< Genesis 24 >

1 Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
Og Abraham var gammel, vel ved Alder, og Herren havde velsignet Abraham i alting.
2 Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
Og Abraham sagde til sin ældste Svend i sit Hus, som raadede over alt hans Gods: Kære, læg din Haand under min Lænd,
3 Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
og jeg vil lade dig sværge ved Herren, Himmelens Gud og Jordens Gud, at du ikke skal tage min Søn en Hustru af Kananiternes Døtre, iblandt hvilke jeg bor;
4 Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
men du skal gaa til mit Land og til min Slægt og tage min Søn Isak en Hustru.
5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
Og Svenden sagde til ham: Maaske Kvinden ikke vil drage med mig til dette Land; skal jeg da vel føre din Søn tilbage til det Land, som du er kommen fra?
6 Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Og Abraham sagde til ham: Forvar dig, at du ikke fører min Søn did igen.
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
Herren, Himmelens Gud, som tog mig fra min Faders Hus og fra min Slægts Land, og som talede med mig, og som tilsvor mig og sagde: dette Land vil jeg give din Sæd, han skal sende sin Engel for dig, at du skal tage min Søn en Hustru derfra.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
Men dersom Kvinden ikke vil følge dig, da skal du være fri for denne min Ed; ikkun min Søn skal du ikke føre derhen.
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Da lagde Svenden sin Haand under Abrahams, sin Herres, Lænd og tilsvor ham om denne Sag.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
Saa tog Svenden ti Kameler af sin Herres Kameler og for bort og havde alle Haande af sin Herres Gods med sig og gjorde sig rede og drog til Aram Naharaim, til Nakors Stad.
11 ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
Der lod han Kamelerne lægge sig uden for Staden ved en Vandbrønd mod Aftens Tid, mod den Tid da Kvinderne gaa ud at drage Vand.
12 Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
Og han sagde: Herre, min Herre Abrahams Gud! Kære, lad det møde mig i Dag, og gør Miskundhed mod min Herre Abraham.
13 Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
Se, jeg staar ved denne Vandbrønd, og Byens Folks Døtre komme ud at drage Vand.
14 Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
Og naar det sker, at der kommer en Pige, til hvem jeg siger: Bøj nu din Krukke ned og lad mig drikke, og hun siger: Drik, og jeg vil ogsaa give dine Kameler at drikke, lad hende da være den, som du har udset til din Tjener Isak, saa jeg derpaa kan kende, at du har gjort Miskundhed mod min Herre.
15 Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Og det skete, før han havde endt at tale, se, da kom Rebekka ud, som var en Datter af Bethuel, som var en Søn af Milka, Nakors, Abrahams Broders, Hustru, og hendes Krukke var paa hendes Skulder.
16 Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
Og Pigen var meget smuk af Anseelse, en Jomfru, og ingen Mand havde kendt hende, og hun gik ned til Brønden og fyldte sin Krukke og gik op.
17 Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
Da løb Svenden imod hende og sagde: Kære, lad mig drikke lidt Vand af din Krukke.
18 Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
Og hun sagde: Drik, min Herre! og hun skyndte sig og tog sin Krukke ned i sin Haand og gav ham at drikke.
19 Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
Der hun havde givet ham at drikke, da sagde hun: Jeg vil og drage Vand til dine Kameler, til de have afdrukket.
20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
Og hun skyndte sig og tømte sin Krukke i Truget og løb fremdeles til Brønden at øse, og hun drog til alle hans Kameler.
21 Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Og Manden undrede sig over hende, tav dog stille for at faa at vide, om Herren havde ladet hans Rejse lykkes eller ej.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
Og det skete, der Kamelerne havde afdrukket, gav Manden hende en Guldring, som vejede en halv Sekel, og satte to Armbaand paa hendes Hænder, de vejede ti Guldsekler.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
Og han sagde: Hvis Datter er du? Kære, sig mig, monne der være Rum i din Faders Hus at give os Nattely?
24 Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
Og hun sagde til ham: Jeg er en Datter af Bethuel, som er en Søn af Milka, der fødte ham for Nakor.
25 Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
Og hun sagde til ham: Der er baade Straa og meget Foder hos os, ogsaa er der Rum til Herberge i Nat.
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
Og Manden bøjede sig og tilbad Herren.
27 wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
Og han sagde: Lovet være Herren, min Herre Abrahams Gud, som ikke har afladt med sin Miskundhed og sin Trofasthed mod min Herre! mig, ja, mig har Herren ført paa Vejen til min Herres Broders Hus.
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
Og Pigen løb og kundgjorde i sin Moders Hus disse Ting.
29 Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
Og Rebekka havde en Broder, og hans Navn var Laban, og Laban løb ud til Manden, til Brønden.
30 Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
Og det skete, der han saa Ringen og Armbaandene paa sin Søsters Hænder, og der han hørte Rebekkas, sin Søsters, Ord, at hun sagde: Saaledes har Manden sagt til mig, da kom han til Manden, og se, han stod hos Kamelerne ved Brønden.
31 Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
Og han sagde: Kom ind, du Herrens Velsignede, hvi staar du herude? thi jeg har beredt Huset, og der er Rum for Kamelerne.
32 Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
Saa kom Manden i Huset og løste Kamelerne, og han gav Straa og Foder til Kamelerne, og Vand til at to hans Fødder og de Mænds Fødder, som vare med ham.
33 Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
Og der blev sat Mad for ham; men han sagde: Jeg vil ikke æde, før jeg har udsagt mit Ærinde; og han sagde: Tal!
34 Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
Og han sagde: Jeg er Abrahams Svend.
35 Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Og Herren har velsignet min Herre meget, at han er bleven mægtig; og han har givet ham Faar og Kvæg og Sølv og Guld og Svende og Tjenestepiger og Kameler og Asener.
36 Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
Og Sara, min Herres Hustru, har født min Herre en Søn, efter at hun var gammel, og denne har han givet alt det, han ejer.
37 Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
Og min Herre har taget en Ed af mig og sagt: Du skal ikke tage min Søn en Hustru af Kananiternes Døtre, i hvis Land jeg bor.
38 ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
Men du skal fare hen til min Faders Hus og til min Slægt og tage min Søn en Hustru.
39 “Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
Og jeg sagde til min Herre: Maaske Kvinden ikke vil drage med mig.
40 “Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
Og han sagde til mig: Herren, for hvis Ansigt jeg har vandret, skal sende sin Engel med dig og give dig en lyksalig Rejse, og du skal tage min Søn en Hustru af min Slægt og af min Faders Hus.
41 Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
Da skal du være fri for min Ed, naar du kommer til min Slægt; og om de ikke ville give dig hende, saa er du fri for min Ed.
42 “Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
Saa kom jeg i Dag til Brønden og sagde: Herre, min Herre Abrahams Gud! Kære, dersom du har givet Lykke paa min Rejse, paa hvilken jeg har vandret,
43 Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
se, jeg staar ved denne Vandbrønd, og naar det sker, der kommer en Jomfru ud at drage Vand, og jeg siger til hende: Giv mig nu lidet Vand at drikke af din Krukke;
44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
og hun siger mig: Baade maa du drikke, og jeg vil ogsaa øse til dine Kameler, lad hende være den Kvinde, som Herren har udset til min Herres Søn.
45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
Førend jeg havde udtalet i mit Hjerte, se, da kom Rebekka ud, og hendes Krukke var paa hendes Skulder, og hun gik ned til Brønden og drog Vand! da sagde jeg til hende: Kære, giv mig at drikke.
46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
Saa skyndte hun sig og tog sin Krukke ned ad sig og sagde: Drik, og jeg vil ogsaa give dine Kameler at drikke; og jeg drak, og hun gav ogsaa Kamelerne at drikke.
47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
Og jeg spurgte hende og sagde: Hvis Datter er du? og hun sagde: Jeg er en Datter af Bethuel, Nakors Søn, som Milka fødte ham. Saa hængte jeg en Ring i hendes Næse og Armbaand paa hendes Hænder.
48 Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
Og jeg bøjede mig og tilbad Herren og lovede Herren, min Herre Abrahams Gud, som havde ledet mig paa den rette Vej at tage min Herres Broders Datter til hans Søn.
49 Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
Og nu, dersom I ville vise Miskundhed og Trofasthed mod min Herre, siger mig det; men dersom I ikke ville det, da siger mig det, at jeg kan vende mig til den højre eller til den venstre Side.
50 Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
Da svarede Laban og Bethuel og sagde: Denne Sag er kommen fra Herren, vi kunne hverken tale til dig ondt eller godt.
51 Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
Se, der er Rebekka for dig, tag hende og gak, at hmi bliver din Herres Søns Hustru, som Herren har sagt.
52 Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
Og det skete, der Abrahams Svend hørte deres Ord, da bøjede han sig til Jorden for Herren.
53 Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
Og Svenden udtog Sølvtøj og Guldtøj og Klæder og gav Rebekka; men hendes Broder og hendes Moder gav han dyrebar Skænk.
54 Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
Saa aade de og drak, han og de Mænd, som vare med ham, og bleve der om Natten, og de stode op om Morgenen, og han sagde: Lader mig fare til min Herre!
55 Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
Da sagde hendes Broder og hendes Moder: Lad Pigen blive hos os nogle Dage eller ti, siden maa du fare.
56 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
Og han sagde til dem: Holder mig ikke op, thi Herren har givet Lykke paa min Rejse; lader mig fare, og jeg vil vandre til min Herre.
57 Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
Og de sagde: Lader os kalde Pigen og spørge, hvad hun siger.
58 Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
Saa kaldte de ad Rebekka og sagde til hende: Vil du fare med denne Mand? og hun sagde: Jeg vil fare.
59 Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
Saa lode de deres Søster Rebekka og hendes Amme og Abrahams Svend og hans Mænd fare.
60 Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
Og de velsignede Rebekka og sagde til hende: Vor Søster! bliv du til tusinde Gange Titusinde, og din Sæd skal eje sine Fjenders Port.
61 Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Saa stod Rebekka op og hendes Piger, og de satte sig paa Kameler og fore med Manden, og Svenden annammede Rebekka og for bort.
62 Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
Og Isak kom gaaende fra den Brønd, som kaldes Beer Lakai Roi; thi han boede i Landet imod Sønden.
63 Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
Og Isak var udgangen til at gøre Bøn paa Marken mod Aften, og han opløftede sine Øjne og saa, og se, Kamelerne kom.
64 Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
Og Rebekka opløftede sine Øjne og saa Isak og steg hastig ned ad Kamelen.
65 ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
Og hun sagde til Svenden: Hvo er den Mand, som gaar paa Marken imod os? og Svenden sagde: Det er min Herre; saa tog hun et Slør og skjulte sig.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
Og Svenden fortalte Isak hele Sagen, som han havde udrettet.
67 Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.
Saa ledte Isak hende til sin Moder Saras Telt, og han tog Rebekka, og hun blev hans Hustru, og han elskede hende; og Isak blev trøstet efter sin Moder.

< Genesis 24 >