel,
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
and seide to the child, Who is that man that cometh bi the feeld in to the metyng of vs? And the child seide to hir, He is my lord. And sche took soone a mentil, and hilide hir.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Forsothe the seruaunt tolde to his lord Ysaac alle thingis whiche he hadde do;
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
which Ysaac ledde hir in to the tabernacle of Sare, his modir, and took hir to wijf; and so myche he louede hir, that he temperide the sorewe which bifelde of the deeth of the modir.

< Genesis 24 >